< I Kronik 17 >

1 I stało się, gdy mieszkał Dawid w domu swym, że rzekł do Natana proroka: Oto ja mieszkam w domu cedrowym, a skrzynia przymierza Pańskiego pod kortynami.
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti fi ìdí kalẹ̀ sínú ààfin rẹ̀, ó sọ fún Natani wòlíì pé, “Èmi nìyí, tí ń gbé inú ààfin kedari nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wà lábẹ́ àgọ́.”
2 I rzekł Natan do Dawida: Cokolwiek jest w sercu twem, uczyń, gdyż Bóg jest z tobą.
Natani dá Dafidi lóhùn pé, “Ohunkóhun tí o bá ní lọ́kàn, ṣe é nítorí tí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.”
3 Potem onej nocy stało się słowo Boże do Natana, mówiąc:
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Natani wá, wí pé:
4 Idź, a mów do Dawida, sługi mego: Tak mówi Pan: Nie ty mi będziesz budował domu do mieszkania;
“Lọ sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún mi láti máa gbé.
5 Ponieważem nie mieszkał w domu ode dnia, któregom wywiódł synów Izraelskich, aż do dnia tego: alem się przechadzał z namiotu do namiotu, i z przybytku do przybytku.
Èmi kò tí ì gbé nínú ilé láti ọjọ́ tí mo ti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí. Èmi ń lọ láti àgọ́ dé àgọ́ àti láti ibùgbé dé ibùgbé.
6 Wszędzie gdziemkolwiek chodził ze wszystkim Izraelem, izalim i słowo rzekł któremu z sędziów Izraelskich, którymem rozkazał, aby paśli lud mój, mówiąc: Przeczżeście mi nie zbudowali domu cedrowego?
Ni ibi gbogbo tí mo ti bá gbogbo Israẹli rìn dé, ǹjẹ́ mo wí nǹkan kan sí ọ̀kan nínú àwọn adarí Israẹli, tí èmí pàṣẹ fún láti máa jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn mi, wí pé, “Kí ní ṣe tí ẹ̀yin kò fi kọ́ ilé tí a fi igi kedari kọ́ fún mi?”’
7 Przetoż teraz tak powiesz słudze memu Dawidowi: Tak mówi Pan zastępów: Jam ciebie wziął z owczarni, gdyś chodził za trzodą, abyś był wodzem nad ludem moim Izraelskim;
“Nígbà náà, sọ fún ìránṣẹ́ mi Dafidi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: Èmi mú ọ kúrò ní pápá oko tútù wá, àní kúrò lẹ́yìn agbo àgùntàn, kí ìwọ kí ó lè máa ṣe olórí àwọn ènìyàn mi Israẹli.
8 I byłem z tobą wszędzie, gdzieśkolwiek chodził, a wygładziłem wszystkich nieprzyjaciół twoich przed twarzą twoją, i uczyniłem ci imię, jako imię wielkich ludzi, którzy są za ziemi.
Èmi ti wà pẹ̀lú rẹ ní, ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmí sì ti gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ. Nísinsin yìí Èmi yóò mú kí orúkọ rẹ kí ó dàbí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá jùlọ tí ó wà ní ayé.
9 A postanowiłem miejsce ludowi memu Izraelskiemu, i wszczepiłem go; i będzie mieszkał na miejscu swem, a nie będzie więcej poruszowny, ani go więcej synowie nieprawości trapić, jako przedtem;
Èmi yóò sì pèsè ààyè kan fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, kí wọn kí ó lè ní ilé tiwọn, kí a má sì ṣe dààmú wọn mọ́. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò ni wọ́n lára mọ́, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìbẹ̀rẹ̀.
10 Zaraz ode dni, którychem postanowił sędziów nad ludem moim Izraelskim, i poniżyłem wszystkich nieprzyjaciół twoich, i oznajmiłem ci, żeć Pan dom zbuduje.
Bí wọ́n sì ti ṣe láti ìgbà tí mo ti yan àwọn aṣáájú lórí àwọn ènìyàn mi Israẹli. Èmi pẹ̀lú yóò ṣẹ́gun gbogbo àwọn ọ̀tá yín. “‘Èmi sọ fún yín pé Olúwa yóò kọ́ ilé kan fún yín,
11 A gdy się wypełnią dni twoje, abyś szedł za ojcami twoimi, wzbudzę nasienie twoje po tobie, które będzie z synów twoich, i umocnię królestwo jego.
nígbà ti ọjọ́ rẹ bá kọjá, tí ìwọ bá lọ láti lọ bá àwọn baba à rẹ, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ sókè láti rọ́pò rẹ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ tìrẹ, Èmi yóò sì fìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀.
12 Ten mi zbuduje dom, i utwierdzę stolicę jego aż na wieki.
Òun ni ẹni tí yóò kọ́ ilé fún mi, èmi yóò sí fi ìdí ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ títí láé.
13 Ja mu będę za ojca a on mi będzie za syna, a miłosierdzia mego nie odejmę od niego, jakom je odjął od tego, który był przed tobą;
Èmi yóò jẹ́ baba rẹ̀, Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi. Èmi kì yóò mú ìfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ láéláé gẹ́gẹ́ bí mo ṣe mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn aṣáájú rẹ̀.
14 Owszem postanowię go w domu moim, i w królestwie mojem aż na wieki, a stolica jego będzie trwała aż na wieki.
Èmi yóò gbé e ka orí ilé mi àti ìjọba mi títí láé; ìtẹ́ rẹ̀ ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.’”
