< اشعیا 8 >
خداوند به من فرمود که لوحی بزرگ بگیرم و با خط درشت روی آن بنویسم: «مهیر شلال حاش بز» | 1 |
Olúwa sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi kálàmù ìkọ̀wé lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
من از اوریای کاهن و زکریا (پسر یبرکیا) که مردانی امین هستند خواستم هنگام نوشتن حاضر باشند و شهادت دهند که من آن را نوشتهام. | 2 |
Èmi yóò sì mú Uriah àlùfáà àti Sekariah ọmọ Jeberekiah gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí òtítọ́ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
پس از چندی، همسرم حامله شد و هنگامی که پسرمان به دنیا آمد خداوند فرمود: «نام او را مهیر شلال حاش بز بگذار. | 3 |
Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Olúwa sì wí fún mi pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Basi.
پیش از آنکه این پسر بتواند”پدر“و”مادر“بگوید، پادشاه آشور به دمشق و سامره یورش خواهد برد و اموال آنها را غارت خواهد کرد.» | 4 |
Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé, ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi,’ gbogbo ọrọ̀ Damasku àti ìkógun ti Samaria ni ọba àwọn Asiria yóò ti kó lọ.”
پس از آن، باز خداوند به من فرمود: | 5 |
Olúwa sì tún sọ fún mi pé,
«حال که مردم یهودا آبهای ملایم نهر شیلوه را خوار میشمارند و دلشان با رصین پادشاه و فقح پادشاه خوش است، | 6 |
“Nítorí pé àwọn ènìyàn yìí ti kọ omi Ṣiloa tí ń sàn jẹ́ẹ́jẹ́ sílẹ̀ tí wọ́n sì ń yọ̀ nínú Resini àti ọmọ Remaliah,
من سیلابی نیرومند از رود فرات، یعنی پادشاه آشور را با تمامی شکوهش، بر آنها خواهم آورد. این سیلاب بر تمامی آبراههای خود طغیان کرده، | 7 |
ǹjẹ́ nítorí náà kíyèsi i, Olúwa ń fa omi odò tí ó le, tí ó sì pọ̀ wá sórí wọn, àní, ọba Asiria àti gbogbo ògo rẹ̀, yóò sì wá sórí gbogbo ọ̀nà odò rẹ̀, yóò sì gun orí gbogbo bèbè rẹ̀,
به سوی یهودا پیش خواهد رفت و آن را تا به گردن خواهد پوشاند؛ و بالهایش را باز کرده، سرتاسر سرزمین تو را، ای عِمانوئیل، پر خواهد ساخت.» | 8 |
yóò sì gbá àárín Juda kọjá, yóò sì ṣàn bò ó mọ́lẹ̀, yóò sì mú un dọ́rùn. Nínà ìyẹ́ apá rẹ̀ yóò sì bo gbogbo ìbú ilẹ̀ rẹ̀, ìwọ Emmanueli.”
ای قومها هر کاری از دستتان برمیآید بکنید، ولی بدانید که موفق نخواهید شد و شکست خواهید خورد. ای همهٔ دشمنان گوش دهید: برای جنگ آماده شوید، ولی بدانید که پیروز نخواهید شد. | 9 |
Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ ọ yín túútúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jíjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúú!
با هم مشورت کنید و نقشهٔ حمله را بکشید، اما بدانید که نقشهٔ شما عملی نخواهد شد، زیرا خدا با ما است! | 10 |
Ẹ gbìmọ̀ pọ̀, yóò sì di asán, ẹ gbèrò ọ̀rọ̀ náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa.
خداوند به تأکید به من امر کرد که راه مردم یهودا را در پیش نگیرم، و فرمود: | 11 |
Olúwa bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ o ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé,
«هر آنچه این قوم توطئه مینامند، شما نپذیرید، و از آنچه میترسند شما از آن بیم و هراس نداشته باشید. | 12 |
“Má ṣe pe èyí ní ọ̀tẹ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn yìí pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.
بدانید که خداوند لشکرهای آسمان، مقدّس است و تنها از او باید بترسید. | 13 |
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,
او برای شما پناهگاه است. اما برای یهودا و اسرائیل سنگی خواهد بود که سبب لغزش شود و صخرهای که باعث سقوط گردد. او برای ساکنان اورشلیم دامی پنهان خواهد بود. | 14 |
Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Israẹli méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọsẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ni yóò jẹ́ tàkúté àti ìdẹ̀kùn.
بسیاری از آنان لغزیده، خواهند افتاد و خرد خواهند شد و بسیاری دیگر در دام افتاده، گرفتار خواهند گردید.» | 15 |
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọsẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”
ای شاگردان من، شما باید کلام و دستورهایی را که خدا به من داده است مهر و موم کرده، حفظ کنید. | 16 |
Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.
من منتظرم تا خداوند ما را یاری کند، هر چند اکنون خود را از قوم خویش پنهان کرده است. بر او امیدوار خواهم بود. | 17 |
Èmi yóò dúró de Olúwa, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jakọbu. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.
من و فرزندانی که خداوند به من داده است، از طرف خداوند لشکرهای آسمان که در اورشلیم ساکن است برای اسرائیل علامت و نشانه هستیم. | 18 |
Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí Olúwa fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Israẹli láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òkè Sioni.
وقتی مردم به شما میگویند که با فالگیران و جادوگرانی که زیر لب ورد میخوانند مشورت کنید، شما در جواب بگویید: «آیا از مردگان دربارهٔ زندگان مشورت بخواهیم؟ چرا از خدای خود مشورت نخواهیم؟» | 19 |
Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókùúsọ̀rọ̀ àti àwọn oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?
مردم موافق کلام و دستورهای خدا سخن نمیگویند و کلامشان عاری از نور حقیقت است. | 20 |
Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò rí ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.
ایشان در تنگی و گرسنگی قرار خواهند گرفت و آواره خواهند شد. از شدت گرسنگی و پریشانی پادشاه و خدای خود را نفرین خواهند کرد. به آسمان خواهند نگریست | 21 |
Nínú ìnilára àti ebi, ni wọn yóò máa kọjá lọ láàrín ilẹ̀ náà, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni wọn yóò máa kanra, wọn yóò wòkè, wọn yóò sì fi ọba àti Ọlọ́run wọn ré.
و به زمین نگاه خواهند کرد، ولی چیزی جز تنگی و پریشانی و تاریکی نخواهند دید، و به سوی تاریکی محض رانده خواهند شد. | 22 |
Nígbà náà ni wọn yóò sì wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúru tí ó ba ni lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.