< ارمیا 3 >

خداوند می‌فرماید: «اگر مردی زن خود را طلاق بدهد و زن از او جدا شده، همسر مردی دیگر شود، آن مرد دیگر او را به همسری نخواهد گرفت، چون چنین کاری سبب فساد آن سرزمین خواهد شد. ولی تو، هر چند مرا ترک کردی و به من خیانت ورزیدی، با وجود این از تو می‌خواهم که نزد من بازگردی. 1
“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
آیا در سراسر این سرزمین جایی پیدا می‌شود که با زنای خود، یعنی پرستش بتها، آن را آلوده نکرده باشی؟ مانند فاحشه، بر سر راه به انتظار فاسق می‌نشینی، درست مثل عرب بادیه‌نشین که در کمین رهگذر می‌نشیند. تو با کارهای شرم‌آور خود زمین را آلوده کرده‌ای! 2
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
برای همین است که نه رگبار می‌بارد و نه باران بهاری، چون تو مانند یک روسپی شرم و حیا را از خود دور کرده‌ای. 3
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
با این حال به من می‌گویی: ای پدر، از زمان کودکی تو مرا دوست داشته‌ای؛ پس تا ابد بر من خشمگین نخواهی ماند! این را می‌گویی و هر کار زشتی که از دستت برآید، انجام می‌دهی.» 4
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
5
Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
در زمان سلطنت یوشیای پادشاه، خداوند به من فرمود: «می‌بینی اسرائیل خیانتکار چه می‌کند؟ مثل یک زن هرزه که در هر فرصتی خود را در اختیار مردان دیگر قرار می‌دهد، اسرائیل هم روی هر تپه و زیر هر درخت سبز، بت می‌پرستد. 6
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
من فکر می‌کردم روزی نزد من باز خواهد گشت و بار دیگر از آن من خواهد شد، اما چنین نشد. خواهر خیانت پیشهٔ او، یهودا هم یاغیگری‌های دائمی اسرائیل را دید. 7
Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
با اینکه یهودا دید که من اسرائیل بی‌وفا را طلاق داده‌ام، نترسید و اینک او نیز مرا ترک کرده، تن به روسپی‌گری داده و به سوی بت‌پرستی رفته است. 8
Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
او با بی‌پروایی بتهای سنگی و چوبی را پرستیده، زمین را آلوده می‌سازد؛ با این حال این گناهان در نظر او بی‌اهمیت جلوه می‌کند. 9
Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
یهودا، این خواهر خیانت‌پیشه، هنگامی نیز که نزد من بازگشت، توبه‌اش ظاهری بود نه از صمیم قلب. 10
Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
در واقع گناه اسرائیل بی‌وفا سبکتر از گناه یهودای خائن است!» 11
Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
همچنین خداوند به من گفت که بروم و به اسرائیل بگویم: «ای قوم گناهکار من، نزد من برگرد، چون من باگذشت و دلسوزم و تا ابد از تو خشمگین نمی‌مانم. 12
Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
به گناهانت اقرار کن! بپذیر که نسبت به خداوند، خدای خود سرکش شده‌ای و با پرستش بتها در زیر هر درختی، مرتکب زنا گشته‌ای؛ اعتراف کن که نخواستی مرا پیروی کنی. 13
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
ای فرزندان خطاکار، به سوی من بازگردید، چون من سرور شما هستم و شما را در هر جا که باشید بار دیگر به صَهیون باز می‌گردانم 14
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
و رهبرانی بر شما می‌گمارم که مورد پسند من باشند تا از روی فهم و حکمت، شما را رهبری کنند!» 15
Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
خداوند می‌فرماید: «وقتی بار دیگر سرزمین شما از جمعیت پر شود، دیگر حسرت دوران گذشته را نخواهید خورد، دورانی که صندوق عهد خداوند در اختیارتان بود؛ دیگر کسی از آن روزها یاد نخواهد کرد و صندوق عهد خداوند دوباره ساخته نخواهد شد. 16
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
در آن زمان شهر اورشلیم به”محل سلطنت خداوند“مشهور خواهد شد و تمام قومها در آنجا به حضور خداوند خواهند آمد و دیگر سرکشی نخواهند نمود و به دنبال خواسته‌های ناپاکشان نخواهند رفت. 17
Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
در آن هنگام اهالی یهودا و اسرائیل با هم از تبعید شمال بازگشته، به سرزمینی خواهند آمد که من به اجدادشان به ارث دادم. 18
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
«مایل بودم در اینجا با فرزندانم ساکن شوم؛ در نظر داشتم این سرزمین حاصلخیز را که در دنیا بی‌همتاست، به شما بدهم؛ انتظار داشتم مرا”پدر“صدا کنید و هیچ فکر نمی‌کردم که بار دیگر از من روی بگردانید؛ 19
“Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
اما شما به من خیانت کردید و از من دور شده، به بتهای بیگانه دل بستید. شما مانند زن بی‌وفایی هستید که شوهرش را ترک کرده باشد.» 20
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
از کوهها صدای گریه و زاری شنیده می‌شود؛ این صدای گریۀ بنی‌اسرائیل است که از خدا روی گردانده و سرگردان شده‌اند! 21
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
ای فرزندان ناخلف و سرکش نزد خدا بازگردید تا شما را از بی‌ایمانی شفا دهد. ایشان می‌گویند: «البته که می‌آییم، چون تو خداوند، خدای ما هستی. 22
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
ما از بت‌پرستی بر بالای تپه‌ها و عیاشی بر روی کوهها خسته شده‌ایم؛ این کارها بیهوده است؛ بنی‌اسرائیل تنها در پناه خداوند، خدای ما می‌تواند نجات یابد. 23
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
از کودکی با چشمان خود دیدیم که چگونه دسترنج پدرانمان، از گله‌ها و رمه‌ها و پسران و دختران، در اثر بت‌پرستی شرم‌آورشان بلعیده شد! 24
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
هم ما و هم پدرانمان از کودکی نسبت به خداوند، خدایمان گناه کرده‌ایم و دستورهای او را پیروی ننموده‌ایم؛ پس بگذار در شرمساری‌مان غرق شویم! بگذار رسوایی، ما را فرا گیرد!» 25
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

< ارمیا 3 >