< Marka 1 >

1 Oto niezwykła opowieść o Jezusie—Mesjaszu, Synu Bożym.
Ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.
2 Już przez proroka Izajasza Bóg zapowiedział: „Oto Ja posyłam przed Tobą mojego wysłańca; on przygotuje Twoją drogę”.
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé, “Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ, Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”
3 „Głos wołającego na pustyni: Przygotujcie drogę dla Pana, prostujcie dla Niego ścieżki!”
“Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
4 Posłańcem tym był Jan Chrzciciel. Mieszkał na pustyni i przekonywał ludzi, że muszą zmienić swoje grzeszne życie. Na znak zerwania z grzechem powinni pozwolić zanurzyć się w wodzie.
Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
5 Mieszkańcy Jerozolimy i całej Judei podążali na Pustynię Judejską, aby zobaczyć i posłuchać Jana. Wielu z nich wyznawało swoje grzechy, a on chrzcił ich w Jordanie.
Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
6 Jan nosił ubranie z wielbłądziej wełny i skórzany pas. Żywił się wyłącznie szarańczą i leśnym miodem.
Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
7 Często mówił: —Wkrótce przyjdzie Ktoś o wiele większy ode mnie—tak wielki, że ja nie jestem nawet godzien rozwiązać rzemyka Jego sandałów.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú.
8 Ja zanurzam was w wodzie, lecz On zanurzy was w Duchu Świętym!
Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”
9 Pewnego dnia przyszedł do Jana Jezus z Nazaretu i został ochrzczony w Jordanie.
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani.
10 Gdy wychodził z wody, ujrzał otwarte niebo i Ducha Świętego, który zstąpił na Niego jak gołąb.
Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí.
11 A z nieba rozległ się głos: —Jesteś moim ukochanym Synem, moją największą radością.
Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
12 Zaraz też Jezus, prowadzony przez Ducha Świętego, udał się na pustynię.
Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù,
13 Tam, otoczony tylko przez pustynne zwierzęta, spędził samotnie czterdzieści dni i był kuszony przez szatana. Potem zaś przyszli do Niego aniołowie i służyli Mu.
Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.
14 A gdy król Herod uwięził Jana, Jezus udał się do Galilei, by tam głosić Bożą dobrą nowinę.
Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run.
15 —Nadszedł już czas!—mówił. —Zbliża się królestwo Boże! Porzućcie grzechy i uwierzcie w dobrą nowinę!
Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìyìnrere yìí gbọ́.”
16 Pewnego dnia, idąc brzegiem Jeziora Galilejskiego, Jezus spotkał dwóch rybaków: Szymona i jego brata, Andrzeja, którzy łowili ryby.
Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n.
17 —Chodźcie ze Mną!—rzekł do nich. —Uczynię was rybakami ludzi!
Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
18 Oni natychmiast zastawili sieci i poszli z Nim.
Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
19 Nieco dalej zobaczył Jakuba i Jana, synów Zebedeusza, którzy siedzieli w łodzi i naprawiali sieci.
Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe.
20 Ich również zawołał, a oni poszli z Nim, zostawiając ojca i jego pomocników.
Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
21 Razem udali się do miasta Kafarnaum. W szabat weszli do synagogi, a Jezus zaczął nauczać.
Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni.
22 Wszyscy byli zdumieni Jego nauką. Mówił bowiem do nich nie jak ich przywódcy religijni, ale jak ktoś, kto ma władzę nad ludźmi.
Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn.
23 Nagle jakiś człowiek, będący pod wpływem demona, zaczął wykrzykiwać:
Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé,
24 —Dlaczego nas niepokoisz, Jezusie z Nazaretu? Czy przyszedłeś nas zniszczyć? Wiem, kim jesteś! Świętym Synem Boga!
“Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”
25 —Milcz i wyjdź z tego człowieka!—rozkazał Jezus duchowi.
Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.”
26 Zły duch szarpnął nim gwałtownie i z krzykiem go opuścił.
Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.
27 Świadkowie tego zdarzenia oniemieli z wrażenia, a następnie komentowali to, co ujrzeli: —Jaka moc jest w Jego słowach, skoro słuchają Go nawet złe duchy?
Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.”
28 A wiadomość o tym wydarzeniu lotem błyskawicy obiegła Galileę i całą okolicę.
Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.
29 Jezus wyszedł z synagogi i wraz z Jakubem oraz Janem udał się do domu Szymona i Andrzeja.
Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu.
30 Teściowa Szymona miała akurat wysoką gorączkę i leżała w łóżku. Gdy powiedziano o tym Jezusowi,
Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀.
31 On podszedł do chorej, wziął ją za rękę i pomógł jej się podnieść. Temperatura natychmiast spadła, a teściowa wstała i przygotowała im posiłek.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
32 Wieczorem, już po zachodzie słońca, przyprowadzono do Jezusa wielu chorych i zniewolonych przez demony.
Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá.
33 Przed bramą zaś zgromadził się ogromny tłum mieszkańców, ciekawych nadchodzących wydarzeń.
Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà.
34 Jezus uzdrowił wielu chorych i wielu demonom rozkazał opuścić swe ofiary. A ponieważ demony wiedziały, kim On jest, zabronił im cokolwiek mówić.
Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.
35 Następnego dnia wstał jeszcze przed świtem i udał się na pustynię, aby się modlić.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
36 Po jakimś czasie odnalazł Go Szymon i pozostali uczniowie.
Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a.
37 —Wszyscy o Ciebie pytają—mówili.
Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”
38 —Musimy odwiedzić także inne miasta, aby i tam nauczać!—odpowiedział Jezus. —Po to przecież przyszedłem.
Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”
39 Przemierzał więc całą krainę galilejską, przemawiając w synagogach oraz uwalniając wielu ludzi od demonów.
Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.
40 Pewnego razu podszedł do Niego trędowaty i na kolanach błagał o uzdrowienie: —Jeśli tylko zechcesz, możesz mnie uzdrowić—prosił.
Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”
41 Jezus, ogarnięty współczuciem, dotknął go i rzekł: —Chcę. Bądź uzdrowiony!
Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
42 Trąd natychmiast zniknął i w jednej chwili człowiek ten odzyskał zdrowie.
Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.
43 Jezus zaraz go odprawił, surowo przykazując mu:
Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi
44 —Nie mów o tym nikomu. Idź i poproś, aby zbadał cię kapłan. A na dowód tego, że wyzdrowiałeś, zanieś ofiarę, jaką Mojżesz wyznaczył uleczonemu z trądu.
Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”
45 Lecz człowiek ten, idąc, opowiadał wszystkim o swoim cudownym uzdrowieniu. A Jezus, z powodu rozgłosu, nie mógł już swobodnie pokazywać się w miastach—schronił się więc na pustyni. Lecz nawet tam przychodzili do Niego ludzie.
Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.

< Marka 1 >