< ارمیا 7 >
آنگاه خداوند به ارمیا فرمود | 1 |
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
که کنار دروازهٔ خانهٔ خداوند بایستد و این پیام را به گوش مردم برساند: ای مردم یهودا، ای تمام کسانی که در اینجا خداوند را عبادت میکنید، به کلام خداوند گوش فرا دهید! | 2 |
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
خداوند لشکرهای آسمان، خدای قوم اسرائیل میفرماید: «اگر راهها و اعمالتان را تغییر داده، اصلاح کنید، اجازه خواهم داد در سرزمین خود باقی بمانید. | 3 |
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
فریب سخنان دروغ را نخورید، فکر نکنید که چون خانهٔ من در اینجاست نخواهم گذاشت که اورشلیم ویران شود. | 4 |
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
من فقط در صورتی اجازه خواهم داد در این سرزمینی که جاودانه به پدرانتان دادهام باقی بمانید که از کردار و رفتار بد دست کشیده، با یکدیگر با درستی و انصاف رفتار کنید، از یتیمان، بیوهزنان و غریبان بهرهکشی نکنید، از ریختن خون بیگناهان دست بردارید و از پیروی خدایان دیگر که باعث زیان و لطمهٔ شماست روی گردان شوید. | 5 |
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
«اما شما به سخنان دروغ و بیپایه امید بستهاید؛ | 8 |
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
دزدی میکنید، مرتکب زنا و قتل میشوید، به دروغ قسم میخورید، برای بت بعل بخور میسوزانید و خدایان بیگانه را میپرستید، | 9 |
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
و بعد به خانهای که به نام من نامیده شده آمده، در حضور من میایستید و میگویید:”ما در امن و امانیم!“و باز برمیگردید و غرق کارهای زشتتان میشوید. | 10 |
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
مگر خانهای که نام مرا بر خود دارد، آشیانهٔ دزدان است؟ هر آنچه در آنجا میکنید، میبینم. | 11 |
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
«به شیلوه بروید، به شهری که نخستین عبادتگاه من در آن قرار داشت، و ببینید به سبب گناهان قومم اسرائیل، با آن چه کردم! | 12 |
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
به سبب تمام گناهانی که مرتکب شدهاید همان بلا را بر سر شما نیز خواهم آورد. با اینکه بارها در این مورد با شما سخن گفته، هشدار دادم و شما را فرا خواندم، ولی شما نه گوش کردید و نه جواب دادید. پس همانطور که اجازه دادم خانهٔ مرا در شیلوه خراب کنند، اجازه خواهم داد تا این خانه را نیز خراب کنند. بله، این خانه را که به نام من بوده و چشم امیدتان به آن است و این سرزمین را که به شما و به پدرانتان دادهام، ویران خواهم کرد؛ | 13 |
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
همانطور که برادران افرایمی شما را تبعید نمودم، شما را نیز تبعید خواهم کرد. | 15 |
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
«پس تو ای ارمیا، دیگر برای این قوم دعای خیر نکن و برای آنها گریه و زاری و شفاعت ننما، چون نخواهم پذیرفت. | 16 |
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
مگر نمیبینی در تمام شهرهای یهودا و در کوچههای اورشلیم چه میکنند؟ | 17 |
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
ببین چطور بچهها هیزم جمع میکنند، پدرها آتش میافروزند، زنها خمیر درست میکنند تا برای بت”ملکۀ آسمان“گردههای نان بپزند و برای سایر خدایانشان هدایای نوشیدنی تقدیم کنند و به این ترتیب مرا به خشم آورند! | 18 |
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
آیا این کارها، به من لطمه میزنند؟ بیشتر از همه به خودشان ضرر میرسانند و خودشان را رسوا میکنند. | 19 |
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
پس من آتش خشم و غضب خود را فرو خواهم ریخت. بله، شعلههای خشم و غضب من، این عبادتگاه را سوزانده، مردم، حیوانات، درختان و محصولات زمین را از میان خواهد برد و کسی نخواهد توانست آن را خاموش کند!» | 20 |
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
خداوند لشکرهای آسمان، خدای اسرائیل میفرماید: «گوشت قربانیهایی را که ذبح میکنید چه آنهایی را که مجاز به خوردنشان هستید، چه آنهایی که خوردنشان ممنوع است، همه را بخورید، | 21 |
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
چون وقتی پدران شما را از مصر بیرون آوردم، و با ایشان سخن گفته، دستورهای خود را به ایشان دادم از ایشان هدیه و قربانی نخواستم، | 22 |
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
بلکه آنچه به ایشان فرموده بودم این بود: از من پیروی کنید تا من خدای شما باشم و شما قوم من! فقط به هر راهی که من میگویم، بروید تا سعادتمند شوید. | 23 |
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
ولی ایشان گوش فرا ندادند و توجهی ننمودند، بلکه به دنبال هوس دل خود رفتند و به جای پیشرفت و بهتر شدن، وضعشان بدتر شد. | 24 |
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
از روزی که پدران شما از مصر بیرون آمدند تا به امروز، خادمین یعنی انبیای خود را هر روز نزد شما فرستادم. | 25 |
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
ولی نه به سخنانشان گوش دادید و نه به ایشان اعتنایی کردید، بلکه سختدل و یاغی شده بدتر از پدرانتان رفتار نمودید. | 26 |
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
«بنابراین ای ارمیا، هر آنچه میفرمایم به ایشان بگو، ولی انتظار نداشته باش گوش بدهند! به ایشان هشدار بده، ولی منتظر پاسخی نباش. | 27 |
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
بگو که ایشان قومی هستند که نمیخواهند دستورهای خداوند، خدای خود را اطاعت کنند و نمیخواهند درس عبرت بگیرند، چون راستی از بین رفته و سخنی نیز از آن به میان نمیآید.» | 28 |
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
خداوند میفرماید: «ای اهالی اورشلیم، عزاداری کنید؛ موی خود را به نشانهٔ شرم تراشیده، دور بریزید؛ بر بلندیها برآیید و نوحهسرایی کنید، چون من از شما خشمگین هستم و شما را طرد کرده و ترک نمودهام. | 29 |
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
اهالی یهودا در برابر چشمان من شرارت ورزیدهاند و بتهای خود را به خانهٔ من آورده و آنجا را نجس ساختهاند. | 30 |
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
در وادی”ابن هنوم“نیز مذبحی به نام”توفت“بنا نمودهاند و در آنجا پسران و دختران خود را برای بتها زندهزنده در آتش، قربانی میکنند کار زشت و هولناکی که نه امر فرموده بودم و نه حتی از خاطرم گذشته بود. | 31 |
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
بنابراین روزی خواهد رسید که دیگر به آنجا”توفت“یا وادی”ابن هنوم“نخواهند گفت، بلکه آن را”وادی کشتارگاه“خواهند نامید، چون اجساد بیشماری از کشتهشدگان را در آنجا دفن خواهند کرد، طوری که جایی باقی نماند؛ | 32 |
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
و لاشههای قوم من خوراک پرندگان آسمان و حیوانات بیابان خواهند شد و کسی باقی نخواهد ماند که آنها را براند. | 33 |
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
من آوای سرود و شادمانی و هلهلهٔ عروس و داماد را از شهرهای یهودا و کوچههای اورشلیم قطع خواهم نمود و این سرزمین را به ویرانه مبدل خواهم ساخت.» | 34 |
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.