< 4 Mosebok 5 >

1 Og Herren talte til Moses og sa:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Byd Israels barn at de skal sende ut av leiren alle spedalske og alle som har flod, og alle som er blitt urene ved lik!
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
3 Både mann og kvinne skal I sende bort; utenfor leiren skal I sende dem, forat de ikke skal gjøre deres leir uren, der hvor jeg bor midt iblandt dem.
Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
4 Og Israels barn gjorde så og sendte dem utenfor leiren; som Herren hadde sagt til Moses, således gjorde Israels barn.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
5 Og Herren talte til Moses og sa:
Olúwa sọ fún Mose pé,
6 Si til Israels barn: Når en mann eller kvinne gjør nogen av de synder som mennesker gjør, og bærer sig troløst at mot Herren, så de fører skyld over sig,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
7 da skal de bekjenne den synd som de har gjort, og godtgjøre det de med urette har tatt, med dets fulle verd og enda legge til femtedelen; de skal gi det til den som de har syndet mot.
Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
8 Men dersom mannen ikke har efterlatt sig nogen nær slektning som de kan gi vederlaget til, da skal vederlaget høre Herren til og tilfalle presten foruten sonings-væren, som skal ofres til soning for dem.
Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
9 Og alle gaver, alt det som Israels barn helliger og kommer til presten med, skal høre ham til;
Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
10 hver manns hellige gaver skal høre presten til; det nogen gir ham, skal høre ham til.
Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
11 Og Herren talte til Moses og sa:
Olúwa sọ fún Mose wí pé,
12 Tal til Israels barn og si til dem: Når en manns hustru forsynder sig og er ham utro,
“Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
13 og en annen mann har samleie med henne, men hennes mann ikke vet om det, fordi hun har latt sig vanære i lønndom, og der ikke er noget vidne mot henne, og hun ikke er grepet på fersk gjerning,
nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
14 og det så kommer en skinnsykens ånd over ham, så han blir skinnsyk på sin hustru, og hun virkelig har latt sig vanære, eller det kommer en skinnsykens ånd over ham, så han blir skinnsyk på sin hustru, uaktet hun ikke har latt sig vanære,
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
15 da skal mannen ta sin hustru med sig til presten og som offer for henne ha med tiendedelen av en efa byggmel; men han skal ikke helle olje på det, heller ikke legge virak på det; for det er et skinnsyke-matoffer, et ihukommelses-matoffer, som skal minne om en brøde.
nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
16 Så skal presten føre henne frem og stille henne for Herrens åsyn.
“‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
17 Og presten skal ta hellig vann i et lerkar og ta noget av støvet som er på tabernaklets gulv, og kaste i vannet.
Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
18 Og når presten har stilt kvinnen frem for Herrens åsyn, skal han løse hennes hår og legge ihukommelses-matofferet i hennes hender - et skinnsyke-matoffer er det - og i sin hånd skal presten ha bitterhetens vann, som volder forbannelse.
Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
19 Så skal presten ta kvinnen i ed og si til henne: Så sant ingen har ligget hos dig, og så sant du ikke har vært utro mot din mann og latt dig vanære, så skal du intet mén ha av dette bitterhetens vann som volder forbannelse.
Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
20 Men er det så at du har vært utro mot din mann og latt dig vanære, og at nogen annen enn din mann har hatt samleie med dig
Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
21 - nu skal presten lese op forbannelses-eden for kvinnen og si til henne: - så gjøre Herren dig til en forbannelse og til en ed blandt ditt folk; han la dine hofter svinne inn og din buk hovne op;
nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
22 og dette vann som volder forbannelse, skal trenge inn i dine innvoller, så din buk hovner op og dine hofter svinner inn. Og kvinnen skal si: Amen! Amen!
Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
23 Derefter skal presten skrive op disse forbannelser på et blad og vaske dem ut i bitterhetens vann,
“‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
24 og han skal la kvinnen drikke bitterhetens vann, som volder forbannelse, og vannet som volder forbannelse, skal trenge inn i henne og volde bitter ve.
Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
25 Så skal presten ta skinnsyke-matofferet av kvinnens hånd og svinge det for Herrens åsyn og bære det frem til alteret.
Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
26 Og presten skal ta en håndfull av matofferet som ihukommelses-offer og brenne det på alteret; Og så skal han la kvinnen drikke vannet.
Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
27 Og når han har latt henne drikke vannet, da skal det skje at dersom hun har latt sig vanære og har vært utro mot sin mann, så skal vannet som volder forbannelse, trenge inn i henne og volde bitter ve; hennes buk skal hovne op og hennes hofter svinne inn; og den kvinne skal bli til en forbannelse blandt sitt folk.
Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
28 Men har kvinnen ikke latt sig vanære, og er hun ren, da skal hun intet mén ha av det, og hun skal få barn.
Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
29 Dette er skinnsyke-loven: Når en kvinne er utro mot sin mann og lar sig vanære,
“‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
30 eller når en skinnsykens ånd kommer over en mann, så han blir skinnsyk på sin hustru, så skal han stille kvinnen frem for Herrens åsyn, og presten skal gjøre med henne alt det som er sagt i denne lov.
tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
31 Og mannen skal være fri for skyld, men kvinnen skal lide for sin misgjerning.
Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”

< 4 Mosebok 5 >