< Jeremias 44 >

1 Dette er det ord som kom til Jeremias om alle de jøder som bodde i Egyptens land, dem som bodde i Migdol og i Tahpanhes og i Memfis og i landet Patros:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
2 Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: I har sett all den ulykke jeg har latt komme over Jerusalem og over alle Judas byer, og se, nu er de en ørken, og det er ingen som bor i dem,
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
3 for det onde som de gjorde, så de vakte min harme, da de gikk avsted og brente røkelse og dyrket andre guder, som de ikke kjente, hverken de eller I eller eders fedre.
Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
4 Og jeg sendte alle mine tjenere, profetene, til eder tidlig og sent og sa: Gjør ikke denne vederstyggelige ting som jeg hater!
Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
5 Men de hørte ikke og la ikke øret til, så de vendte om fra sin ondskap og holdt op med å brenne røkelse for andre guder.
Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
6 Da blev min harme og vrede utøst, og den brente i Judas byer og på Jerusalems gater, og de blev til en ørken, til en ødemark, som det sees på denne dag.
Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
7 Og nu sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud, så: Hvorfor gjør I så stor en ondskap mot eder selv, så mann og kvinne, barn og diebarn utryddes for eder av Judas midte, så det ikke levnes eder nogen rest,
“Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
8 og vekker min harme ved eders henders gjerninger, ved å brenne røkelse for andre guder i Egyptens land, dit I har draget for å bo der - så de skal bli utryddet for eder, og I bli til en forbannelse og til spott blandt alle jordens folkeslag?
Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
9 Har I glemt eders fedres onde gjerninger og Judas kongers onde gjerninger og dets kvinners onde gjerninger og eders egne onde gjerninger og eders kvinners onde gjerninger, det de gjorde i Juda land og på Jerusalems gater?
Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
10 Til denne dag er de ikke blitt ydmyket, og de frykter ikke og lever ikke efter min lov og mine bud, som jeg har forelagt eder og eders fedre.
Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
11 Derfor sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud, så: Se, jeg vender mitt åsyn imot eder til det onde, og jeg vil utrydde hele Juda.
“Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
12 Og jeg vil ta dem som er blitt igjen av Juda, dem som satte sig fore å dra til Egyptens land for å bo der, og de skal alle omkomme, i Egyptens land skal de falle; ved sverd og ved hunger skal de omkomme; både små og store skal dø ved sverd og ved hunger, og de skal bli til en ed, til en forferdelse og en forbannelse og til spott.
Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
13 Og jeg vil hjemsøke dem som bor i Egyptens land, likesom jeg hjemsøkte Jerusalem, med sverd, med hunger og med pest.
Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
14 Og av dem som er blitt tilbake av Juda, av dem som er kommet for å bo der i Egyptens land, skal ingen slippe unda og bli igjen, så han kommer tilbake til Juda land, som de stunder efter å komme tilbake til for å bo der; for ingen skal komme tilbake igjen uten nogen få undslopne.
Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
15 Da svarte de Jeremias alle de menn som visste at deres kvinner brente røkelse for andre guder, og alle kvinnene som stod der i en stor flokk, og alt folket som bodde i Egyptens land, i Patros, og de sa:
Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
16 Vi vil ikke høre på dig i det du har talt til oss i Herrens navn,
“Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
17 men vi vil gjøre alt det som vi har lovt med vår munn; vi vil brenne røkelse for himmelens dronning og utøse drikkoffer for henne, likesom vi har gjort, vi og våre fedre, våre konger og våre høvdinger, i Judas byer og på Jerusalems gater. Da blev vi mettet med brød, og det gikk oss vel, og ingen ulykke rammet oss.
Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
18 Men fra den tid vi holdt op med å brenne røkelse for himmelens dronning og utøse drikkoffer for henne, har vi manglet alt, og ved sverd og hunger er vi omkommet.
Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
19 Og når vi brente røkelse for himmelens dronning og utøste drikkoffer for henne, mon det da var uten våre menns vitende og vilje at vi laget kaker for henne og dyrket henne og utøste drikkoffer for henne?
Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
20 Da sa Jeremias til alt folket, til mennene og til kvinnene og til alt folket som hadde svart ham:
Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
21 Det at I har brent røkelse i Judas byer og på Jerusalems gater, I og eders fedre, eders konger og eders høvdinger og landets folk, mon Herren ikke har kommet det i hu og tenkt på det?
“Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
22 Og Herren kunde ikke mere tåle det for eders onde gjerningers skyld, for de vederstyggeligheters skyld som I gjorde, og så blev eders land til en ørken og en ødemark og til en forbannelse, så ingen bor der, som det sees på denne dag.
Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
23 Fordi I brente røkelse og syndet mot Herren og ikke hørte på Herrens røst og ikke levde efter hans lov og bud og vidnesbyrd, derfor rammet denne ulykke eder, som det sees på denne dag.
Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
24 Og Jeremias sa til alt folket og til alle kvinnene: Hør Herrens ord, alle I av Juda som er i Egyptens land!
Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
25 Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: I og eders kvinner, I talte med eders munn og fullbyrdet det med eders hender, og I sa: Vi vil holde de løfter som vi har gjort: å brenne røkelse for himmelens dronning og utøse drikkoffer for henne. Hold bare eders løfter og opfyll dem!
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
26 Hør derfor Herrens ord, alle I av Juda som bor i Egyptens land: Se, jeg har svoret ved mitt store navn, sier Herren: Sannelig, mitt navn skal ikke mere nevnes i nogen jødisk manns munn i hele Egyptens land, så han sier: Så sant Herren, Israels Gud, lever!
Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
27 Se, jeg våker over dem til det onde og ikke til det gode, og hver mann av Juda som er i Egyptens land, skal omkomme ved sverd og ved hunger, inntil de er tilintetgjort.
Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
28 Og de som undkommer fra sverdet, skal vende tilbake fra Egyptens land til Juda land, en liten flokk, og alle de som er blitt igjen av Juda, som er kommet til Egyptens land for å bo der, skal få merke hvis ord skal stå ved makt, mitt eller deres.
Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
29 Og dette, sier Herren, skal være tegnet for eder på at jeg vil hjemsøke eder på dette sted, så I skal vite at mine ord om eder skal stå ved makt til ulykke for eder:
“‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
30 Så sier Herren: Se, jeg gir Egyptens konge Farao Hofra i hans fienders hånd og i deres hånd som står ham efter livet, likesom jeg har gitt Judas konge Sedekias i Babels konge Nebukadnesars hånd, som var hans fiende og stod ham efter livet.
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”

< Jeremias 44 >