< Matteus 2 >
1 Da Jesus var født i Betlehem i Judea, i kong Herodes' dager, se, da kom nogen vismenn fra Østerland til Jerusalem og sa:
Lẹ́yìn ìgbà tí a bí Jesu ní Bẹtilẹhẹmu ti Judea, ni àkókò ọba Herodu, àwọn amòye ti ìlà-oòrùn wá sí Jerusalẹmu.
2 Hvor er den jødenes konge som nu er født? Vi har sett hans stjerne i Østen og er kommet for å tilbede ham.
Wọ́n si béèrè pé, “Níbo ni ẹni náà tí a bí tí í ṣe ọba àwọn Júù wà? Àwa ti rí ìràwọ̀ rẹ̀ ní ìlà-oòrùn, a sì wá láti foríbalẹ̀ fún un.”
3 Men da kong Herodes hørte det, blev han forferdet, og hele Jerusalem med ham.
Nígbà tí ọba Herodu sì gbọ́ èyí, ìdààmú bá a àti gbogbo àwọn ara Jerusalẹmu pẹ̀lú rẹ̀.
4 Og han sammenkalte alle yppersteprestene og de skriftlærde blandt folket og spurte dem hvor Messias skulde fødes.
Nígbà tí ó sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin jọ, ó bi wọ́n léèrè níbi ti a ó gbé bí Kristi?
5 De sa til ham: I Betlehem i Judea; for så er skrevet ved profeten:
Wọ́n sì wí pé, “Ní Bẹtilẹhẹmu ti Judea, èyí ni ohun tí wòlíì ti kọ ìwé rẹ̀ pé,
6 Og du Betlehem i Juda land, du er ingenlunde den ringeste blandt høvdingene i Juda; for fra dig skal utgå en høvding som skal være hyrde for mitt folk Israel.
“‘Ṣùgbọ́n ìwọ Bẹtilẹhẹmu, ní ilẹ̀ Judea, ìwọ kò kéré jù láàrín àwọn ọmọ-aládé Juda; nítorí láti inú rẹ ni Baálẹ̀ kan yóò ti jáde, ẹni ti yóò ṣe ìtọ́jú Israẹli, àwọn ènìyàn mi.’”
7 Da kalte Herodes hemmelig vismennene til sig og spurte dem nøie om tiden da stjernen hadde vist sig;
Nígbà náà ni Herodu ọba pe àwọn amòye náà sí ìkọ̀kọ̀, ó sì wádìí ni ọwọ́ wọn, àkókò náà gan an tí wọ́n kọ́kọ́ rí ìràwọ̀.
8 og han sendte dem til Betlehem og sa: Gå og spør nøie om barnet; og når I har funnet det, da si mig til, forat også jeg kan komme og tilbede det!
Ó sì rán wọn lọ sí Bẹtilẹhẹmu, ó sì wí pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí fínní fínní ní ti ọmọ náà tí a bí. Lẹ́yìn tí ẹ bá sì rí i, ẹ padà wá sọ fún mi, kí èmi náà le lọ foríbalẹ̀ fún un.”
9 Da de hadde hørt kongens ord, drog de avsted; og se, stjernen som de hadde sett i Østen, gikk foran dem, inntil den kom og blev stående over det sted hvor barnet var.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba, wọ́n mú ọ̀nà wọn pọ̀n, sì wò ó, ìràwọ̀ tí wọ́n ti rí láti ìhà ìlà-oòrùn wá, ó ṣáájú wọn, títí tí ó fi dúró lókè ibi tí ọmọ náà gbé wà.
10 Og da de så stjernen, blev de over all måte glade.
Nígbà tí wọ́n sì rí ìràwọ̀ náà, ayọ̀ kún ọkàn wọn.
11 Og de gikk inn i huset og så barnet med Maria, dets mor, og de falt ned og tilbad det, og oplot sine gjemmer og bar frem gaver til det: gull og røkelse og myrra.
Bí wọ́n tí wọ inú ilé náà, wọn rí ọmọ ọwọ́ náà pẹ̀lú Maria ìyá rẹ̀, wọ́n wólẹ̀, wọ́n foríbalẹ̀ fún un. Nígbà náà ni wọ́n tú ìṣúra wọn, wọ́n sì ta Jesu lọ́rẹ: wúrà, tùràrí àti òjìá.
