< 3 Mosebok 5 >
1 Når nogen synder, idet han hører opropet til ed og kunde vidne om noget som han enten har sett eller er blitt vitende om, men allikevel ikke gir oplysning derom, og det således ligger en misgjerning på ham,
“‘Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé kò sọ̀rọ̀ nígbà tí a bi í ní gbangba pé kó jẹ́rìí nípa nǹkan tó rí tàbí nǹkan tó mọ̀ nípa ìṣẹ̀lẹ̀ kan, a ó di ẹ̀bi rẹ̀ rù ú.
2 eller når nogen uten å vite det rører ved noget urent, enten det er åtselet av et urent vilt dyr eller åtselet av et urent tamt dyr eller åtselet av et urent kryp, og han således er blitt uren og har ført skyld over sig,
“‘Tàbí bí ẹnìkan bá fọwọ́ kan ohun tí a kà sí àìmọ́ yálà òkú ẹranko aláìmọ́ tàbí òkú ẹran ọ̀sìn aláìmọ́ tàbí òkú ẹ̀dá yówù tó ń rìn lórí ilẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, ó ti di aláìmọ́, ó sì ti jẹ̀bi.
3 eller når han uten å vite det rører ved et menneskes urenhet, hvad det så er for urenhet det gjelder, og han siden får vite det og kjenner sig skyldig,
Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan ohun àìmọ́ ti ènìyàn, ohunkóhun tó lè mú ènìyàn di aláìmọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni náà kò mọ̀, nígbà tí ó bá mọ̀ nípa rẹ̀ yóò jẹ̀bi.
4 eller når nogen uten å sanse sig sverger tankeløst med sine leber at han vil gjøre noget, enten ondt eller godt, hvad det så kan være et menneske tankeløst sverger på, og han siden blir det var og kjenner sig skyldig i noget av disse stykker -
Tàbí bí ẹni kan bá búra láti ṣe ohun kan láì ronú lé e lórí, yálà ohun tó dára tàbí ohun búburú, nínú ọ̀rọ̀ yówù tó ti búra láì kíyèsi ara, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, kò mọ̀ nípa rẹ̀ tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kó rí, nígbà tó bá mọ̀ yóò jẹ̀bi.
5 når nogen altså har ført skyld over sig med noget av dette og bekjenner det han har syndet i,
Bí ẹnikẹ́ni bá jẹ̀bi ọ̀kan nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí, ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ irú ọ̀nà tó ti dẹ́ṣẹ̀
6 da skal han til bot for den synd han har gjort, bære frem for Herren et syndoffer; det skal være en hun av småfeet, et får eller en gjet. Og presten skal gjøre soning for ham og fri ham for hans synd.
àti pé gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ó gbọdọ̀ mú wa fún Olúwa, abo àgùntàn tàbí abo ewúrẹ́ láti inú agbo ẹran wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀.
7 Men dersom han ikke har råd til et stykke småfe, skal han til bot for sin synd bære frem for Herren to turtelduer eller to dueunger, en til syndoffer og en til brennoffer.
“‘Bí kò bá lágbára àti mú ọ̀dọ́-àgùntàn wá, kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀—ọ̀kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, èkejì fún ẹbọ sísun.
8 Han skal føre dem frem til presten, og presten skal først ofre den som er til syndoffer; han skal vri hodet av den like over nakken, dog uten å rive det av.
Kí ó kó wọn wá fún àlùfáà tí yóò kọ́kọ́ rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ kí ó yín in lọ́rùn, ṣùgbọ́n kí ó má já orí rẹ̀ tan,
9 Så skal han sprenge av syndofferets blod på alterets vegg, og det som er tilovers av blodet, skal krystes ut ved alterets fot; det er et syndoffer.
kí ó sì wọ́n díẹ̀ lára ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ, ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà ni kí ó ro sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
10 Den andre fugl skal han ofre som brennoffer, som foreskrevet er. Og presten skal gjøre soning for ham og fri ham for den synd han har gjort sig skyldig i, så han får forlatelse.
Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wá rú ẹbọ sísun gẹ́gẹ́ bí ìlànà, yóò sì ṣe ètùtù fún un nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, a ó sì dáríjì í.
11 Men dersom han ikke har råd til to turtelduer eller to dueunger, så skal han til bot for det han har syndet, ofre tiendedelen av en efa fint mel som syndoffer; han skal ikke ha olje på det og ikke legge virak ved; for det er et syndoffer.
“‘Bí ó bá sì jẹ́ pé kò ní agbára àti mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì wá, kí ó mú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná dáradára wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ, kò gbọdọ̀ fi òróró tàbí tùràrí sí i nítorí pé ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
12 Han skal bære det til presten, og presten skal ta en håndfull av det som ihukommelses-offer og brenne det på alteret sammen med Herrens ildoffer; det er et syndoffer.
Kí ó gbé e wá sí ọ̀dọ̀ àlùfáà, àlùfáà yóò sì bu ẹ̀kúnwọ́ ìyẹ̀fun gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí, kí ó sì sun ún lórí pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa. Ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni.
13 Og presten skal gjøre soning for ham for den synd han har gjort i noget av hine stykker, så han får forlatelse. Og resten av det skal høre presten til på samme måte som ved matofferet.
Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà fún èyíkéyìí nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá, a ó sì dáríjì í: ìyókù sì jẹ́ ti àlùfáà, bí ẹbọ ohun jíjẹ.’”
14 Og Herren talte til Moses og sa:
Olúwa sọ fún Mose pé,
15 Når nogen farer troløst frem og av vanvare forsynder sig mot nogen av Herrens hellige ting, så skal han til bot for sin synd ofre Herren som skyldoffer en vær uten lyte av sitt småfe, en som efter din verdsetning er verd minst to sekler i sølv efter helligdommens sekel.
“Nígbà tí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ ìrékọjá tí ó sì ṣe láìmọ̀ ní ti àwọn ohun mímọ́ Olúwa, kí ó mú àgbò láti inú agbo ẹran wá fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ìtánràn, àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́. Ẹbọ ẹ̀bi ni.
16 Og det hellige han har forsyndet sig mot, skal han gi vederlag for, og han skal legge femtedelen til og gi det til presten. Og presten skal gjøre soning for ham med skyldoffer-væren, så han får forlatelse.
Kí ó ṣe àtúnṣe nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀ nínú ti àwọn ohun mímọ́, kí ó sì fi ìdámárùn-ún kún iye rẹ̀, kí ó sì kó gbogbo rẹ̀ fún àlùfáà. Àlùfáà yóò sì fi àgbò ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà ṣe ètùtù fún, a ó sì dáríjì í.
17 Når nogen uten å vite det synder mot noget av Herrens bud og gjør noget han har forbudt å gjøre, og han således har ført skyld over sig, og det ligger misgjerning på ham,
“Bí ẹnìkan bá dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kó yẹ ko ṣe sí ọ̀kan nínú òfin Olúwa, bí kò tilẹ̀ mọ̀, ó jẹ̀bi, yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
18 så skal han som skyldoffer føre frem til presten en vær uten lyte av sitt småfe, efter din verdsetning. Og presten skal gjøre soning for ham for den synd han uvitterlig har gjort, så han får forlatelse.
kí ó mú àgbò kan láti inú agbo ẹran wá sọ́dọ̀ àlùfáà, fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àgbò tí kò lábùkù tí ó sì níye lórí bí iye owó ibi mímọ́. Báyìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún ẹni náà, fún àṣìṣe tí ó ṣe láìmọ̀, a ó sì dáríjì í.
19 Det er et skyldoffer; han er blitt skyldig for Herren.
Ẹbọ ẹ̀bi ni, ó ti jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀ sí Olúwa.”