< Salmenes 126 >
1 En sang ved festreisene. Da Herren lot Sions fanger vende tilbake, var vi som drømmende;
Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
2 da fyltes vår munn med latter, og vår tunge med jubel, da sa de iblandt hedningene: Store ting har Herren gjort imot disse.
Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
3 Store ting har Herren gjort imot oss; vi blev glade.
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
4 Herre, la våre fanger vende tilbake likesom bekker i sydlandet!
Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
5 De som sår med gråt, skal høste fryderop.
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
6 De går gråtende og bærer den de strør ut; de kommer hjem fryderop og bærer sine kornbånd.
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.