< I Kronik 4 >
1 Synowie Judowi: Fares, Hesron, i Charmi, i Hur, i Sobal.
Àwọn ọmọ Juda: Peresi, Hesroni, Karmi, Huri àti Ṣobali.
2 A Rejasz, syn Sobalowy spłodził Jahata, a Jahat spłodził Achuma, i Laada. Teć są rodzaje Zaratego.
Reaiah ọmọ Ṣobali ni baba Jahati, àti Jahati baba Ahumai àti Lahadi. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀yà ará Sorati.
3 Ci też są z ojca Etama: Jezreel, i Jesema, i Idbas; a imię siostry ich Selelfuni.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Etamu: Jesreeli, Iṣima, Idbaṣi, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Haseleponi
4 A Faunuel ojciec Giedory, i Ezer ojciec Hosy. Cić są synowie Hura, pierworodnego Efraty, ojca Betlehemczyków.
Penueli sì ni baba Gedori, àti Eseri baba Huṣa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata àti baba Bẹtilẹhẹmu.
5 A Assur, ojciec Tekui, miał dwie żony: Chelę i Naarę.
Aṣihuri baba Tekoa sì ní aya méjì, Hela àti Naara.
6 I urodziła mu Naara Achusama, i Hefera, i Temana, i Achastara. Cić są synowie Naary.
Naara sì bí Ahussamu, Heferi Temeni àti Haaṣtari. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Naara.
7 Synowie zasię Cheli: Seret, Jesochar, i Etnan.
Àwọn ọmọ Hela: Sereti Sohari, Etani,
8 A Kos spłodził Anuba, i Hasoboba, i dom Acharchela, syna Harumy.
àti Kosi ẹni tí ó jẹ́ baba Anubu àti Sobeba àti ti àwọn ẹ̀yà Aharheli ọmọ Harumu.
9 A Jabes był zacniejszy nad braci swych, któremu matka jego dała imię Jabes, mówiąc: Bom go w boleści urodziła.
Jabesi sì ní ọlá ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jabesi wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
10 I wzywał Jabes Boga Izraelskiego, mówięc: Jeźli błogosławiąc błogosławić mi będziesz, a rozszerzysz granice moje, a będzie ręka twoja ze mną, a wybawisz mię od złego, abym utrapiony nie był. I wypełnił to Bóg, o co go prosił.
Jabesi sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Israẹli wí pé, “Háà, Ìwọ yóò bùkún fún mi, ìwọ yóò sì mú agbègbè mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mi mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
11 A Chelub, brat Sucha, spłodził Mechyra; ten jest ojcem Estona.
Kelubu arákùnrin Ṣuha, sì jẹ́ baba Mehiri, ẹni tí ó jẹ́ baba Eṣtoni.
12 A Eston spłodził Betrafa, i Paseacha, i Techynna, ojca miasta Nahas. Cić są mężowie Rechy.
Eṣtoni sì jẹ́ baba Beti-Rafa, Pasea àti Tehina ti baba ìlú Nahaṣi. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Reka.
13 A synowie Kienazowi: Otonijel, i Seraja; a synowie Otonijelowi: Hatat i Meanataj.
Àwọn ọmọ Kenasi: Otnieli àti Seraiah. Àwọn ọmọ Otnieli: Hatati àti Meonotai.
14 A Meanataj spłodził Ofra, a Serajasz spłodził Joaba, ojca w dolinie mieszkających rzemieślników; bo rzemieślnicy byli.
Meonotai sì ni baba Ofira. Seraiah sì jẹ́ baba Joabu, baba Geharaṣinu. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn oníṣọ̀nà ní ìwọ̀n.
15 Synowie zasię Kaleba, syna Jefumi: Hyru, Ela, i Nahain; a syn Ela jest Kienaz.
Àwọn ọmọ Kalebu ọmọ Jefunne: Iru, Ela, àti Naamu. Àwọn ọmọ Ela: Kenasi.
16 A synowie Jehaleleela: Zyf i Zyfa, Tyryja, i Azarel.
Àwọn ọmọ Jehaleeli: Sifi, àti Sifa, Tiria àti Asareeli.
17 A synowie Ezry: Jeter, i Mered, i Efer, i Jalon; a żona Merodowa urodziła Miryjama, i Samaja, i Isbacha, ojca Estemoa.
Àwọn ọmọ Esra: Jeteri, Meredi, Eferi àti Jaloni. Ọ̀kan lára àwọn aya Meredi sì bí Miriamu, Ṣammai àti Iṣba baba Eṣitemoa.
18 Żona też jego Judaja urodziła Jereda, ojca Giedor, i Hebera, ojca Socho, i Jekutyjela, ojca Zanoach. Cić są synowie Betii, córki Faraonowej, którą był pojął Mered.
Aya rẹ̀ láti ẹ̀yà Juda sì bí Jaredi baba Gedori, àti Heberi baba Soko àti Jekutieli baba Sanoa. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọbìnrin Farao Bitia, ẹni ti Meredi ti fẹ́.
19 A synowie żony Hodyjaszowej, siostry Nahama, ojca Ceili: Garmi i Estemoa Mahatczyk.
Àwọn ọmọ aya Hodiah arábìnrin Nahamu, baba Keila ará Garimu, àti Eṣitemoa àwọn ará Maakati.
20 A synowie Symonowi: Amnon, i Rynna, Benchanan i Tylon; a synowie Isy: Zochet i Bensochet.
Àwọn ọmọ Ṣimoni: Amnoni, Rina, Beni-Hanani àti Tiloni. Àwọn ọmọ Iṣi: Soheti àti Beni-Soheti.
