< تثنیه 12 >

وقتی به سرزمینی می‌رسید که خداوند، خدای پدرانتان آن را به شما داده است، باید این فرایض و قوانین را تا وقتی که در آن سرزمین زندگی می‌کنید، اطاعت نمایید. 1
Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
در هر جا که بتخانه‌ای می‌بینید، چه در بالای کوهها و تپه‌ها، و چه در زیر هر درخت سبز، باید آن را نابود کنید. 2
Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
مذبحهای بت‌پرستان را بشکنید، ستونهایی را که می‌پرستند خرد کنید، مجسمه‌های شرم‌آورشان را بسوزانید و بتهای آنها را قطعه‌قطعه کنید و چیزی باقی نگذارید که شما را به یاد آنها بیندازد. 3
Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
مانند بت‌پرستان در هر جا برای خداوند، خدایتان قربانی نکنید، بلکه در محلی که خودش در میان قبیله‌های اسرائیل به عنوان عبادتگاه خود انتخاب می‌کند، او را عبادت نمایید. 4
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
5
Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
قربانیهای سوختنی و سایر قربانیها، یک دهم دارایی‌تان، هدایای مخصوص، هدایای نذری، هدایای داوطلبانه، و نخست‌زاده‌های گله‌ها و رمه‌هایتان را به آنجا بیاورید. 6
Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
در آنجا شما و خانواده‌هایتان در حضور خداوند، خدایتان خواهید خورد و از دسترنج خود لذت خواهید برد، زیرا او شما را برکت داده است. 7
Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
وقتی به سرزمینی که در آنجا خداوند، خدایتان به شما صلح و آرامش می‌بخشد رسیدید، دیگر نباید مثل امروز هر جا که خواستید او را عبادت کنید. 8
Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
9
Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
زمانی که از رود اردن بگذرید و در آن سرزمین اقامت کنید و یهوه خدایتان به شما آرامش ببخشد و شما را از دست دشمنانتان حفظ کند، 10
Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
آنگاه باید تمام قربانیها و هدایای خود را که به شما امر کرده‌ام به عبادتگاه یهوه خدایتان در محلی که خود انتخاب خواهد کرد بیاورید: قربانیهای سوختنی و دیگر قربانیها، ده‌یک‌ها، هدایای مخصوص و همۀ بهترین هدایای نذری خود را که برای خداوند نذر کرده‌اید. 11
Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
در آنجا با پسران و دختران، غلامان و کنیزان خود، در حضور یهوه خدایتان شادی کنید. به خاطر داشته باشید که لاویان شهرتان را به جشن و شادی خود دعوت کنید، چون ایشان زمینی از خود ندارند. 12
Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
قربانیهای سوختنی خود را نباید در هر جایی که رسیدید قربانی کنید. 13
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
آنها را فقط در جایی می‌توانید قربانی کنید که خداوند در میان یکی از قبیله‌های شما انتخاب کرده باشد. در آنجا هر آنچه من به شما فرمان می‌دهم به جا آورید. 14
Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
ولی حیواناتی را که گوشتشان را می‌خورید می‌توانید در هر جا سر ببرید همان‌طور که غزال و آهو را سر می‌برید. از این گوشت هر قدر میل دارید و هر وقت که یهوه خدایتان به شما بدهد، بخورید. کسانی که نجس باشند نیز می‌توانند آن را بخورند. 15
Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
تنها چیزی که نباید بخورید خون آن است که باید آن را مثل آب بر زمین بریزید. 16
Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
ولی هیچ‌کدام از هدایا را نباید در خانه بخورید، نه ده‌یک غله و شراب تازه و روغن زیتون‌تان و نه نخست‌زادهٔ گله‌ها و رمه‌هایتان و نه چیزی که برای خداوند نذر کرده‌اید و نه هدایای داوطلبانه و نه هدایای مخصوصتان. 17
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
همهٔ اینها را باید به مذبح بیاورید و همراه فرزندان خود و لاویانی که در شهر شما هستند، در آنجا در حضور خداوند، خدایتان آن خوراکی‌ها را بخورید. او به شما خواهد گفت که این مذبح در کجا باید ساخته شود. در هر کاری که می‌کنید در حضور خداوند، خدایتان شادی کنید. 18
Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
مواظب باشید تا وقتی که در زمینِ خود زندگی می‌کنید، لاویان را فراموش نکنید. 19
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
هنگامی که خداوند، خدایتان طبق وعدهٔ خود مرزهایتان را توسعه دهد اگر مذبح از شما دور باشد آنگاه می‌توانید گله‌ها و رمه‌هایتان را که خداوند به شما می‌بخشد، در هر وقت و در هر جا که خواستید سر ببرید و بخورید، همان‌طور که غزال و آهویتان را سر می‌برید و می‌خورید. حتی اشخاصی که نجس هستند می‌توانند آنها را بخورند. اما مواظب باشید گوشت را با خونش که بدان حیات می‌بخشد، نخورید، 20
Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
21
Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
22
Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
23
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
بلکه خون را مثل آب بر زمین بریزید. اگر چنین کنید، خداوند از شما راضی خواهد شد و زندگی شما و فرزندانتان به خیر خواهد بود. 24
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
25
Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
آنچه را که به خداوند وقف می‌کنید، و هدایایی را که نذر کرده‌اید و قربانیهای سوختنی خود را به مذبح ببرید. اینها را باید فقط بر مذبح خداوند، خدایتان قربانی کنید. خون را باید روی مذبح ریخته، گوشت آن را بخورید. 26
Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
27
Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
مواظب باشید آنچه را که به شما امر می‌کنم، اطاعت کنید. اگر آنچه در نظر خداوند، خدایتان پسندیده است انجام دهید، همه چیز برای شما و فرزندانتان تا به ابد به خیر خواهد بود. 28
Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
وقتی یهوه خدای شما، قومهای سرزمینی را که در آن زندگی خواهید کرد نابود کند، 29
Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
در پرستیدن خدایانشان از ایشان پیروی نکنید و گرنه در دام مهلکی گرفتار خواهید شد. نپرسید که این قومها چگونه خدایانشان را می‌پرستند و بعد رفته مثل آنها پرستش کنید. 30
Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
هرگز نباید چنین اهانتی به خداوند، خدایتان بکنید. این قومها کارهای ناپسندی را که خداوند از آنها نفرت دارد، برای خدایانشان بجا می‌آورند. آنها حتی پسران و دخترانشان را برای خدایانشان می‌سوزانند. 31
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
تمام فرمانهایی را که به شما می‌دهم اطاعت کنید. چیزی به آنها نیافزایید و چیزی هم از آنها کم نکنید. 32
Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.

< تثنیه 12 >