< Dommernes 2 >

1 Og Herrens engel kom fra Gilgal op til Bokim. Og han sa: Jeg hentet eder op fra Egypten og førte eder til det land jeg tilsvor eders fedre, og sa: Aldri i evighet vil jeg bryte min pakt med eder;
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa dìde kúrò láti Gilgali lọ sí Bokimu ó sì wí pé, “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, èmi sì síwájú yín wá sí ilẹ̀ tí mo ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín. Èmi sì wí pé, ‘Èmi kì yóò yẹ májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín,
2 men I skal ikke gjøre pakt med dette lands innbyggere; deres altere skal I rive ned. Men I hørte ikke på mine ord; hvad har I gjort!
ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Síbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sí mi. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?
3 Jeg sa også: Jeg vil ikke drive dem ut for eder, men de skal bli til brodder i eders sider, og deres guder skal bli til en snare for eder.
Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”
4 Og da Herrens engel talte disse ord til alle Israels barn, gråt folket høit.
Bí angẹli Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Israẹli tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sọkún kíkorò,
5 Derfor kalte de dette sted Bokim, og de ofret der til Herren.
wọ́n sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Bokimu (ibi tí àwọn ènìyàn ti sọkún). Wọ́n sì rú ẹbọ sí Olúwa níbẹ̀.
6 Da Josva hadde latt folket fare, og Israels barn hadde draget hver til sin arv for å ta landet i eie,
Lẹ́yìn tí Joṣua ti tú àwọn ènìyàn Israẹli ká, àwọn ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan lọ sí ilẹ̀ tí a fi fún wọn láti lọ gbà á ní ìní wọn.
7 tjente folket Herren så lenge Josva levde, og så lenge alle de eldste levde som overlevde Josva og hadde sett alle de store gjerninger Herren hadde gjort for Israel.
Àwọn ènìyàn náà sin Olúwa ní gbogbo ìgbà ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
8 Men da Josva, Nuns sønn, Herrens tjener, var død, hundre og ti år gammel,
Joṣua ọmọ Nuni, ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
9 og de hadde begravet ham på hans arvelodds grunn i Timnat-Heres i Efra'im-fjellene, nordenfor Ga'as-fjellet,
Wọ́n sì sìnkú rẹ̀ sí ààlà ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní Timnati-Hereki ní ilẹ̀ òkè Efraimu ní àríwá òkè Gaaṣi.
10 og da hele denne slekt var samlet til sine fedre, og det efter dem var vokset op en annen slekt, som ikke kjente Herren, og heller ikke de gjerninger han hadde gjort for Israel,
Ní ìgbẹ̀yìn, gbogbo ìran náà sì kú; àwọn ìran tí ó tẹ̀lé wọn kò sì sin Olúwa nítorí wọn kò mọ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ ohun tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
11 da gjorde Israels barn det som var ondt i Herrens øine, og dyrket Ba'alene.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà Baali.
12 De forlot Herren, sine fedres Gud, som hadde ført dem ut av Egyptens land, og de fulgte andre guder av de folks guder som bodde rundt omkring dem, og de tilbad dem og vakte Herrens harme.
Wọ́n kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀, ẹni tí ó mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n ń tọ àwọn òrìṣà lẹ́yìn, wọ́n sì ń sin àwọn oríṣìíríṣìí òrìṣà àwọn ará ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú Olúwa bínú,
13 De forlot Herren og dyrket Ba'al og Astarte-billedene.
nítorí tí wọ́n kọ̀ Olúwa sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ń sin Baali àti Aṣtoreti.
14 Da optendtes Herrens vrede mot Israel, og han gav dem i røveres hånd, som plyndret dem; han solgte dem i deres fienders hånd, de som bodde rundt omkring dem, og de kunde ikke mere stå sig mot sine fiender.
Nínú ìbínú rẹ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli Olúwa fi wọ́n lé àwọn akónisìn lọ́wọ́ tí ó kó wọn ní ẹrú, tí ó sì bà wọ́n jẹ́. Ó sì tà wọ́n fún àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká àwọn ẹni tí wọn kò le dúró dè láti kọ ojú ìjà sí.
15 Overalt hvor de drog ut, var Herrens hånd imot dem, så det gikk dem ille, således som Herren hadde sagt dem, og som Herren hadde svoret, og deres trengsel var stor.
