< ارمیا 5 >

خداوند می‌فرماید: «تمام کوچه‌های اورشلیم را بگردید. بر سر چهارراه‌ها بایستید. همه جا را خوب جستجو کنید! اگر بتوانید حتی یک شخص با انصاف و درستکار پیدا کنید، من این شهر را از بین نخواهم برد! 1
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
این قوم حتی به نام من قسم می‌خورند!» 2
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
ای خداوند، تو به یک چیز اهمیت می‌دهی و آن راستی و درستی است. تو سعی کردی ایشان را اصلاح کنی، اما آنها نخواستند؛ هر چند ایشان را زدی، ولی دردی احساس نکردند! روی خود را از سنگ هم سختتر کرده‌اند و نمی‌خواهند توبه کنند. 3
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
آنگاه گفتم: «از اشخاص فقیر و نادان چه انتظاری می‌شود داشت؟ آنها از راهها و فرمانهای خدا چیزی نمی‌فهمند! پس چطور می‌توانند دستورهای او را اطاعت کنند؟ 4
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
بنابراین نزد رهبران ایشان رفته و با آنها وارد گفتگو خواهم شد، زیرا آنها راههای خداوند و دستورهای او را می‌دانند.» ولی دیدم که ایشان هم از پیروی خدا برگشته و علیه او سر به طغیان برداشته‌اند. 5
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
به همین دلیل شیرهای درندهٔ جنگل به جان ایشان خواهند افتاد، گرگهای بیابان به ایشان حمله خواهند کرد و پلنگها در اطراف شهرهایشان کمین خواهند کرد تا هر کس را که بیرون برود، پاره‌پاره کنند؛ زیرا گناهانشان از حد گذشته و بارها از خدا روی برگردانده‌اند. 6
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
خداوند می‌گوید: «دیگر چگونه می‌توانم شما را ببخشم؟ چون حتی فرزندانتان مرا ترک گفته‌اند و آنچه را که خدا نیست می‌پرستند. من خوراک به آنها دادم تا سیر بشوند، ولی به جای تشکر، غرق زناکاری شدند و وقت خود را با فاحشه‌ها تلف کردند. 7
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
آنها مثل اسبان سیر و سرحالی هستند که برای جفت مادهٔ همسایهٔ خود شیهه می‌کشند. 8
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
آیا برای این کارهای شرم‌آور تنبیه‌شان نکنم؟ آیا نباید از چنین قومی انتقام بگیرم؟ 9
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
«پس ای دشمنان به تاکستان‌هایشان هجوم ببرید و خرابشان کنید! ولی به کلی نابود نکنید. شاخه‌هایشان را قطع کنید، چون از آن خداوند نیستند. 10
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
خداوند می‌فرماید: مردم اسرائیل و مردم یهودا به من خیانت بزرگی کرده‌اند؛ 11
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
آنها دربارۀ من به دروغ گفته‌اند:”او با ما کاری ندارد! هیچ بلایی بر سر ما نخواهد آمد. نه قحطی خواهد شد و نه جنگ. 12
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
انبیا، همگی طبلهای توخالی هستند و کلام خدا در دهان هیچ‌یک از ایشان نیست؛ بلایی که ما را از آن می‌ترسانند، بر سر خودشان خواهد آمد!“» 13
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
از این رو خداوند، خدای لشکرهای آسمان، به من چنین فرمود: «برای این گونه سخنان است که من کلام خود را در دهان تو ای ارمیا، مانند آتش می‌سازم و این قوم را همانند هیزم می‌گردانم تا ایشان را بسوزاند.» 14
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
خداوند می‌فرماید: «ای بنی‌اسرائیل، من قومی را از دور دست بر ضد تو خواهم فرستاد، قومی نیرومند و قدیمی که زبانشان را نمی‌فهمی. 15
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
کمانداران آنها همه جنگجویانی نیرومندند که بدون ترحم می‌کشند. 16
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
آنها خرمن تو را غارت کرده، نان فرزندانت را خواهند برد؛ گله‌های گوسفند و رمه‌های گاو، انگور و انجیر تو را به یغما برده، شهرهای حصاردارت را که خیال می‌کنی در امن و امانند، تاراج خواهند کرد. 17
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
اما در آن زمان هم باز شما را به کلی از میان نخواهم برد. 18
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
«پس اگر از تو ای ارمیا بپرسند: چرا خداوند ما را دچار این بلایا می‌کند؟ در پاسخ بگو: همان‌طور که شما خدا را فراموش کردید و در سرزمین خود خدایان بیگانه را پرستیدید، به همان ترتیب بیگانگان را در سرزمینی که از آن شما نیست خدمت و بردگی خواهید کرد.» 19
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
خداوند می‌فرماید که به اهالی یهودا و به قوم اسرائیل چنین اعلام نمایید: 20
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
«ای قوم نادان و بی‌فهم که چشم دارید، ولی نمی‌بینید؛ گوش دارید، ولی نمی‌شنوید، این را بشنوید: 21
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
آیا نباید به من احترام بگذارید؟ آیا نباید در حضور من، ترس وجودتان را فرا گیرد؟ من که شن را به عنوان قانونی جاودانی، سرحد دریاها قرار دادم؛ اگرچه دریاها خروش برآورند و امواجشان به تلاطم آیند، از این حد نمی‌توانند بگذرند!» 22
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
خداوند می‌فرماید: «قوم من دلی سرکش و طغیانگر دارند. ایشان یاغی شده و مرا ترک گفته‌اند، و هیچگاه حرمت مرا نگاه نداشته‌اند، هر چند من باران را در بهار و پاییز به ایشان عطا کردم، و فصل کشت و برداشت محصول را برای آنان تعیین نمودم. 23
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
برای همین است که این برکات نیکو را از ایشان گرفته‌ام؛ گناه، ایشان را از تمام این بخشش‌ها محروم کرده است. 25
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
«در میان قوم من اشخاص بدکاری وجود دارند که همچون شکارچیانی که برای شکار کمین می‌گذارند، ایشان هم برای انسان دام می‌گذارند. 26
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
همان‌طور که شکارچی قفس خود را پر از پرنده می‌کند، ایشان نیز خانه‌های خود را از نقشه‌های فریبکارانه و غارتگرانه پرکرده‌اند، به همین دلیل است که اکنون قدرتمند و ثروتمند هستند. 27
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
خوب می‌خورند و خوب می‌پوشند و رفتار بدشان حد و اندازه‌ای ندارد؛ نه به داد یتیمان می‌رسند و نه حق فقیران را به آنها می‌دهند. 28
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
بنابراین من ایشان را مجازات خواهم کرد و از چنین قومی انتقام خواهم گرفت! 29
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
«اتفاق عجیب و هولناکی در این سرزمین روی داده است: 30
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
انبیا پیامهای دروغین می‌دهند و کاهنان نیز بنا بر گفتهٔ ایشان عمل می‌نمایند، قوم من هم از این وضع راضی‌اند. اما بدانید که چیزی به نابودی شما نمانده است؛ آنگاه چه خواهید کرد؟» 31
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< ارمیا 5 >