< مزامیر 59 >

برای رهبر سرایندگان: در مایۀ «نابود نکن». غزل داوود دربارۀ زمانی که شائول مردانی فرستاد تا خانۀ داوود را کشیک بکشند و او را بکُشند. ای خدای من، مرا از دست دشمنانم برهان؛ مرا از چنگ مخالفانم حفظ کن. 1
Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
مرا از شرّ مردمان گناهکار و خونریز نجات بده. 2
Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
ببین چگونه در کمین من نشسته‌اند. ستمکاران بر ضد من برخاسته‌اند بدون آنکه گناه یا خطایی از من سر زده باشد. 3
Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
کار خلافی مرتکب نشده‌ام، با این حال آنها آماده می‌شوند بر من هجوم آورند. خدایا، برخیز و ببین و به کمکم بیا! 4
Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
ای خداوند، خدای لشکرهای آسمان، ای خدای اسرائیل، برخیز و همهٔ قومها را به سزای اعمالشان برسان؛ بر ستمکاران و گناهکاران رحم نکن. 5
Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
دشمنانم شامگاهان باز می‌گردند و مانند سگ پارس می‌کنند و شهر را دور می‌زنند. 6
Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
فریاد برمی‌آورند و ناسزا می‌گویند؛ زبانشان مانند شمشیر تیز است. گمان می‌برند کسی سخنان توهین‌آمیزشان را نمی‌شنود. 7
Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
اما تو ای خداوند، به آنها خواهی خندید و تمام آن قومها را تمسخر خواهی نمود. 8
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
ای قوت من، چشم امید من بر توست، زیرا پشتیبان من تو هستی. 9
Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
خدای من با محبت خویش پیشاپیش من می‌رود و مرا هدایت می‌کند؛ خداوند به من اجازه خواهد داد شکست دشمنانم را ببینم. 10
Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
ای خداوندی که سپر ما هستی، آنها را یکباره نابود نکن، مبادا مردم این درس عبرت را زود فراموش کنند، بلکه آنها را با قدرت خویش پراکنده و خوار گردان. 11
Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
گناه بر زبان آنهاست؛ تمامی سخنانشان آلوده به شرارت است. باشد که در تکبر خود گرفتار شوند. آنها دشنام می‌دهند و دروغ می‌گویند، 12
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
پس آنها را با خشم خود نابود کن تا نامشان گم شود و مردم بدانند که خدا نه تنها بر اسرائیل، بلکه بر سراسر جهان حکمرانی می‌کند. 13
pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
دشمنانم شامگاهان باز می‌گردند و مانند سگ پارس می‌کنند و شهر را دور می‌زنند. 14
Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
آنها برای خوراک به این سوی و آن سوی می‌دوند و اگر سیر نشوند زوزه می‌کشند. 15
Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
اما من قدرت تو را خواهم سرایید؛ صبحگاهان با شادی در وصف محبت تو سرود خواهم خواند، زیرا در سختیهای روزگار، تو پناهگاه من هستی. 16
Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
ای خدا، ای قوت من، برای تو سرود می‌خوانم. پناهگاه من تویی، ای خدایی که مرا محبت می‌کنی. 17
Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.

< مزامیر 59 >