Nígbàkígbà tí àwọn Israẹli bá jáde lọ sí ojú ogun láti jà, ọwọ́ Olúwa sì wúwo ní ara wọn, àwọn ọ̀tá a sì borí wọn, àní gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún wọn. Wọ́n sì wà nínú ìpọ́njú púpọ̀.
16 Da opreiste Herren dommere, og de frelste dem av røvernes hånd.
Olúwa sì gbé àwọn onídàájọ́ dìde tí ó gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ń kó wọn lẹ́rú.
17 Men heller ikke mot sine dommere var de lydige; de holdt sig med andre guder og tilbad dem; de vek snart av fra den vei deres fedre hadde vandret i lydighet mot Herrens bud, og gjorde ikke som de.
Síbẹ̀síbẹ̀ wọn kò fi etí sí ti àwọn onídàájọ́ wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àgbèrè, wọ́n ń sin òrìṣà. Wọn kò dàbí àwọn baba wọn, kíákíá ni wọ́n yípadà kúrò lọ́nà tí àwọn baba wọ́n ń tọ̀, ọ̀nà ìgbọ́ràn sí àwọn òfin Olúwa.
18 Og når Herren opreiste dem dommere, så var Herren med dommeren og frelste dem av deres fienders hånd så lenge dommeren levde; for Herren ynkedes over dem når de sukket for deres skyld som plaget og undertrykte dem.
Nígbà kí ìgbà tí Olúwa bá gbé onídàájọ́ dìde fún wọn, Olúwa máa ń wà pẹ̀lú onídàájọ́ náà, a sì gbà wọ́n kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn ní ìwọ̀n ìgbà tí onídàájọ́ náà bá wà láààyè nítorí àánú Olúwa wà ní ara wọn, nígbà tí wọ́n bá ké ìrora lábẹ́ àwọn tí ń tẹrí wọn ba, tí sì ń fi ìyà jẹ wọ́n.
19 Men når så dommeren døde, falt de igjen tilbake og fór verre frem enn sine fedre: De fulgte andre guder og dyrket dem og tilbad dem; de avstod ikke fra nogen av sine gjerninger eller fra sin gjenstridige ferd.
Ṣùgbọ́n ní kété tí onídàájọ́ bá ti kú, àwọn ènìyàn náà a sì tún padà sí ọ̀nà ìbàjẹ́ àní ju ti àwọn baba wọn lọ, wọn a tẹ̀lé òrìṣà, wọ́n ń sìn wọ́n, wọn a sì foríbalẹ̀ fún wọn, wọ́n kọ̀ láti yàgò kúrò ní ọ̀nà ibi wọn àti agídí ọkàn wọn.
20 Så optendtes Herrens vrede mot Israel, og han sa: Fordi dette folk har brutt min pakt, som jeg oprettet med deres fedre, og ikke har hørt på min røst,
Ìbínú Olúwa yóò sì tún ru sí Israẹli a sì wí pé, “Nítorí tí orílẹ̀-èdè yìí ti yẹ májẹ̀mú tí mo fi lélẹ̀ fún àwọn baba ńlá wọn, tí wọn kò sì fetí sí mi,
21 så vil jeg heller ikke mere drive bort for dem noget av de folk som Josva lot tilbake da han døde.
Èmi kì yóò lé ọ̀kankan nínú àwọn orílẹ̀-èdè tí Joṣua fi sílẹ̀ nígbà tí ó kú jáde.
22 Ved dem skulde Israel prøves, om de vilde ta vare på Herrens vei og vandre på den, som deres fedre gjorde, eller ikke.
Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀ èmi yóò lo àwọn orílẹ̀-èdè yìí láti fi dán Israẹli wò, láti mọ̀ bóyá wọ́n yóò pa ọ̀nà Olúwa mọ́ àti pé bóyá wọn ó rìn nínú rẹ̀ bí àwọn baba ńlá wọn ti rìn.”
23 Så lot da Herren disse folk bli og hastet ikke med å drive dem bort; han gav dem ikke i Josvas hånd.
Nítorí náà Olúwa fi àwọn orílẹ̀-èdè náà sílẹ̀ ní ilẹ̀ náà kò sì lé wọn jáde, tàbí kí ó jẹ́ kí àwọn Israẹli pa wọ́n run, bẹ́ẹ̀ kò sì fi wọ́n lé Joṣua lọ́wọ́.

< Dommernes 2 >