< مزامیر 9 >
برای رهبر سرایندگان: مزمور داوود، در مایۀ «مرگ پسر». ای خداوند، با تمام وجود تو را میستایم و از کارهای شگفتانگیز تو سخن میرانم. | 1 |
Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
تو شادی و خوشی من هستی و من در وصف تو، ای خدای متعال، میسرایم. | 2 |
Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
دشمنانم عقبنشینی کرده، در حضور تو بر زمین خواهند افتاد و هلاک خواهند شد، | 3 |
Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
زیرا تو ای داور عادل بر مسند خود نشستهای و از حق من دفاع میکنی. | 4 |
Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
تو قومهای شرور را محکوم و نابود کردهای و نام آنها را از صفحهٔ روزگار محو ساختهای. | 5 |
Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
دشمنان ما را به کلی ریشهکن نمودهای و شهرهای آنها را ویران کردهای به طوری که حتی نامی از آنها نیز باقی نمانده است. | 6 |
Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
خداوند تا به ابد پادشاه است. او مسند داوری خود را برقرار کرده | 7 |
Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
تا بر قومهای دنیا با عدل و انصاف داوری نماید. | 8 |
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
خداوند پناهگاه رنجدیدگان است و ایشان را در سختیها حفظ میکند. | 9 |
Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
خداوندا، کسانی که تو را میشناسند، به تو پناه میآورند زیرا تو هرگز طالبان خود را ترک نکردهای. | 10 |
Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
در وصف خداوند که در اورشلیم سلطنت میکند، بسرایید! کارهای او را در میان همهٔ قومها اعلام کنید! | 11 |
Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
زیرا او قاتلان را بیسزا نخواهد گذاشت و فریاد ستمدیدگان را فراموش نخواهد کرد. | 12 |
Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
ای خداوند، ببین دشمنانم چگونه به من ظلم میکنند. بر من رحم کن و مرا از چنگال مرگ رهایی دِه | 13 |
Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
تا تو را در حضور همهٔ مردم اورشلیم ستایش کنم و به سبب این رهایی شادی نمایم. | 14 |
kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
دشمنان در چاهی که برای دیگران کنده بودند، افتادهاند و در دامهایی که برای دیگران گذاشته بودند گرفتار شدهاند. | 15 |
Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
خداوند بدکاران را در دامهای خودشان گرفتار میکند و نشان میدهد که خدای عادلی است. | 16 |
A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
همهٔ بدکاران و تمام قومهایی که خدا را از یاد میبرند هلاک خواهند شد. (Sheol ) | 17 |
Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol )
بیچارگان و ستمدیدگان سرانجام به یاد آورده خواهند شد و امیدشان بر باد نخواهد رفت. | 18 |
Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
برخیز، ای خداوند! نگذار انسان پیروز شود؛ باشد که قومها در حضور تو داوری شوند. | 19 |
Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
آنها را به وحشت انداز تا بفهمند که انسان فانیای بیش نیستند. | 20 |
Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)