< اشعیا 51 >
خداوند میفرماید: «ای کسانی که میخواهید نجات یابید، ای کسانی که چشم امیدتان به من است، سخنان مرا بشنوید. به معدنی که از آن استخراج شدهاید و به صخرهای که از آن جدا گشتهاید، توجه نمایید. | 1 |
“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa. Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
به اجدادتان ابراهیم و سارا فکر کنید که از ایشان به وجود آمدید. هنگامی که ابراهیم را دعوت کردم او فرزندی نداشت و تنها بود، اما من او را برکت دادم و قوم بزرگی از او به وجود آوردم. | 2 |
ẹ wo Abrahamu baba yín, àti Sara, ẹni tó bí i yín. Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni, Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
«من بار دیگر اسرائیل را برکت خواهم داد و خرابههای آن را آباد خواهم ساخت. زمینهای بایر و بیابانهای خشک آن چون باغ عدن سرسبز خواهند شد. خوشی و شادمانی همه جا را پر خواهد ساخت، و شکرگزاری همراه با سرودهای شاد در همه جا به گوش خواهد رسید. | 3 |
Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀; Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni, àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa. Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀, ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.
«ای قوم من، به من گوش دهید، ای مردم من، صدایم را بشنوید، زیرا احکام من صادر خواهد شد و عدالتم نوری برای قومهای جهان خواهد بود. | 4 |
“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi; gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi. Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá; ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
بهزودی میآیم تا آنها را نجات دهم و با عدل و انصاف بر آنها حکومت کنم. چشم امید سرزمینهای دور دست به من است، و برای بازوی پرتوان من انتظار میکشند. | 5 |
Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan, ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà, àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá sí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn erékùṣù yóò wò mí wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
چشمان خود را به آسمان بدوزید و به زمین زیر پایتان نگاه کنید، روزی خواهد آمد که آسمان مانند دود، ناپدید خواهد شد و زمین همچون لباس، پوسیده خواهد شد و مردمش خواهند مرد. اما نجاتی که من به ارمغان میآورم برای همیشه باقی خواهد ماند و عدالت من هرگز از بین نخواهد رفت. | 6 |
Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run, wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀; àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín, ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin. Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé, òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.
«ای کسانی که احکام مرا دوست میدارید و خوب را از بد تشخیص میدهید، به من گوش کنید. از سرزنش و تهمت مردم نترسید؛ | 7 |
“Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́, ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
زیرا بید، آنها را مانند لباس از بین خواهد برد و کرم، ایشان را همچون پشم خواهد خورد. اما عدالت من هرگز از بین نخواهد رفت و کار نجاتبخش من نسل اندر نسل باقی خواهد ماند.» | 8 |
Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ, ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé, àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”
ای خداوند برخیز و با قدرتت ما را نجات ده همانگونه که در گذشته ما را نجات دادی. تو همان خدایی هستی که اژدهای رود نیل، یعنی مصر را نابود کردی. | 9 |
Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára ìwọ apá Olúwa; dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì, àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́. Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́ tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
تو دریا را خشک ساختی و راهی از میان آن باز کردی تا قومی که آزاد ساخته بودی از آن عبور کنند. | 10 |
Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí àti àwọn omi inú ọ̀gbun, tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
کسانی که خداوند آزادشان کرده، سرودخوانان با شادی جاودانی، از آن راه به اورشلیم خواهند آمد. غم و نالهٔ آنان برای همیشه پایان خواهد یافت و جای خود را به شادی و سرود خواهد داد. | 11 |
Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ; ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn. Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.
خداوند میفرماید: «من هستم که به شما تسلی میدهم و شما را شاد میسازم؛ پس چرا از انسان فانی میترسید انسانی که مانند گیاه، خشک شده، از بین میرود؟ | 12 |
“Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú. Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara, àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
اما شما خداوند، آفرینندهٔ خود را فراموش کردهاید، او را که آسمان را همچون خیمه گسترانید و زمین را بنیان نهاد. چرا دائم از ظلم و ستم انسانها میترسید و تمام روز از خشم دشمنان میهراسید؟ کجاست خشم ستمکیش آنها؟ | 13 |
tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ, ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́ nítorí ìbínú àwọn aninilára, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun? Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
شما اسیران، بهزودی آزاد خواهید شد. دیگر در سیاهچالها گرسنه نخواهید ماند و نخواهید مرد. | 14 |
Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ wọn kò ní kú sínú túbú wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
من یهوه خدای شما هستم همان خداوند لشکرهای آسمان که از میان امواج خروشان دریا، راهی خشک برای شما پدید آورد! | 15 |
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
من که زمین را بنیاد نهادم و آسمانها را برقرار ساختم، به اسرائیل میگویم: شما قوم من هستید. من احکام خود را به شما دادهام و با دست خود شما را حفظ میکنم.» | 16 |
Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́, Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀, ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀, àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’”
برخیز ای اورشلیم، برخیز! به اندازهٔ کافی از جام غضب خداوند نوشیدهای. آن را تا ته سر کشیدهای و سرگیجه گرفتهای. | 17 |
Jí, jí! Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu, ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa ago ìbínú rẹ̀, ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
کسی از ساکنانت باقی نمانده تا دستت را بگیرد و تو را راهنمایی کند. | 18 |
Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́ kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
بلای مضاعف بر تو عارض شده است؛ سرزمینت خراب شده و مردمانت از قحطی و شمشیر به هلاکت رسیدهاند. دیگر کسی باقی نمانده تا تو را دلداری و تسلی دهد. | 19 |
Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ— ta ni yóò tù ọ́ nínú? Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
مردم تو مانند آهوانی هستند که در دام صیاد گیر کرده باشند؛ آنها در کوچههایت افتادهاند و قدرت ندارند از جا برخیزند، زیرا خداوند غضب خود را بر آنها نازل کرده است. | 20 |
Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú; wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà, gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n. Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́ àti ìbáwí Ọlọ́run yín.
اما ای مصیبتزده که مست و گیج هستی، اما نه از شراب، اکنون گوش بده. | 21 |
Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́, tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì.
خداوند تو یهوه که مدافع توست چنین میگوید: «من کاسهٔ غضب خود را که باعث سرگیجهٔ تو شده از دست تو میگیرم و تو دیگر مجبور نخواهی شد از آن بنوشی. | 22 |
Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí, Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́, “Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n; láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi, ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
جام غضب خود را به دست کسانی خواهم داد که بر تو ظلم میکنند و به تو میگویند:”در کوچهها دراز بکش تا تو را مانند خاک زمین لگدمال کنیم.“» | 23 |
Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’ Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”