< I Jana 3 >

1 Patrzcie, jaką miłość dał nam Ojciec, abyśmy dziatkami Bożemi nazwani byli. Dlategoć świat nie zna nas, iż onego nie zna.
Ẹ wo irú ìfẹ́ tí Baba fi fẹ́ wa, tí a fi ń pè wá ní ọmọ Ọlọ́run; bẹ́ẹ̀ ni a sá à jẹ́. Nítorí èyí ni ayé kò ṣe mọ̀ wá, nítorí tí kò mọ̀ ọ́n.
2 Najmilsi! teraz dziatkami Bożemi jesteśmy, ale się jeszcze nie objawiło, czem będziemy; lecz wiemy, iż gdy się on objawi, podobni mu będziemy; albowiem ujrzymy go tak, jako jest.
Olùfẹ́, ọmọ Ọlọ́run ni àwa ń ṣe nísinsin yìí, a kò ì tí i fihàn bí àwa ó ti rí: àwa mọ̀ pé, nígbà tí òun ba farahàn, àwa yóò dàbí rẹ̀; nítorí àwa yóò rí i, àní bí òun tí rí.
3 A ktokolwiek ma tę nadzieję w nim, oczyszcza się, jako i on czysty jest.
Olúkúlùkù ẹni tí ó ba sì ní ìrètí yìí nínú rẹ̀, ń wẹ ara rẹ̀ mọ́, àní bí òun ti mọ́.
4 Każdy, co czyni grzech, ten i zakon przestępuje; albowiem grzech jest przestępstwo zakonu.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ó ń rú òfin pẹ̀lú, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ni rírú òfin.
5 A wiecie, iż się on objawił, aby grzechy nasze zgładził, a grzechu w nim nie masz.
Ẹ̀yin sì mọ̀ pé, òun farahàn láti mu ẹ̀ṣẹ̀ kúrò; ẹ̀ṣẹ̀ kò sì ṣí nínú rẹ̀.
6 Wszelki tedy, kto w nim mieszka, nie grzeszy; ale ktokolwiek grzeszy, nie widział go, ani go poznał.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba ń gbé inú rẹ̀ kì í dẹ́ṣẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ń dẹ́ṣẹ̀ kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni kò mọ̀ ọ́n.
7 Dziateczki! niechaj was nikt nie zwodzi; kto czyni sprawiedliwość, sprawiedliwy jest, jako i on sprawiedliwy jest;
Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín, ẹni tí ó bá ń ṣe òdodo, ó jásí olódodo, gẹ́gẹ́ bí òun tí jẹ olódodo.
8 Kto czyni grzech, z dyjabła jest; gdyż od początku dyjabeł grzeszy. Na to się objawił Syn Boży, aby zepsował uczynki dyjabelskie.
Ẹni tí ó ba ń dẹ́ṣẹ̀ tí èṣù ni; nítorí láti àtètèkọ́ṣe ni èṣù ti ń dẹ́ṣẹ̀. Nítorí èyí ni Ọmọ Ọlọ́run ṣe farahàn, kí ó lè pa iṣẹ́ èṣù run.
9 Wszelki, co się narodził z Boga, grzechu nie czyni, iż nasienie jego w nim zostaje, i nie może grzeszyć, iż z Boga narodzony jest.
Ẹnikẹ́ni tí a ti ipa Ọlọ́run bí, kì í dẹ́ṣẹ̀; nítorí tí irú rẹ̀ ń gbé inú rẹ̀, kò sì lè dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé a ti ti ipa Ọlọ́run bí i.
10 Po tem poznać dziatki Boże i dzieci dyjabelskie. Wszelki, który nie czyni sprawiedliwości, nie jest z Boga, i który nie miłuje brata swego.
Nínú èyí ni àwọn ọmọ Ọlọ́run ń farahàn, àti àwọn ọmọ èṣù; ẹnikẹ́ni tí kò ba ń ṣe òdodo, àti ẹni tí kò fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ kì í ṣe ti Ọlọ́run.
11 Albowiem to jest poselstwo, któreście słyszeli od początku, abyśmy jedni drugich miłowali.
Nítorí èyí ni iṣẹ́ tí ẹ̀yin tí gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe, pé ki àwa fẹ́ràn ara wa.
12 Nie jako Kain, który był z tego złośnika i zabił brata swego. A dlaczegoż go zabił? Iż uczynki jego złe były, a brata jego sprawiedliwe.
