< Salmenes 35 >

1 Av David. Trett, Herre, med dem som tretter med mig! Strid mot dem som strider mot mig!
Ti Dafidi. Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí; kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!
2 Grip skjold og verge og reis dig til hjelp for mig!
Di asà àti àpáta mú, kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!
3 Dra spydet frem og steng veien for mine forfølgere! Si til min sjel: Jeg er din frelse!
Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi. Sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà rẹ.”
4 La dem blues og bli til skamme som står mig efter livet! La dem vike tilbake med skam som tenker ondt imot mig!
Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú; kí a sì mú wọn padà, kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.
5 La dem bli som agner for vinden, og Herrens engel støte dem bort!
Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.
6 La deres vei bli mørk og glatt, og Herrens engel forfølge dem!
Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!
7 For uten årsak har de lønnlig gjort i stand sin garngrav for mig, uten årsak har de gravd en grav for mitt liv.
Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi, ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.
8 La ødeleggelse komme over ham, uten at han merker det, og la hans garn som han lønnlig har utlagt, fange ham, la ham falle i det til sin ødeleggelse!
Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì. Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀; kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.
9 Da skal min sjel glede sig i Herren, fryde sig i hans frelse;
Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa, àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.
10 alle mine ben skal si: Herre, hvem er som du, du som frir den elendige fra den som er ham for sterk, og den elendige og fattige fra den som plyndrer ham?
Gbogbo egungun mi yóò wí pé, “Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa? O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ, tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”
11 Der opstår urettferdige vidner, de spør mig om det jeg ikke vet.
Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde; wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.
12 De gjengjelder mig godt med ondt; min sjel er forlatt.
Wọ́n fi búburú san ìre fún mi; láti sọ ọkàn mi di òfo.
13 Og jeg, jeg klædde mig i sørgeklær, da de var syke; jeg plaget min sjel med faste, og min bønn vendte tilbake til min barm.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀; mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú. Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;
14 Jeg gikk omkring, som om det var min venn, min bror; jeg gikk nedbøiet i sørgeklær som en som sørger over sin mor.
èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀ bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni. Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́ bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.
15 Men nu da jeg vakler, gleder de sig og flokker sig sammen; skarns-folk flokker sig om mig uten at jeg visste det; de sønderriver og hviler ikke.
Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ; wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀. Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.
16 Som skamløse som spotter for et stykke brød, skjærer de tenner imot mig.
Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.
17 Herre, hvor lenge vil du se til? Fri min sjel ut fra deres ødeleggelser, mitt eneste fra de unge løver.
Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ? Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn, àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.
18 Jeg vil prise dig i en stor forsamling, love dig blandt meget folk.
Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá; èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.
19 La ikke dem glede sig over mig, som uten grunn er mine fiender! La ikke dem som hater mig uten årsak, blinke med øiet!
Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ lórí ì mi; bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.
20 For de taler ikke fred, men optenker svik mot de stille i landet.
Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà, ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.
21 Og de lukker sin munn vidt op imot mig, de sier: Ha, ha! Der ser vårt øie!
Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà! Ojú wa sì ti rí i.”
22 Du ser det, Herre, ti ikke! Herre, vær ikke langt borte fra mig!
Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́! Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!
23 Våkn op og bli våken for å gi mig rett, min Gud og Herre, for å føre min sak!
Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi, àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!
24 Døm mig efter din rettferdighet, Herre min Gud, og la dem ikke glede sig over mig!
Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!
25 La dem ikke si i sitt hjerte: Ha! Efter ønske! La dem ikke si: Vi har opslukt ham!
Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!” Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”
26 La alle dem få skam og bli til skamme som gleder sig ved min ulykke! La dem som ophøier sig over mig, klæs i skam og skjensel!
Kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀, àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.
27 La dem juble og glede sig som unner mig min rett, og la dem alltid si: Høilovet være Herren, som unner sin tjener at det går ham vel!
Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú; kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa, sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”
28 Da skal min tunge synge om din rettferdighet, hele dagen om din pris.
Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ, àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.

< Salmenes 35 >