< Salmenes 118 >

1 Pris Herren, for han er god, hans miskunnhet varer evindelig!
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Israel sie: Hans miskunnhet varer evindelig!
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Arons hus sie: Hans miskunnhet varer evindelig!
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 De som frykter Herren, sie: Hans miskunnhet varer evindelig!
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 Ut av trengselen kalte jeg på Herren; Herren svarte mig og førte mig ut i fritt rum.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 Herren er med mig, jeg frykter ikke; hvad skulde et menneske gjøre mig?
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 Herren er med mig, den som hjelper mig, og jeg skal se med lyst på dem som hater mig.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 Det er bedre å sette sin lit til Herren enn å stole på mennesker.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 Det er bedre å ta sin tilflukt til Herren enn å stole på fyrster.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 Alle hedninger omringer mig; i Herrens navn skal jeg hugge dem ned.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 De omgir mig, ja, de omringer mig; i Herrens navn skal jeg hugge dem ned.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 De omgir mig som bier, de slukner som ild i tornebusker; i Herrens navn skal jeg hugge dem ned.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 Hårdt støtte du mig forat jeg skulde falle; men Herren hjalp mig.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 Herren er min styrke og lovsang, og han blev mig til frelse.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 Det høres fryderop om frelse i de rettferdiges telt; Herrens høire hånd gjør storverk.
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 Herrens høire hånd ophøier, Herrens høire hånd gjør storverk.
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 Jeg skal ikke dø, men leve og fortelle Herrens gjerninger.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 Hårdt tuktet Herren mig, men til døden overgav han mig ikke.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Lukk op rettferdighets porter for mig! Jeg vil gå inn gjennem dem, jeg vil prise Herren.
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 Dette er Herrens port; de rettferdige skal gå inn gjennem den.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 Jeg vil prise dig fordi du svarte mig og blev mig til frelse.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 Den sten som bygningsmennene forkastet, er blitt hovedhjørnesten.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 Av Herren er dette gjort, det er underfullt i våre øine.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 Dette er dagen som Herren har gjort; la oss fryde oss og glede oss på den!
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 Å Herre, frels dog! Å Herre, la det dog lykkes!
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Velsignet være han som kommer i Herrens navn! Vi velsigner eder fra Herrens hus.
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 Herren er Gud, og han lot det bli lyst for oss. Bind høitidsofferet med rep like inn til alterets horn!
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 Du er min Gud, og jeg vil love dig, min Gud, jeg vil ophøie dig.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 Pris Herren, for han er god, hans miskunnhet varer evindelig.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

< Salmenes 118 >