Kì í ṣe bí Kaini, tí í ṣe ẹni búburú, tí o sì pa arákùnrin rẹ̀. Nítorí kín ni ó sì ṣe pa á? Nítorí tí iṣẹ́ tirẹ̀ jẹ́ búburú ṣùgbọ́n tí arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ òdodo.
13 Nie dziwujcie się, bracia moi! jeźli was świat nienawidzi.
Kì ẹnu má ṣe yà yín, ẹ̀yin ará mi, bí ayé bá kórìíra yín.
14 My wiemy, żeśmy przeniesieni z śmierci do żywota, iż miłujemy braci; kto nie miłuje brata, zostaje w śmierci.
Àwa mọ̀ pé àwa tí rékọjá láti inú ikú sínú ìyè, nítorí tí àwa fẹ́ràn àwọn ará. Ẹni tí kò ba ni ìfẹ́, ó ń gbé inú ikú.
15 Każdy, co nienawidzi brata swego, mężobójcą jest; a wiecie, iż żaden mężobójca nie ma żywota wiecznego w sobie zostawającego. (aiōnios g166)
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kórìíra arákùnrin rẹ̀ apànìyàn ni, ẹ̀yin sì mọ́ pé kò sí apànìyàn tí ó ni ìyè àìnípẹ̀kun láti máa gbé inú rẹ̀. (aiōnios g166)
16 Przez tośmy poznali miłość Bożą, iż on duszę swoję za nas położył; i myśmy powinni kłaść duszę za braci.
Nípa èyí ni àwa mọ ìfẹ́ nítorí tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ fún wa, ó sì yẹ kí àwa fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún àwọn ará.
17 A kto by miał majętność świata tego i widziałby brata swego potrzebującego, a zawarłby wnętrzności swoje przed nim, jakoż w nim zostaje miłość Boża?
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ni ohun ìní ayé, tí ó sì ri arákùnrin rẹ̀ tí ó ṣe aláìní, tí ó sì sé ìlẹ̀kùn ìyọ́nú rẹ̀ mọ́ ọn, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe ń gbé inú rẹ̀?
18 Dziateczki moje! nie miłujmy słowem ani językiem, ale uczynkiem i prawdą.
Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi ọ̀rọ̀ tàbí ahọ́n fẹ́ràn, bí kò ṣe ni ìṣe àti ní òtítọ́.
19 A przez to poznajemy, iż z prawdy jesteśmy i przed nim uspokojemy serca nasze.
Àti nípa èyí ni àwa ó mọ̀ pé àwa jẹ́ ti òtítọ́, àti pé àwa ó sì fi ọkàn ara wa balẹ̀ níwájú rẹ̀.
20 Bo jeźliby nas potępiało serce nasze, daleko większy jest Bóg niż serce nasze i wie wszystko.
Nínú ohunkóhun tí ọkàn wa bá ń dá wa lẹ́bi; nítorí pé Ọlọ́run tóbi ju ọkàn wa lọ, ó sì mọ ohun gbogbo.
21 Najmilsi! jeźliby serce nasze nas nie potępiało, ufanie mamy ku Bogu;
Olùfẹ́, bí ọkàn wa kò bá dá wa lẹ́bi, ǹjẹ́ àwa ni ìgboyà níwájú Ọlọ́run?
22 I o cokolwiek byśmy prosili, bierzemy od niego; bo przykazania jego chowamy i to, co się podoba przed obliczem jego, czynimy.
Àti ohunkóhun tí àwa bá béèrè, ni àwa ń rí gbà lọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí tí àwa ń pa òfin rẹ̀ mọ́, àwa sì ń ṣe àwọn nǹkan tí ó dára lójú rẹ̀.
23 A toć jest przykazanie jego, abyśmy wierzyli imieniowi Syna jego, Jezusa Chrystusa, i miłowali jedni drugich, jako nam przykazał.
Èyí sì ni òfin rẹ̀, pé kí àwa gba orúkọ Jesu Kristi Ọmọ rẹ̀ gbọ́, kí a sì fẹ́ràn ara wá gẹ́gẹ́ bí ó tí fi òfin fún wa.
24 Bo kto chowa przykazania jego, w nim mieszka, a on też w nim; a przez to znamy, iż mieszka w nas, to jest z Ducha, którego nam dał.
Ẹni tí ó bá sì pa òfin rẹ̀ mọ́ ń gbé inú rẹ̀, àti òun nínú rẹ̀. Àti nípa èyí ni àwa mọ̀ pé ó ń gbé inú wa, nípa Ẹ̀mí tí ó fi fún wa.

< I Jana 3 >