< پیدایش 28 >

پس اسحاق یعقوب را فرا‌خوانده، او را برکت داد و به او گفت: «با هیچ‌یک از این دختران کنعانی ازدواج نکن. 1
Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
بلکه بلند شو و به فَدّان‌اَرام، به خانهٔ پدر بزرگت بتوئیل برو و با یکی از دختران دایی خود لابان ازدواج کن. 2
Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
خدای قادر مطلق تو را برکت دهد و به تو فرزندان بسیار ببخشد تا از نسل تو قبایل زیادی به وجود آیند! 3
Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
او برکتی را که به ابراهیم وعده داد، به تو و نسل تو دهد تا صاحب این سرزمینی که خدا آن را به ابراهیم بخشیده و اکنون در آن غریب هستیم بشوی.» 4
Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
پس اسحاق یعقوب را روانه نمود و او به فَدّان‌اَرام، نزد دایی خود لابان، پسر بتوئیل ارامی رفت. 5
Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
عیسو فهمید که پدرش اسحاق از دختران کنعانی بیزار است، و یعقوب را از گرفتن زن کنعانی برحذر داشته و پس از برکت دادن او، وی را به فَدّان‌اَرام فرستاده است تا از آنجا زنی برای خود بگیرد و یعقوب هم از پدر و مادر خود اطاعت کرده به فَدّان‌اَرام رفته است. 6
Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
7
àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
8
Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
پس عیسو هم نزد خاندان عمویش اسماعیل که پسر ابراهیم بود رفت و علاوه بر زنانی که داشت، محلت، دختر اسماعیل، خواهر نبایوت را نیز به زنی گرفت. 9
Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
پس یعقوب بئرشبع را به قصد حران ترک نمود. 10
Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
همان روز پس از غروب آفتاب، به مکانی رسید و خواست شب را در آنجا به سر برد. پس سنگی برداشت و زیر سر خود نهاده، همان جا خوابید. 11
Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
در خواب نردبانی را دید که پایهٔ آن بر زمین بود و سرش به آسمان می‌رسد و فرشتگان خدا از آن بالا و پایین می‌روند 12
Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
و خداوند بر بالای نردبان ایستاده است. سپس خداوند چنین فرمود: «من خداوند، خدای ابراهیم و خدای پدرت اسحاق هستم. زمینی که روی آن خوابیده‌ای از آن توست. من آن را به تو و نسل تو می‌بخشم. 13
Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
فرزندان تو چون غبار زمین، بی‌شمار خواهند شد! از مشرق تا مغرب، و از شمال تا جنوب را خواهند پوشانید. تمامی مردمِ زمین توسط تو و نسل تو برکت خواهند یافت. 14
Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
هر جا که بروی من با تو خواهم بود و از تو حمایت نموده، دوباره تو را به سلامت به این سرزمین باز خواهم آورد. تا آنچه به تو وعده داده‌ام به جا نیاورم تو را رها نخواهم کرد.» 15
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
سپس یعقوب از خواب بیدار شد و گفت: «بدون شک خداوند در این مکان حضور دارد و من ندانستم!» 16
Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
پس ترسید و گفت: «این چه جای ترسناکی است! این است خانهٔ خدا و این است دروازهٔ آسمان!» 17
Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
پس یعقوب صبح زود برخاست و سنگی را که زیر سر نهاده بود، چون ستونی بر پا داشت و بر آن روغن زیتون ریخت. 18
Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
او آن مکان را بیت‌ئیل (یعنی «خانهٔ خدا») نامید. (نام این شهر پیش از آن لوز بود.) 19
Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
آنگاه یعقوب نذر کرده گفت: «اگر خدا در این سفر با من باشد و مرا محافظت نماید و خوراک و پوشاک به من بدهد، 20
Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
و مرا به سلامت به خانهٔ پدرم بازگرداند، آنگاه یهوه خدای من خواهد بود؛ 21
tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
و این ستونی که به عنوان یادبود بر پا کردم، مکانی خواهد بود برای عبادت خدا و ده‌یک هر چه را که او به من بدهد به وی باز خواهم داد.» 22
Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”

< پیدایش 28 >