< Salmenes 17 >
1 En bønn av David. Hør, Herre, på rettferdighet, merk på mitt klagerop, vend øret til min bønn fra leber uten svik!
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi; fi etí sí igbe mi. Tẹ́tí sí àdúrà mi tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.
2 La min rett gå ut fra ditt åsyn, dine øine skue hvad rett er!
Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ; kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.
3 Du har prøvd mitt hjerte, gjestet det om natten, du har ransaket mig, du fant intet; min munn viker ikke av fra mine tanker.
Ìwọ ti dán àyà mi wò, ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi, ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé, ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.
4 Mot menneskenes gjerninger har jeg efter dine lebers ord tatt mig i vare for voldsmannens stier.
Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ, èmi ti pa ara mi mọ́ kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.
5 Mine skritt holdt fast ved dine fotspor, mine trin vaklet ikke.
Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ; ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.
6 Jeg roper til dig, for du svarer mig, Gud! Bøi ditt øre til mig, hør mitt ord!
Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
7 Vis din miskunnhet i underfulle gjerninger, du som med din høire hånd frelser dem som flyr til dig, fra deres motstandere!
Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
8 Vokt mig som din øiesten, skjul under dine vingers skygge
Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ; fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,
9 for de ugudelige, som ødelegger mig, mine dødsfiender, som omringer mig!
lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi, kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.
10 Sitt fete hjerte lukker de til, med sin munn taler de overmodig.
Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́, wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
11 Hvor vi går, kringsetter de mig nu; sine øine retter de på å felle mig til jorden.
Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká, pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.
12 Han er lik en løve som stunder efter å sønderrive, og en ung løve som ligger på lønnlige steder.
Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ, àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.
13 Reis dig, Herre, tred ham i møte, slå ham ned, frels min sjel fra den ugudelige med ditt sverd,
Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.
14 fra menneskene med din hånd, Herre, fra denne verdens mennesker, som har sin del i livet, og hvis buk du fyller med dine skatter, som er rike på sønner og efterlater sin overflod til sine barn.
Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀, kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí. Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́; àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.
15 Jeg skal i rettferdighet skue ditt åsyn, jeg skal, når jeg våkner, mettes ved din skikkelse.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo; nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.