21 Synowie Seli, syna Judowego: Her, ojciec Lecha i Laada, ojciec Maraa; i rodzaje domów tych, którzy robili około bisioru w domu Asbeat,
Àwọn ọmọ Ṣela ọmọ Juda: Eri baba Leka, Lada baba Meraṣa àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń hun aṣọ oníṣẹ́ ní Beti-Aṣibea.
22 I Joakim i mężowie Chozeby, i Joaz i Saraf, którzy panowali w Moab, i Jasubi Lechem; ale te rzeczy są dawne.
Jokimu, ọkùnrin Koseba, àti Joaṣi àti Sarafi, olórí ní Moabu àti Jaṣubi Lehemu. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́.)
23 Cić są garncarze, którzy mieszkali w sadach i między płotami, którzy tam przy królu dla robót jego mieszkali.
Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Netaimu àti Gedera; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ fún ọba.
24 Synowie Symeonowi: Namuel, i Jamin, i Jaryb, Zera, Saul.
Àwọn ọmọ Simeoni: Nemueli, Jamini, Jaribi, Sera àti Saulu;
25 Sallum syn jego, Mabsam syn jego, Misma syn jego.
Ṣallumu sì jẹ́ ọmọ Saulu, Mibsamu ọmọ rẹ̀ Miṣima ọmọ rẹ̀.
26 A synowie Mismy: Hamuel syn jego, Zachur syn jego, Semej syn jego.
Àwọn ọmọ Miṣima: Hamueli ọmọ rẹ̀ Sakkuri ọmọ rẹ̀ àti Ṣimei ọmọ rẹ̀.
27 Ten Semej miał synów szesnaście, i córek sześć; ale bracia jego nie mieli wiele synów, tak, że wszystkiej rodziny ich nie było tak wiele, jako synów Judowych.
Ṣimei sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Juda.
28 I mieszkali w Beerseba i w Molada, i w Hasersual,
Wọ́n sì ń gbé ní Beerṣeba, Molada, Hasari-Ṣuali,
29 I w Bela, i w Asem, i w Etolad,
àti ní Biliha, àti ní Esemu, àti ní Toladi,
30 I w Betul, i w Horma, i w Sycelegu,
Betueli, Horma, Siklagi,
31 I w Bet Marchabot, i w Hasersusa, i w Betbirze, i w Saaraim. Te miasta ich były, póki królował Dawid.
Beti-Markaboti Hormah; Hasari Susimu, Beti-Biri àti Ṣaraimi. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dafidi,
32 A wsi ich były: Etam, i Hain, Remnon, i Tochen i Asan przy tych pięciu miastach;
agbègbè ìlú wọn ni Etamu, Aini, Rimoni, Tokeni, Aṣani àwọn ìlú márùn-ún,
33 I wszystkie wsi ich, które były około tych miast aż do Baal; teć były mieszkaniem ich według narodu ich.
àti gbogbo ìletò wọn, tí ó wà yí ìlú náà ká, dé Baali. Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn. Àti ìtàn ìdílé wọ́n.
34 A Mosobab, i Jamlech, i Josa, syn Amazyjaszowy;
Meṣobabu àti Jamleki, Josa ọmọ Amasiah,
35 I Joel, i Jehu, syn Josabijasza, syna Serajaszowego, syna Asyjelowego;
Joẹli, Jehu ọmọ Josibiah, ọmọ Seraiah, ọmọ Asieli,
36 I Elichenaj, i Jakóba, i Jesochaja, i Asaja, i Adyjel, i Jesymijel, i Banajas;
àti pẹ̀lú Elioenai, Jaakoba, Jeṣohaiah, Asaiah, Adieli, Jesimieli, Benaiah,
37 I Sysa, syn Syfy, syna Allonowego, syna Jodajaszowego, syna Symry, i syna Semajaszowego.
àti Sisa ọmọ Ṣifi ọmọ Alloni, ọmọ Jedaiah, ọmọ Ṣimri ọmọ Ṣemaiah.
38 Ci mianowani postanowieni są za książęta w narodach swych, a domy ojców ich rozmnożyły się bardzo.
Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ sí i gidigidi,
39 Przetoż ruszyli się, aby szli do Gador, aż na wschód słońca onej doliny, aby szukali paszy bydłu swemu.
wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gedori. Lọ títí dé ìlà-oòrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn.
40 I znaleźli obfite i wyborne pasze, a ziemię przestronną i spokojną i rodzajną; bo tam naród Chamów mieszkał przedtem.
Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ọmọ Hamu ni ó ti ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
41 Przetoż przyszedłszy ci z imienia opisani za dni Ezechyjasza, króla Judzkiego, poburzyli namioty ich i przybytki ich, które tam były znalezione; a wymordoealiich, i nie masz ich aż do dnia tego, i osiedli miejsce ich; bo tam mieli paszy dla bydeł swoich.
Àwọn ọkùnrin tí a kọ orúkọ rẹ̀ sókè, dé ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Wọ́n sì kọlu àwọn ará Hamu ní àgọ́ wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Mehuni tí a rí níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátápátá títí di òní yìí. Wọ́n sì ń gbé ní ipò wọn, nítorí pé koríko ń bẹ níbẹ̀ fún agbo ẹran wọn.
42 A z onych synów Symeonowych niektórzy szli na górę Seir, pięć set mężów, a Faltyjasz, i Necharyjasz, i Rafajasz, i Husel, synowie Isy, byli wodzami ich.
Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Simeoni, lábẹ́ ìdarí pẹ̀lú Pelatiah, Neariah, Refaiah àti Usieli, àwọn ọmọ Iṣi, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Seiri.
43 I wymordowali ostatki, które były uszły z Amalekitów, a mieszkali tam aż po dziś dzień.
Wọ́n sì pa àwọn ará Amaleki tí ó kù, àwọn tí ó ti sálà, wọ́n sì ti ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.