< I Kronik 18 >
1 I stało się potem, że poraził Dawid Filistynów i poniżył ich, a wziął Get i wsi jego z rąk Filistynów.
Ní àkókò kan, Dafidi kọlu àwọn ará Filistini, ó sì ṣẹ́gun wọn. Ó sì mú Gati àti àwọn ìletò agbègbè rẹ̀ kúrò lábẹ́ ìdarí àwọn ará Filistini.
2 Poraził też Moabczyki, i byli Moabczyki sługami Dawidowymi, przynosząc mu hołd.
Dafidi borí àwọn ará Moabu, wọ́n sì di ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì mú owó òde wá.
3 Poraził też Dawid Hadarezera, króla Soby w Emat, gdy był wyjechał, aby rozprzestrzeniał państwo swoje nad rzeką Eufrates.
Síbẹ̀, Dafidi sì kọlu Hadadeseri ọba Soba ní Hamati, bí ó ti ń lọ láti fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ létí odò Eufurate.
4 Zabrał mu tedy Dawid tyziąc wozów, i siedm tysięcy jezdnych, i dwadzieścia tysięcy mężów pieszych, i poderznął Dawid żyły wszystkich woźników, zachowawszy z nich koni do sta wozów.
Dafidi fi agbára gba ẹgbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ àti ogún ẹgbẹ̀rún ológun ilẹ̀. Ó sì já gbogbo ọgọ́rùn-ún iṣan ẹsẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin náà.
5 Przyciągnęli też Syryjczycy z Damaszku na pomoc Hadarezerowi, królowi Soby; lecz poraził Dawid z Syryjczyków dwadzieścia i dwa tysiące mężów.
Nígbà ti àwọn ará Siria ti Damasku wá láti ran Hadadeseri ọba Soba lọ́wọ́, Dafidi lu ẹgbẹ̀rún méjìlélógún wọn bọ lẹ̀.
6 Tedy Dawid osadził żołnierzem Syryję Damaską, a byli Syryjczycy sługami Dawidowymi, oddawając mu hołd; i zachowywał Pan Dwida, gdzie się kolwiek obrócił.
Ó sì fi àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ sínú ìjọba Siria ti Damasku, àwọn ará Siria sì ń sìn ní abẹ́ rẹ̀, wọ́n sì mú owó ìṣákọ́lẹ̀ wá. Olúwa sì ń fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní ibi gbogbo tí ó bá lọ.
7 Pobrał też Dawid tarcze złote, które mieli słudzy Hadarezerowi, i wniósł je do Jeruzalemu.
Dafidi mú àpáta wúrà tí àwọn ìjòyè Hadadeseri gbé, ó sì gbé wọn wá sí Jerusalẹmu.
8 Przytem z Tybchat i z Chun, miast Hadarezerowych, nabrał Dawid miedzi bardzo wiele, z której Salomon sprawił morze miedziane, i słupy, i naczynia miedziane.
Láti Tibhati àti Kuni, àwọn ìlú Hadadeseri, Dafidi kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ idẹ tí Solomoni lò láti fi ṣe okùn idẹ, àwọn òpó àti oríṣìí ohun èlò idẹ.
9 A gdy usłyszał Tohy, król Emat, że poraził Dawid wszystko wojsko Hadarezera, króla Soby.
Nígbà tí Tou ọba Hamati gbọ́ pé Dafidi ti borí gbogbo ọmọ-ogun Hadadeseri ọba Soba.
10 Posłał Adorama, syna swego, do króla Dawida, aby go pozdrowił w pokoju, i aby mu powinszował, przeto, że zwalczył Hadarezera, i poraził go; (albowiem walczył Tohy z Hadarezerem) który przyniósł z sobą wszelakie naczynie złote, i srebrne, i miedziane.
Ó rán ọmọ rẹ̀ Hadoramu sí ọba Dafidi láti kí i àti láti lọ bá a yọ̀ lórí ìṣẹ́gun rẹ̀ nínú ogun lórí Hadadeseri, tí ó wà lójú ogun pẹ̀lú Tou. Hadoramu mú oríṣìíríṣìí ohun èlò ti wúrà àti fàdákà àti idẹ wá.
11 Które też poświęcił król Dawid Panu z srebrem i ze złotem, które był pobrał od wszystkich narodów, od Edomczyków, i od Moabczyków, o od synów Ammonowych, i od Filistynów, i od Amalekitów.
Ọba Dafidi ya ohun èlò wọ́n yí sí mímọ́ fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe pẹ̀lú fàdákà àti wúrà tí ó ti mú láti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí: Edomu àti Moabu, ará Ammoni àti àwọn ará Filistini àti Amaleki.
12 A Abisaj, syn Sarwii, poraził Edomczyków w dolinie solnej ośmnaście tysięcy.
Abiṣai ọmọ Seruiah lu ẹgbàá mẹ́sàn ará Edomu bolẹ̀ ní àfonífojì Iyọ̀.
13 I osadził Edomską ziemię żołnierzem: a byli wszyscy Edomczycy sługami Dawidowymi: i zachowywał Pan Dawida wszędzie, gdzie się obrócił.
Ó fi ẹgbẹ́ ogun sí Edomu, gbogbo àwọn ará Edomu sì ń sìn ní abẹ́ Dafidi. Olúwa fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní gbogbo ibí tí ó bá lọ.
14 A tak królował Dawid nad wszystkim Izraelem, czyniąc sąd i sprawiedliwość wszystkiemu ludowi swemu.
Dafidi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli, ó sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 A był Joab, syn Sarwii, nad wojskiem, a Jozafat, syn Ahiludowy, kanclerzem.
Joabu ọmọ Seruiah jẹ́ olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi jẹ́ akọ̀wé ìrántí;
16 A Sadok, syn Achitobowy, i Abimelech, syn Abijatara, byli kapłanami, a Susa był pisarzem.
Sadoku ọmọ Ahitubu àti Abimeleki ọmọ Abiatari jẹ́ àwọn àlùfáà; Ṣafṣa jẹ́ akọ̀wé;
17 Benajasz też, syn Jojady, był przełożonym nad Cheretczykami i Feletczykami; a synowie Dawidowi byli pierwszymi przy boku królewskim.
Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ́ olórí àwọn Kereti àti Peleti; àwọn ọmọ Dafidi sì ni àwọn olóyè oníṣẹ́ ní ọ̀dọ̀ ọba.