15 Według tych wszystkich słów i według wszystkiego widzenia tego, tak mówił Natan do Dawida.
Natani ròyìn fún Dafidi gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ ti ìfihàn yí.
16 Zatem wszedłszy król Dawid, siadł przed obliczem Pańskiem, i rzekł: Cóżem ja jest, Panie Boże! co jest dom mój, żeś mię przywiódł aż dotąd?
Nígbà náà, ọba Dafidi wọlé lọ, ó sì jókòó níwájú Olúwa ó sì wí pé, “Ta ni èmi, Olúwa Ọlọ́run, àti ki ni ìdílé mi, tí ìwọ mú mi dé ibí?
17 Lecz i to mało było przed oczyma twemi, o Boże! aleś też obietnicę uczynił o domie sługi twego na czas daleki, i wejrzałeś na mię według obyczaju ludzkiego, wywyższając mię, o Panie Boże!
Pẹ̀lú bí ẹni pé èyí kò tó lójú rẹ, Ọlọ́run, ìwọ ti sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ iwájú ilé ìránṣẹ́ rẹ. Ìwọ ti wò mí bí ẹni pé èmi ni ẹni gbígbéga jù láàrín àwọn ọkùnrin Olúwa Ọlọ́run.
18 Cóż jeszcze więcej ma mówić Dawid przed tobą o uwielbieniu sługi twego? albowiem ty znasz sługę twego.
“Kí ni ohun tí Dafidi tún lè sọ nítorí ọlá tí o bù fún ìránṣẹ́ rẹ? Nítorí tí ìwọ mọ ìránṣẹ́ rẹ,
19 Panie! dla sługi twego i według serca twego uczyniłeś te wszystkie wielkie rzeczy, abyś znajome uczynił te wszystkie wielmożne sprawy.
Olúwa. Nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ àti gẹ́gẹ́ bí àṣẹ rẹ, ìwọ ti ṣe ohun ńlá yìí àti láti fi gbogbo ìlérí ńlá yìí hàn.
20 Panie! nie masz podobnego tobie, i nie masz Boga oprócz ciebie, wedle wszystkiego, cośmy słyszeli w uszy nasze.
“Kò sí ẹnìkan bí rẹ Olúwa, kò sì sí Ọlọ́run kan àfi ìwọ, gẹ́gẹ́ bí à ti gbọ́ pẹ̀lú etí ara wa.
21 I któż jest jako lud twój, jako Izrael, naród jedyny na ziemi, dla któregoby Bóg szedł, aby go sobie odkupił za lud, a uczynił sobie imię, czyniąc wielkie rzeczy i straszne, wyganiając pogany przed twarzą ludu twego, któryś wykupił z Egiptu?
Pẹ̀lú ta ni ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ Israẹli—orílẹ̀-èdè kan ní ayé, tí Ọlọ́run jáde lọ láti ra àwọn ènìyàn kan padà fún ara rẹ̀, àti láti lè ṣe orúkọ fún ara à rẹ, àti láti ṣe ohun ńlá àti ọwọ́ ìyanu nípa lílé àwọn orílẹ̀-èdè kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀, ẹni tí ó gbàlà láti Ejibiti?
22 I uczyniłeś lud twój Izraelski sobie za lud aż na wieki, a ty Panie! stałeś się im za Boga.
Ìwọ ṣe àwọn ènìyàn rẹ Israẹli ní tìrẹ láéláé ìwọ Olúwa sì ti di Ọlọ́run wọn.
23 Przetoż teraz, o Panie! słowo, któreś powiedział o słudze twoim, i o domu jego, niech będzie stwierdzone aż na wieki, a uczyń, jakoś powiedział.
“Nísinsin yìí, Olúwa, jẹ́ kí ìlérí tí ìwọ ti ṣe fún ìránṣẹ́ rẹ àti ilé rẹ̀ di fífi ìdí múlẹ̀ títí láé. Ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe ìlérí.
24 Niechajże się tak stanie, i niechaj będzie uwielbione imię twoje aż na wieki, aby mówiono: Pan zastępów, Bóg Izraelski, Bogiem jest nad Izraelem; a dom Dawida, sługi twego, niechaj umocniony będzie przed twarzą twoją.
Kí ó lè di fífi ìdí múlẹ̀ àti kí orúkọ rẹ di gbígbéga títí láé. Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin yóò wí pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni Ọlọ́run Israẹli.’ Ilé ìránṣẹ́ rẹ Dafidi sì ni a ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níwájú rẹ.
25 Albowiemeś ty, Boże mój! objawił słudze twemu, iż mu zbudujesz dom; przetoż znalazł sługa twój u siebie, aby się modlił przed tobą.
“Ìwọ, Ọlọ́run mi, ti fihan ìránṣẹ́ rẹ pé, ìwọ yóò kọ́ ilé fún un. Bẹ́ẹ̀ ni ìránṣẹ́ rẹ ti ní ìgboyà láti gbàdúrà sí ọ.
26 A tak o Panie! tyś sam Bóg, a mówiłeś to dobre o słudze swym.
Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run. Ìwọ ti fi ìlérí dídára yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
27 Teraz tedy począłeś błogosławić domowi sługi twego, aby trwał na wieki przed tobą; boś ty Panie! jemu błogosławił, a będzie ubłogosławiony na wieki.
Nísinsin yìí ó ti tẹ́ ọ lọ́rùn láti bùkún ilé ìránṣẹ́ rẹ kí ó lè tẹ̀síwájú ní ojú rẹ; nítorí ìwọ, Olúwa, ti bùkún un, a ó sì bùkún un títí láéláé.”

< I Kronik 17 >