12 Og da de var blitt varslet av Gud i en drøm at de ikke skulde vende tilbake til Herodes, drog de en annen vei bort til sitt land.
Nítorí pé Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún wọn ní ojú àlá pé kí wọ́n má ṣe padà tọ Herodu lọ mọ́, wọ́n gba ọ̀nà mìíràn lọ sí ìlú wọn.
13 Men da de hadde draget bort, se, da åpenbarer Herrens engel sig i en drøm for Josef og sier: Stå op, ta barnet og dets mor og fly til Egypten, og bli der inntil jeg sier dig til! for Herodes vil søke efter barnet for å drepe det.
Nígbà tí wọn ti lọ, angẹli Olúwa fi ara hàn Josẹfu ní ojú àlá pé, “Dìde, gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀, kí ó sì sálọ sí Ejibiti. Dúró níbẹ̀ títí tí èmi yóò fi sọ fún ọ, nítorí Herodu yóò wá ọ̀nà láti pa ọmọ ọwọ́ náà.”
14 Da stod han op og tok barnet og dets mor om natten og drog bort til Egypten,
Nígbà náà ni ó sì dìde, ó mú ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ní òru, ó sì lọ sí Ejibiti,
15 og han blev der til Herodes' død, forat det skulde opfylles som er talt av Herren ved profeten, som sier: Fra Egypten kalte jeg min sønn.
ó sì wà níbẹ̀ títí tí Herodu fi kú. Èyí jẹ́ ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí Olúwa sọ láti ẹnu wòlíì pé, “Mo pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.”
16 Da Herodes nu så at han var blitt narret av vismennene, blev han meget vred, og han sendte bud og lot drepe alle de guttebarn som var i Betlehem og alt landet deromkring, fra to år og derunder, efter den tid han nøie hadde utspurt av vismennene.
Nígbà tí Herodu rí í pé àwọn amòye náà ti tan òun jẹ, ó bínú gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu àti ní ẹkùn rẹ̀ láti àwọn ọmọ ọdún méjì sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àkókò tí ó ti fi ẹ̀sọ̀ ẹ̀sọ̀ béèrè lọ́wọ́ àwọn amòye náà.
17 Da blev det opfylt som er talt ved profeten Jeremias, som sier:
Nígbà náà ni èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Jeremiah wá ṣẹ pé:
18 En røst blev hørt i Rama, gråt og stor klage; Rakel gråt over sine barn og vilde ikke la sig trøste, for de er ikke mere til.
“A gbọ́ ohùn kan ní Rama, ohùn réré ẹkún àti ọ̀fọ̀ ńlá, Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀. Ó kọ̀ láti gbìpẹ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
19 Men da Herodes var død, se, da åpenbarer Herrens engel sig i en drøm for Josef i Egypten og sier:
Lẹ́yìn ikú Herodu, angẹli Olúwa fi ara hàn Josẹfu lójú àlá ní Ejibiti
20 Stå op, ta barnet og dets mor og dra til Israels land! for de er døde som stod barnet efter livet.
Ó sì wí fún un pé, “Dìde gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ padà sí ilẹ̀ Israẹli, nítorí àwọn tí ń wá ẹ̀mí ọmọ ọwọ́ náà láti pa ti kú.”
21 Og han stod op og tok barnet og dets mor og kom til Israels land.
Nítorí náà, o sì dìde, ó gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ó sì wá sí ilẹ̀ Israẹli.
22 Men da han hørte at Arkelaus var konge i Judea efter sin far Herodes, fryktet han for å dra dit; men han blev varslet av Gud i en drøm og drog bort til Galilea.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó gbọ́ pé Akelausi ni ó ń jẹ ọba ní Judea ní ipò Herodu baba rẹ̀, ó bẹ̀rù láti lọ sí ì bẹ̀. Nítorí tí Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún un ní ojú àlá, ó yí padà, ó sì gba ẹkùn Galili lọ,
23 Og han kom og tok bolig i en by som heter Nasaret, forat det skulde opfylles som er talt ved profetene, at han skal kalles en nasareer.
ó sì lọ í gbé ní ìlú tí a pè ní Nasareti. Nígbà náà ni èyí tí a sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì wá sí ìmúṣẹ: “A ó pè é ní ará Nasareti.”