< اول تواریخ 22 >

سپس داوود در کنار مذبحی که ساخته بود، ایستاد و گفت: «این همان جایی است که باید خانهٔ یهوه خدا بنا شود و این مذبح برای قربانیهای قوم اسرائیل خواهد بود.» 1
Nígbà náà Dafidi wí pé, “Ilé Olúwa Ọlọ́run ni ó gbọdọ̀ wà níbí, àti pẹ̀lú pẹpẹ ẹbọ sísun fún Israẹli.”
داوود تمام ساکنان غیریهودی اسرائیل را برای ساختن خانهٔ خدا به کار گرفت. از بین آنها افرادی را برای تراشیدن سنگ تعیین کرد. 2
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi pàṣẹ láti kó àwọn àjèjì tí ń gbé ní Israẹli jọ, àti wí pé lára wọn ni ó ti yan àwọn agbẹ́-òkúta láti gbé òkúta dáradára láti fi kọ́lé Ọlọ́run.
او مقدار زیادی آهن تهیه کرد تا از آن میخ و گیره برای دروازه‌ها درست کنند. او همچنین به قدری مفرغ تهیه کرد که نمی‌شد آن را وزن نمود! 3
Dafidi sì pèsè ọ̀pọ̀lọpọ̀ iye irin láti fi ṣe ìṣó fún àwọn ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà àti fún idẹ; àti fún òpó idẹ ni àìní ìwọ̀n.
مردان صور و صیدون نیز تعداد بیشماری الوار سرو برای داوود آوردند. 4
Ó sì tún pèsè ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi Kedari tí ó jẹ́ àìníye, nítorí pé àwọn ará Sidoni àti àwọn ará Tire mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari wá fún Dafidi.
داوود گفت: «پسرم سلیمان، جوان و کم‌تجربه است و خانهٔ خداوند باید پرشکوه و در دنیا معروف و بی‌نظیر باشد. بنابراین، من از حالا برای بنای آن تدارک می‌بینم.» پس داوود پیش از وفاتش، مصالح ساختمانی زیادی را فراهم ساخت 5
Dafidi wí pé, “Ọmọ mi Solomoni ọ̀dọ́mọdé ni ó sì jẹ́ aláìní ìrírí, ilé tí a ó kọ́ fún Olúwa gbọdọ̀ jẹ́ títóbi jọjọ, kí ó sì ní òkìkí àti ògo jákèjádò gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè. Nítorí náà ni èmi yóò ṣe pèsè sílẹ̀ fún un”. Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì ṣe ìpèsè sílẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ kí ó tó di wí pé ó kú.
و به پسر خود سلیمان سفارش کرد خانه‌ای برای خداوند، خدای اسرائیل بنا کند. 6
Nígbà náà ó pe Solomoni ọmọ rẹ̀ ó sì sọ fun pé kí ó kọ́ ilé fún un Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
داوود به سلیمان گفت: «ای پسرم، من خودم می‌خواستم خانه‌ای برای نام یهوه، خدای خود بسازم، 7
Dafidi sì wí fún Solomoni pé, “Ọmọ mi, mo sì ní-in ní ọkàn mi láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi.
اما خداوند به من فرمود: تو خونهای بسیار ریخته‌ای و جنگهای بزرگ کرده‌ای، پس نمی‌توانی خانه‌ای برای نام من بسازی، زیرا دستت به خون انسانهای زیادی آلوده شده است. 8
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé, ‘Ìwọ ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, o sì ti ja ọ̀pọ̀ ogun ńlá ńlá, kì í ṣe ìwọ ni yóò kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ púpọ̀ lórí ilẹ̀ ní ojú mi.
ولی او به من وعده داده، فرمود: پسری به تو می‌دهم که مردی صلح‌جو خواهد بود و من شر تمام دشمنان را از سر او کم خواهم کرد. نام او سلیمان یعنی”صلح“خواهد بود. در طی سلطنت او به قوم اسرائیل صلح و آرامش خواهم بخشید. 9
Ṣùgbọ́n ìwọ yóò ní ọmọ tí yóò sì jẹ́ ọkùnrin onírẹ̀lẹ̀ àti onísinmi, Èmi yóò sì fún un ní ìsinmi láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ yíká. Orúkọ rẹ̀ yóò sì máa jẹ́ Solomoni, Èmi yóò sì fi àlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún Israẹli lásìkò ìjọba rẹ̀.
او خانه‌ای برای من بنا خواهد کرد. او پسر من و من پدر او خواهم بود، و پسران و نسل او را تا به ابد بر تخت سلطنت اسرائیل خواهم نشاند. 10
Òun ni ẹni náà tí yóò kọ́ ilé fún orúkọ mi. Yóò sì jẹ́ ọmọ mi, èmi yóò sì jẹ́ baba rẹ̀ èmi yóò sì fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lórí Israẹli láéláé.’
«پس حال ای پسرم، خداوند همراه تو باشد و تو را کامیاب سازد تا همان‌طور که فرموده است بتوانی خانهٔ خداوند، خدایت را بسازی. 11
“Nísinsin yìí, ọmọ mi, kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, kí ìwọ kí ó sì ní àṣeyọrí kí o sì kọ́ ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ nípa rẹ.
خداوند به تو بصیرت و حکمت عطا کند تا وقتی پادشاه اسرائیل می‌شوی تمام قوانین و دستورهای او را بجا آوری. 12
Kí Olúwa kí ó fún ọ ni ọgbọ́n àti òye nígbà tí ó bá fi ọ́ ṣe aláṣẹ lórí Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó lè pa òfin Olúwa Ọlọ́run mọ́.
چون اگر مطیع دستورها و احکام خداوند که توسط موسی به بنی‌اسرائیل داده است باشی، او تو را موفق می‌گرداند. پس قوی و دلیر باش، و ترس و واهمه را از خود دور کن! 13
Nígbà náà ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí tí ìwọ bá ṣe àkíyèsí láti mú àṣẹ àti ìdájọ́ àti òfin ti Olúwa ti fi fún Mose fun Israẹli ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni ki ìwọ jẹ́ alágbára àti onígboyà. Má ṣè bẹ̀rù tàbí kí àyà má sì ṣe fò ọ́.
«من با تلاش زیاد سه هزار و چهارصد تن طلا و سی و چهار هزار تن نقره جمع‌آوری کرده‌ام، و این علاوه بر آهن و مفرغ بی‌حساب، الوار و سنگی است که برای خانهٔ خداوند آماده ساخته‌ام. تو نیز باید به این مقدار اضافه کنی. 14
“Èmi ti gba ìpọ́njú ńlá láti ṣe fún ilé Olúwa ọ̀kẹ́ márùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà, àti ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà, ìwọ̀n idẹ àti irin tí ó tóbi àìní ìwọ̀n, àti ìtì igi àti òkúta. Ìwọ sì tún le fi kún wọn.
تو سنگتراشها و بنّاها و نجّارها و صنعتگران ماهر بسیار برای انجام هر نوع کاری در خدمت خود داری. 15
Ìwọ sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn oníṣẹ́ ènìyàn: àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn oníṣọ̀nà òkúta àti àwọn agbẹ́-òkúta, àti gẹ́gẹ́ bí onírúurú ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní gbogbo onírúurú iṣẹ́.
ایشان در زرگری و نقره‌سازی و فلزکاری مهارت بسیار دارند. پس کار را شروع کن. خداوند با تو باشد!» 16
Nínú wúrà, fàdákà àti idẹ àti irin oníṣọ̀nà tí kò ní ìwọ̀n. Nísinsin yìí bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́, kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
سپس داوود به تمام بزرگان اسرائیل دستور داد که پسرش را در انجام این کار کمک کنند. 17
Nígbà náà Dafidi pa á láṣẹ fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli láti ran Solomoni ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
داوود به آنان گفت: «خداوند، خدای شما با شماست. او از هر طرف به شما صلح و آرامش بخشیده، زیرا من به یاری خداوند دشمنان این سرزمین را شکست دادم و آنها الان مطیع شما و خداوند هستند. 18
Ó sì wí pé, “Ṣé kò sí Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú rẹ? Òun kò ha ti fi ìsinmi fún ọ lórí gbogbo ilẹ̀? Nítorí ó sì ti fi àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ náà lé mi lọ́wọ́ ó sì ti fi ìṣẹ́gun fún ilẹ̀ náà níwájú Olúwa àti níwájú àwọn ènìyàn.
پس با تمام نیروی خود خداوند، خدای خویش را اطاعت کنید. دست به کار شوید و خانهٔ خداوند را بسازید تا بتوانید صندوق عهد و سایر اشیاء مقدّس را به خانهٔ خداوند بیاورید!» 19
Nísinsin yìí, ẹ ṣí ọkàn yin páyà àti àyà yín sí àti wá Olúwa Ọlọ́run yín. Bẹ́ẹ̀ sì ni kọ́ ibi mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run. Bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó le gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa àti ohun èlò mímọ́ tí ó jẹ́ ti Ọlọ́run, sínú ilé Olúwa tí a o kọ́ fún orúkọ Olúwa.”

< اول تواریخ 22 >