< اشعیا 60 >
ای اورشلیم برخیز و بگذار نور تو بدرخشد، زیرا جلال خداوند بر تو تابان است! | 1 |
“Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
تمام قومهای جهان در تاریکی فرو خواهند رفت، اما نور جلال خداوند بر تو خواهد تابید، | 2 |
Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́ ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
و پادشاهان و قومها به سوی تو خواهند آمد تا نور جلال خداوند را که بر تو تابان است مشاهده کنند. | 3 |
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ, àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.
به اطراف خود نگاه کن و ببین چگونه قوم تو جمع شده به سوی تو میآیند. ایشان پسران و دخترانت را در آغوش گرفته، از راه دور به وطن باز میگردند. | 4 |
“Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò. Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
تو این را به چشم خواهی دید و شاد خواهی شد و از شدت هیجان خواهی لرزید. گنجهای جهان از راه دریا به سوی تو خواهد آمد و ثروت قومها نزد تو جمع خواهد شد. | 5 |
Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán, ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀; ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ, sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
کاروانهای شتر از مِدیان و عیفه و صبا خواهند آمد و با خود طلا و بخور خواهند آورد. مردم خداوند را ستایش خواهند کرد و کارهای او را بشارت خواهند داد. | 6 |
Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani. Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá, wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́ tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
تمام گلههای قیدار و نبایوت را نزد تو خواهند آورد تا بر مذبح خانهٔ خداوند قربانی کنند. در آن روز خداوند خانهٔ پرشکوه خود را زینت خواهد داد. | 7 |
Gbogbo agbo ẹran ìlú Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ, àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́; wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi, bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.
اینها کیستند که مانند ابر به سوی سرزمین اسرائیل در حرکتند؟ ایشان به کبوترهایی میمانند که به لانههای خود باز میگردند. | 8 |
“Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru, gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
اینها قوم خدا هستند که سوار بر کشتی از سرزمینهای دور دست به وطن باز میگردند و با خود طلا و نقره میآورند، زیرا خدای مقدّس اسرائیل که در تمام دنیا مشهور است، قوم خود را در نظر همهٔ قومها عزت و احترام بخشیده است. | 9 |
Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí; ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn, pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn, fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.
خداوند به اورشلیم میگوید: «بیگانگان آمده، دیوارهای تو را بازسازی خواهند کرد و پادشاهان آنها تو را خدمت خواهند نمود، زیرا هر چند در خشم خود تو را مجازات کردم، اما به لطف خویش بر تو رحم خواهم کرد. | 10 |
“Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́, ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
روز و شب، دروازههایت باز خواهد بود تا پادشاهان جهان ثروت کشورهای خود را نزد تو بیاورند. | 11 |
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀, a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
هر قومی که نخواهد تو را خدمت کند، هلاک شده، از بین خواهد رفت. | 12 |
Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun; pátápátá ni yóò sì dahoro.
«از جنگل لبنان چوبهای درختان صنوبر و کاج و چنار را برای تو ای اورشلیم خواهند آورد تا تو را بازسازی کنند و خانهٔ مرا تزئین نمایند و شهر مرا باشکوه سازند. | 13 |
“Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀, láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi; àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
پسران کسانی که بر تو ظلم کردهاند خواهند آمد و در مقابل تو زانو زده، تعظیم خواهند کرد و کسانی که تو را تحقیر کردهاند بر پاهایت خواهند افتاد و تو را سجده خواهند کرد. آنها تو را شهر خداوند و صَهیون قدوس اسرائیل خواهند نامید. | 14 |
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò wá foríbalẹ̀ fún ọ; gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
«تو زمانی متروک و مطرود بودی و کسی از تو عبور نمیکرد، اما اینک تو را برای همیشه باشکوه میسازم و تو تا ابد محل شادمانی خواهی بود. | 15 |
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá, Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé àti ayọ̀ àtìrandíran.
قومها و پادشاهان جهان نیازهای تو را برآورده خواهند ساخت و مانند یک مادر از تو مراقبت خواهند نمود. آنگاه خواهی فهمید که من یهوه خدای قادر اسرائیل، حامی و نجاتدهندۀ تو هستم. | 16 |
Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
«من مفرغ تو را به طلا تبدیل میکنم و آهن تو را به نقره، چوب تو را به مفرغ، و سنگ تو را به آهن. رهبران و حاکمانی به تو خواهم داد که با صلح و عدالت بر تو حکومت کنند. | 17 |
Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ, dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ, àti irin dípò òkúta. Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
ظلم و خرابی را از تو دور خواهم کرد و مانند دیواری محافظ، تو را احاطه خواهم نمود و تو مرا سپاس خواهی گفت چرا که تو را نجات دادهام. | 18 |
A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́, tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
«تو دیگر به روشنایی خورشید و ماه احتیاج نخواهی داشت، زیرا من که خداوند هستم نور جاودانی تو و زیبایی تو خواهم بود. | 19 |
Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́, tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́, nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé, àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
آفتاب تو هرگز غروب نخواهد کرد و ماه تو زوال نخواهد پذیرفت، زیرا من نور جاودانی تو خواهم بود، و روزهای سوگواریت پایان خواهند یافت. | 20 |
Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́, àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́; Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ, àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
همهٔ افراد قوم تو مردمانی درستکار خواهند بود و سرزمین خود را تا ابد حفظ خواهند کرد. من ایشان را با دستان خود در آنجا خواهم کاشت تا عظمت و جلال خود را ظاهر کنم. | 21 |
Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé. Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, láti fi ọláńlá mi hàn.
حتی کوچکترین و ضعیفترین خاندان تو بزرگ شده، به قومی نیرومند تبدیل خواهد شد. هنگامی که زمان معین فرا رسد من که یهوه هستم این را بیدرنگ انجام خواهم داد.» | 22 |
Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan, èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá. Èmi ni Olúwa; ní àkókò rẹ̀, Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”