< اشعیا 1 >

رویای اشعیا ابن آموص که آن را درباره یهودا و اورشلیم، در روزهای عزیا و یوتام و آحاز و حزقیا پادشاهان یهودا دید. ۱ 1
Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
‌ای آسمان بشنو و‌ای زمین گوش بگیر زیراخداوند سخن می‌گوید. پسران پروردم وبرافراشتم اما ایشان بر من عصیان ورزیدند. ۲ 2
Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
گاومالک خویش را و الاغ آخور صاحب خود رامی شناسد، اما اسرائیل نمی شناسند و قوم من فهم ندارند. ۳ 3
Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
وای بر امت خطاکار و قومی که زیربار گناه می‌باشند و بر ذریت شریران و پسران مفسد. خداوند را ترک کردند و قدوس اسرائیل رااهانت نمودند و بسوی عقب منحرف شدند. ۴ 4
Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
چرا دیگر ضرب یابید و زیاده فتنه نمایید؟ تمامی سر بیمار است و تمامی دل مریض. ۵ 5
Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
ازکف پا تا به‌سر در آن تندرستی نیست بلکه جراحت و کوفتگی و زخم متعفن، که نه بخیه شده و نه بسته گشته و نه با روغن التیام شده است. ۶ 6
Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
ولایت شما ویران و شهرهای شما به آتش سوخته شده است. غریبان، زمین شما را در نظرشما می‌خورند و آن مثل واژگونی بیگانگان خراب گردیده است. ۷ 7
Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
و دختر صهیون مثل سایه بان در تاکستان و مانند کپر در بوستان خیار ومثل شهر محاصره شده، متروک است. ۸ 8
Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
اگر یهوه صبایوت بقیه اندکی برای ما وا نمی گذاشت، مثل سدوم می‌شدیم و مانند عموره می‌گشتیم. ۹ 9
Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
‌ای حاکمان سدوم کلام خداوند را بشنویدو‌ای قوم عموره شریعت خدای ما را گوش بگیرید. ۱۰ 10
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
خداوند می‌گوید از کثرت قربانی های شما مرا چه فایده است؟ از قربانی های سوختنی قوچها و پیه پرواریها سیر شده‌ام و به خون گاوان و بره‌ها و بزها رغبت ندارم. ۱۱ 11
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
وقتی که می‌آیید تابه حضور من حاضر شوید، کیست که این را ازدست شما طلبیده است که دربار مرا پایمال کنید؟ ۱۲ 12
Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
هدایای باطل دیگر میاورید. بخور نزدمن مکروه است و غره ماه و سبت و دعوت جماعت نیز. گناه را با محفل مقدس نمی توانم تحمل نمایم. ۱۳ 13
Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
غره‌ها و عیدهای شما را جان من نفرت دارد؛ آنها برای من بار سنگین است که ازتحمل نمودنش خسته شده‌ام. ۱۴ 14
Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
هنگامی که دستهای خود را دراز می‌کنید، چشمان خود را ازشما خواهم پوشانید و چون دعای بسیارمی کنید، اجابت نخواهم نمود زیرا که دستهای شما پر از خون است. ۱۵ 15
Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
خویشتن را شسته، طاهرنمایید و بدی اعمال خویش را از نظر من دورکرده، از شرارت دست بردارید. ۱۶ 16
“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
نیکوکاری رابیاموزید و انصاف را بطلبید. مظلومان را رهایی دهید. یتیمان را دادرسی کنید و بیوه‌زنان راحمایت نمایید. ۱۷ 17
kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
خداوند می‌گوید بیایید تا با همدیگر محاجه نماییم. اگر گناهان شما مثل ارغوان باشد مانند برف سفید خواهد شد و اگرمثل قرمز سرخ باشد، مانند پشم خواهد شد. ۱۸ 18
“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
اگر خواهش داشته، اطاعت نمایید، نیکویی زمین را خواهید خورد. ۱۹ 19
Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
اما اگر ابا نموده، تمردکنید شمشیر شما را خواهد خورد زیرا که دهان خداوند چنین می‌گوید. ۲۰ 20
Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
شهر امین چگونه زانیه شده است. آنکه ازانصاف مملو می‌بود و عدالت در وی سکونت می‌داشت، اما حال قاتلان. ۲۱ 21
Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
نقره تو به درد مبدل شده، و شراب تو از آب ممزوج گشته است. ۲۲ 22
Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
سروران تو متمرد شده و رفیق دزدان گردیده، هریک از ایشان رشوه را دوست می‌دارند و در‌پی هدایا می‌روند. یتیمان را دادرسی نمی نمایند ودعوی بیوه‌زنان نزد ایشان نمی رسد. ۲۳ 23
Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
بنابراین، خداوند یهوه صبایوت، قدیر اسرائیل می‌گویدهان من از خصمان خود استراحت خواهم یافت واز دشمنان خویش انتقام خواهم کشید. ۲۴ 24
Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
ودست خود را بر تو برگردانیده، درد تو را بالکل پاک خواهم کرد، و تمامی ریمت را دور خواهم ساخت. ۲۵ 25
Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
و داوران تو را مثل اول و مشیران تو رامثل ابتدا خواهم برگردانید و بعد از آن، به شهرعدالت و قریه امین مسمی خواهی شد. ۲۶ 26
Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
صهیون به انصاف فدیه داده خواهد شد وانابت کنندگانش به عدالت. ۲۷ 27
A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
و هلاکت عاصیان و گناهکاران با هم خواهد شد و آنانی که خداوندرا ترک نمایند، نابود خواهند گردید. ۲۸ 28
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
زیراایشان از درختان بلوطی که شما خواسته بودیدخجل خواهند شد و از باغاتی که شما برگزیده بودید رسوا خواهند گردید. ۲۹ 29
“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
زیرا شما مثل بلوطی که برگش پژمرده و مانند باغی که آب نداشته باشد خواهید شد. ۳۰ 30
Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
و مرد زورآور پرزه کتان و عملش شعله خواهد شد و هردوی آنها باهم سوخته خواهند گردید و خاموش کننده‌ای نخواهد بود. ۳۱ 31
Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

< اشعیا 1 >