< حِزِقیال 5 >
خداوند فرمود: «ای پسر انسان، شمشیری تیز بگیر و آن را همچون تیغ سلمانی به کار ببر و با آن موی سر و ریش خود را ببر. سپس موها را در ترازو بگذار و به سه قسمت مساوی تقسیم کن. | 1 |
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
یک سوم موها را در وسط نقشهای که از اورشلیم کشیدی، بگذار و پس از پایان روزهای محاصره، موها را در همان جا بسوزان. یک سوم دیگر را در اطراف نقشه بپاش و با آن شمشیر آنها را خرد کن. قسمت آخر را در هوا پراکنده ساز تا باد ببرد و من شمشیری در پی آنها خواهم فرستاد. | 2 |
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
چند تار مو نیز بردار و در ردای خود مخفی کن. | 3 |
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
چند تار موی دیگر نیز بردار و در آتش بینداز. از آنجا آتشی بیرون آمده، تمام خاندان اسرائیل را فرا خواهد گرفت.» | 4 |
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
خداوند فرمود: «این تمثیل نشان دهندهٔ بلاهایی است که بر شما، اهالی اورشلیم خواهد آمد. چون از احکام و قوانین من روگردانیده، بدتر از قومهای اطرافتان شدهاید، قومهایی که مرا نمیشناسند. | 5 |
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
بنابراین، من خود بر ضد شما هستم و در برابر تمام قومها، آشکارا مجازاتتان خواهم کرد. | 8 |
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
به سبب گناهان زشتی که مرتکب شدهاید، شما را چنان سخت مجازات خواهم نمود که نظیرش در گذشته دیده نشده و در آینده نیز دیده نخواهد شد! | 9 |
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
پدران، فرزندانشان را خواهند خورد و فرزندان پدرانشان را؛ و کسانی که باقی بمانند در سراسر دنیا پراکنده خواهند شد. | 10 |
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
پس خداوند یهوه میفرماید: به حیات خود قسم، چون شما با بتها و گناهانتان، خانهٔ مرا آلوده کردهاید، من نیز شما را از بین خواهم برد و هیچ ترحم نخواهم کرد. | 11 |
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
یک سوم از شما از قحطی و بیماری خواهید مرد. یک سوم را دشمن خواهد کشت و یک سوم باقیمانده را نیز در سراسر دنیا پراکنده خواهم ساخت و شمشیر دشمن را در آنجا به دنبالتان خواهم فرستاد. | 12 |
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
آنگاه آتش خشم من فرو خواهد نشست و قوم اسرائیل خواهند دانست که من یهوه کلام خود را عملی میسازم. | 13 |
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
تو را برای قومهای اطراف و برای رهگذرانی که از کنار خرابههای شهرتان میگذرند، درس عبرتی خواهم ساخت. | 14 |
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
من شما را در دنیا مایهٔ تمسخر و عبرت خواهم گرداند تا همه بدانند که وقتی من با خشم و غضب بر ضد قومی برمیخیزم، چه سرنوشت غمانگیزی گریبانگیر آن قوم میگردد. من که یهوه هستم، این را گفتهام. | 15 |
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
«قحطی را مانند تیرهای هلاک کننده بر شما نازل خواهم کرد و آن را آنقدر سخت خواهم ساخت که تکهای نان نیز برای خوردن نیابید. | 16 |
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
علاوه بر گرسنگی، جانوران درنده را نیز خواهم فرستاد تا فرزندانتان را نابود کنند. بیماری و جنگ سرزمین شما را فرا خواهد گرفت، و به ضرب شمشیر دشمن کشته خواهید شد. من که یهوه هستم، این را گفتهام!» | 17 |
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”