< لاویان 1 >

خداوند از خیمهٔ ملاقات با موسی سخن گفت و به او فرمود: 1
Olúwa sì pe Mose, ó sì bá a sọ̀rọ̀ láti inú àgọ́ àjọ. Ó wí pé,
«این دستورها را به بنی‌اسرائیل بده. وقتی کسی به خداوند قربانی تقدیم می‌کند، قربانی او باید گاو، گوسفند و یا بز باشد. 2
“Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, kí ọrẹ ẹbọ yín jẹ́ ẹran ọ̀sìn láti inú agbo ẹran tàbí láti inú ọ̀wọ́ ẹran.
اگر بخواهد برای قربانی سوختنی یک گاو قربانی کند، آن گاو باید نر و بی‌عیب باشد. گاو را دم مدخل خیمهٔ ملاقات بیاورد تا مورد قبول خداوند قرار گیرد. 3
“‘Bí ọrẹ ẹbọ náà bá jẹ́ ẹbọ sísun láti inú agbo ẹran kí òun kí ó mú akọ màlúù tí kò lábùkù. Ó sì gbọdọ̀ mú un wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà níwájú Olúwa
شخصی که آن را می‌آورد، باید دستش را روی سر حیوان بگذارد. به این ترتیب آن قربانی پذیرفته شده، گناهان شخص را کفاره می‌کند. 4
kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé orí ẹbọ sísun náà yóò sì jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà dípò o rẹ̀, yóò sì jẹ́ ètùtù fún un.
بعد خود آن شخص حیوان را در حضور خداوند سر ببرد و پسران هارون که کاهنند، خون آن را بیاورند و بر چهار طرف مذبح که جلوی مدخل خیمهٔ ملاقات است، بپاشند. 5
Kí ó pa ọ̀dọ́ akọ màlúù náà níwájú Olúwa, lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà tí í ṣe ọmọ Aaroni yóò gbé ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà yí pẹpẹ tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ ká.
سپس آن شخص پوست گاو را بکند و آن را قطعه‌قطعه کند، 6
Òun yóò bó awọ ara ẹbọ sísun náà, òun yóò sì gé e sí wẹ́wẹ́.
و کاهنان هیزم روی مذبح بگذارند، آتش روشن کنند 7
Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò fi iná sí orí pẹpẹ, wọn yóò sì to igi sórí pẹpẹ náà.
و قطعه‌ها و سر و چربی آن را روی هیزم قرار دهند. 8
Lẹ́yìn náà ni àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà yóò tó ègé ẹran náà, pẹ̀lú orí àti ọ̀rá rẹ̀ sí orí igi tó ń jó lórí pẹpẹ.
آنگاه آن شخص باید دل و روده و پاچه‌های گاو را با آب بشوید و کاهنان همه را روی مذبح بسوزانند. این قربانی سوختنی، هدیه‌ای خوشبو و مخصوص برای خداوند خواهد بود. 9
Kí ó fi omi sàn nǹkan inú àti àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀, kí àlùfáà sì sun gbogbo rẹ̀ lórí pẹpẹ, ó jẹ́ ọrẹ ẹbọ sísun, ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
«اگر گوسفند یا بز برای قربانی بیاورند، آن نیز باید نر و بی‌عیب باشد. 10
“‘Bí ọrẹ ẹbọ náà bá jẹ́ ẹbọ sísun láti inú ọ̀wọ́ ẹran, láti ara àwọn àgùntàn tàbí ewúrẹ́ tàbí àgùntàn, kí ó mú akọ tí kò lábùkù,
شخصی که آن را می‌آورد باید در سمت شمالی مذبح در حضور خداوند سرش را ببرد و کاهنان که پسران هارونند، خونش را بر چهار طرف مذبح بپاشند. 11
kí ó pa á ní apá àríwá pẹpẹ níwájú Olúwa, kí àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí gbogbo ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ náà ká.
سپس، آن شخص حیوان قربانی شده را قطعه‌قطعه کند و کاهنان این قطعه‌ها را با سر و چربی آن روی هیزم مذبح بگذارند. 12
Kí ó gé e sí wẹ́wẹ́, kí àlùfáà sì to ègé ẹran náà; orí àti ọ̀rá rẹ̀ sí orí igi tó ń jó lórí pẹpẹ.
آن شخص باید دل و روده و پاچه‌های گوسفند یا بز را با آب بشوید. سپس کاهنان همهٔ آنها را روی آتش مذبح بسوزانند. این قربانی سوختنی، هدیه‌ای مخصوص و خوشبو برای خداوند خواهد بود. 13
Kí ó fi omi ṣan nǹkan inú àti àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀, kí àlùfáà sì gbé gbogbo rẹ̀ wá láti sun lórí pẹpẹ. Ó jẹ́ ẹbọ sísun tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
«اگر کسی می‌خواهد برای قربانی سوختنی پرنده برای خداوند قربانی کند، آن پرنده باید قمری یا جوجه کبوتر باشد. 14
“‘Bí ó bá sì ṣe pé ti ẹyẹ ni ẹbọ sísun ọrẹ ẹbọ rẹ̀ sí Olúwa, ǹjẹ́ kí ó mú ọrẹ ẹbọ rẹ̀ wá nínú àdàbà tàbí ọmọ ẹyẹlé.
کاهن، پرنده را بگیرد و جلوی مذبح سرش را بپیچاند و آن را بر مذبح بسوزاند. اما اول باید خونش را بر پهلوی مذبح بچلاند. 15
Kí àlùfáà mu wá sí ibi pẹpẹ, kí ó yín in lọ́rùn, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ, kí ó sì ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ.
چینه‌دان و محتویات داخل شکمش را درآورد و آنها را در طرف شرق مذبح در جایی که خاکستر مذبح ریخته می‌شود بیندازد. 16
Kí ó yọ àjẹsí ẹyẹ náà pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀, kí ó gbe lọ ṣí apá ìlà-oòrùn pẹpẹ níbi tí eérú wà.
سپس بالهای پرنده را گرفته، آن را از وسط پاره کند بدون اینکه پرنده دو تکه شود. آنگاه کاهن آن را روی هیزم مذبح بسوزاند. این قربانی سوختنی، هدیه‌ای مخصوص و خوشبو برای خداوند خواهد بود. 17
Kí ó gbá apá rẹ̀ méjèèjì mú, kí ó fà á ya, ṣùgbọ́n kí ó má ya á tan pátápátá. Lẹ́yìn náà ni àlùfáà yóò sun ún lórí igi tí ó ń jó lórí pẹpẹ, ẹbọ sísun ni ọrẹ tí a fi iná ṣe, àní òórùn dídùn sí Olúwa.

< لاویان 1 >