< I Kronik 25 >
1 I odłączył Dawid i hetmani wojska na posługiwanie synów Asafowych i Hemanowych, i Jedytunowych, którzy prorokowali przy cytrach, i przy harfach, i przy cymbałach. A była liczba ich, to jest mążów pracujących w usłudze swej:
Pẹ̀lúpẹ̀lú Dafidi àti àwọn olórí àwọn ọmọ-ogun, ó sì yà díẹ̀ sọ́tọ̀ lára àwọn ọmọ Asafu, Hemani àti Jedutuni fún ìsìn àsọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú dùùrù, ohun èlò orin olókùn àti kimbali. Èyí sì ní àwọn iye àwọn ọkùnrin ẹni tí ó ṣe oníṣẹ́ ìsìn yìí.
2 Z synów Asafowych: Zachur, i Józef, i Natanijasz, i Asarela. Synowie Asafowi byli pod ręką Asafową, który prorokował na rozkazanie królewskie.
Nínú àwọn ọmọ Asafu: Sakkuri, Josẹfu, Netaniah àti Asarela, àwọn ọmọ Asafu ni wọ́n wà lábẹ́ ìbojútó Asafu, ẹni tí ó sọtẹ́lẹ̀ lábẹ́ ìbojútó ọba.
3 Z Jedytuna: Synowie Jedytunowi: Godolijasz, i Zery, i Jesajasz, Hasabijasz, i Matytyjasz, i Symej, sześć, pod ręką ojca ich Jedytuna, który prorokował przy harfie, wyznawając i chwaląc Pana.
Gẹ́gẹ́ bí ti Jedutuni, nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀: Gedaliah, Seri, Jeṣaiah, Ṣimei, Haṣabiah àti Mattitiah, mẹ́fà nínú gbogbo wọn, lábẹ́ ìbojútó baba wọn Jedutuni, ẹni tí ó sọtẹ́lẹ̀, ẹni tí ó lo dùùrù láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa.
4 Z Hemana: Synowie Hemanowi: Bukkijasz, Matanijasz, Husyjel, Zebuel, i Jerymot, Chananijasz, Chanani, Eliata, Gieddalty, i Romantyjeser, i Jasbekassa, Malloty, Hotyr, Machazyjot.
Gẹ́gẹ́ bí ti Hemani, nínú àwọn ọmọ rẹ̀: Bukkiah, Mattaniah, Usieli, Ṣubaeli àti Jerimoti; Hananiah, Hanani, Eliata, Giddalti, àti Romamtieseri, Joṣbekaṣa, Malloti, Hotiri, Mahasiotu.
5 Ci wszyscy byli synowie Hemana, widzącego królewskiego w słowach Bożych, ku wywyższeniu rogu: bo dał Bóg czternaście synów Hemanowych, i trzy córki.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Hemani àti wòlíì ọba. Wọ́n sì fi wọ́n fún nípa ìlérí Ọlọ́run láti máa gbé ìwo sókè. Ọlọ́run sì fún Hemani ní ọmọkùnrin mẹ́rìnlá àti àwọn ọmọbìnrin mẹ́ta.
6 Ci wszyscy byli pod sprawą ojca swego przy śpiewaniu w domu Pańskim na cymbałach, na lutniach, i na cytrach ku służbie w domu Bożym, jako rozkazał król, i Asaf, Jedytun, i Heman.
Gbogbo àwọn ọkùnrin yìí ni wọ́n wà lábẹ́ ìbojútó àwọn baba wọn fún ohun èlò orin ilé Olúwa, pẹ̀lú kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù, fún ìsìn ilé Olúwa. Asafu, Jedutuni àti Hemani sì wà lábẹ́ ọba.
7 A był poczet ich z braci ich, którzy byli ćwiczonymi w pieśniach Pańskich, wszystkich mistrzów dwieście ośmdziesiąt i ośm.
Àwọn ìdílé wọn pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó mòye àti àwọn tí a kọ́ ní ohun èlò orin fún Olúwa, iye wọn sì jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́jọ.
8 I miotali losy, straż przeciwko straży, tak mały jako i wielki, tak mistrz jako i uczeń.
Kékeré àti àgbà bákan náà, olùkọ́ àti gẹ́gẹ́ bí ti akẹ́kọ̀ọ́, ṣẹ́ kèké fún iṣẹ́ wọn.
9 I padł los pierwszy w domu Asafowym na Józefa; na Godolijasza wtóry, z braćmi jego i z synami jego, których było dwanaście.
Kèké èkínní èyí tí ó jẹ́ ti Asafu, jáde sí Josẹfu, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá èkejì sì ni Gedaliah, òun àti àwọn ìdílé rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, méjìlá
10 Na Zachura trzeci, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹta sí Sakkuri, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé, méjìlá
11 Czwarty na Isrego, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin sí Isiri, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
12 Piąty na Natanijasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀karùnún sí Netaniah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
13 Szósty na Bukkijasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà sí Bukkiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
14 Siódmy na Jesarela, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀keje sí Jasarela, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
15 Osmy na Jesajasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ sí Jeṣaiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
16 Dziewiąty na Matanijasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án sí Mattaniah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
17 Dziesiąty na Symejasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá sí Ṣimei, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
18 Jedenasty na Asarela, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá sí Asareeli, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
19 Dwunasty na Hasabijasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹjìlá sí Haṣabiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
20 Trzynasty na Subajela, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹtàlá sí Ṣubaeli, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
21 Czternasty na Matytyjasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlá sí Mattitiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
22 Piętnasty na Jerymota, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹẹ̀dógún sí Jerimoti, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
23 Szesnasty naChananijasza, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínlógún sí Hananiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
24 Siedemnasty na Jesbekassa, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹtàdínlógún sí Joṣbekaṣa, àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
25 Ośmnasty na Chananijego, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kejìdínlógún sí Hanani, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
26 Dziewiętnasty na Mallotego, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kọkàndínlógún sí Malloti, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
27 Dwudziesty na Elijata, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ogún sí Eliata, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
28 Dwudziesty i pierwszy na Hotyra, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kọkànlélógún sí Hotiri, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
29 Dwudziesty i wtóry na Gieddaltego, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kejìlélógún sí Giddalti, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
30 Dwudziesty i trzeci na Machazyjota, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹtàlélógún sí Mahasiotu, àwọn ọmọ rẹ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
31 Dwudziesty i czwarty na Romantyjesera, na synów jego i na braci jego dwanaście.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlélógún sí Romamtieseri àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá.