< Jeremias 33 >

1 Og Herrens ord kom til Jeremias annen gang, mens han ennu satt fengslet i vaktgården, og det lød så:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
2 Så sier Herren, som gjør det han vil, Herren som uttenker det for også å fullføre det, han hvis navn er Herren:
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
3 Rop til mig, og jeg vil svare dig, og jeg vil forkynne dig store og ufattelige ting, ting som du ikke kjenner.
‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
4 For så sier Herren, Israels Gud, om husene i denne by og om husene til Judas konge, som er revet ned til forsvar mot fiendens voller og sverd:
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn ọba Juda tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
5 De kommer for å stride mot kaldeerne; men det blir bare til å fylle husene med døde kropper av de menn som jeg slår i min vrede og harme, og som ved sin store ondskap har voldt at jeg har skjult mitt åsyn for denne by.
nínú ìjà pẹ̀lú Kaldea: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
6 Se, jeg legger forbinding og lægedom på den og læger dem, og jeg vil la dem se en overflod av fred og trygghet.
“‘Wò ó, èmi ó mú ọ̀já àti oògùn ìmúláradá dì í; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́.
7 Og jeg vil gjøre ende på Judas fangenskap og Israels fangenskap, og jeg vil bygge dem op som i den første tid.
Èmi ó mú Juda àti Israẹli kúrò nínú ìgbèkùn, èmi ó sì tún wọn kọ́ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe wà tẹ́lẹ̀.
8 Og jeg vil rense dem fra all deres misgjerning, hvormed de har syndet mot mig, og jeg vil forlate alle deres misgjerninger, hvormed de har syndet og forbrutt sig mot mig.
Èmi ó wẹ̀ wọ́n nù kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti ṣẹ sí mi. Èmi ó sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àìṣedéédéé wọn sí mi jì wọ́n.
9 Og byen skal være mig til et gledesnavn, til pris og pryd for alle jordens folkeslag, når de får høre om alt det gode jeg gjør imot den, og de skal skjelve og beve når de får se alt det gode og all den fred jeg gir den.
Nígbà náà ni ìlú yìí ó fún mi ní òkìkí, ayọ̀, ìyìn àti ọlá níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé; tí wọ́n gbọ́ gbogbo rere tí èmi ṣe fún wọn. Wọn ó sì bẹ̀rù, wọn ó wárìrì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore àti àlàáfíà tí èmi pèsè fún wọn.’
10 Så sier Herren: På dette sted om hvilket I sier: Det er øde, uten mennesker og uten fe - her i Judas byer og på Jerusalems gater, som ligger øde, uten mennesker og uten innbyggere og uten fe, skal det ennu en gang høres
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ẹ̀yin yóò wí nípa ibí yìí pé, “Ó dahoro, láìsí ènìyàn tàbí ẹran.” Síbẹ̀ ní ìlú Juda àti ní òpópónà Jerusalẹmu tí ó dahoro, láìsí ẹni tó gbé ibẹ̀; ìbá à se ènìyàn tàbí ẹran, tí yóò gbọ́ lẹ́ẹ̀kan sí.
11 fryds røst og gledes røst, brudgoms røst og bruds røst, rop av dem som sier: Lov Herren, hærskarenes Gud, for Herren er god, hans miskunnhet varer evindelig - dem som bærer frem takkoffer i Herrens hus. For jeg vil gjøre ende på fangenskapet, så landet blir som i den første tid, sier Herren.
Ariwo ayọ̀ àti inú dídùn, ohùn ìyàwó àti ti ọkọ ìyàwó àti ohùn àwọn tí ó ru ẹbọ ọpẹ́ wọn nílé Olúwa wí pé: “‘“Yin Olúwa àwọn ọmọ-ogun, nítorí Olúwa dára, ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé.” Nítorí èmi ó dá ìkólọ ilẹ̀ náà padà sí bí o ṣe wà tẹ́lẹ̀,’ ni Olúwa wí.
12 Så sier Herren, hærskarenes Gud: Ennu en gang skal det på dette sted som er øde, både uten mennesker og uten fe, og i alle dets byer være et tilhold for hyrder som lar fårene hvile der.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ní ilẹ̀ yìí tí ó ti dahoro láìsí ọkùnrin àti àwọn ẹran nínú gbogbo ìlú, kò ní sí pápá oko fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sinmi.
13 I byene i fjellbygdene, i byene i lavlandet og i byene i sydlandet og i Benjamins land og i landet omkring Jerusalem og i Judas byer skal fårene ennu en gang gå forbi den som teller dem, sier Herren.
Ní ìlú òkè wọ̀n-ọn-nì, nínú ìlú àfonífojì, àti nínú ìlú ìhà gúúsù, àti ní ilẹ̀ ti Benjamini, ní ibi wọ̀n-ọn-nì tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda ni agbo àgùntàn yóò tún máa kọjá ní ọwọ́ ẹni tí ń kà wọ́n,’ ni Olúwa wí.
14 Se, dager kommer, sier Herren, da jeg vil opfylle det gode ord jeg har talt om Israels hus og om Judas hus.
“‘Àwọn ọjọ́ náà ń bọ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí èmi ó mú ìlérí rere tí mo ṣe fún ilé Israẹli àti ilé Juda ṣẹ.
15 I de dager og på den tid vil jeg la spire frem for David en rettferdig spire, og han skal gjøre rett og rettferdighet i landet.
“‘Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àti ní àkókò náà, Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dafidi. Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.
16 I de dager skal Juda bli frelst og Jerusalem bo trygt, og dette er det navn det skal kalles med: Herren, vår rettferdighet.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Juda yóò di ẹni ìgbàlà. Jerusalẹmu yóò sì máa gbé láìséwu. Orúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’
17 For så sier Herren: Det skal aldri fattes en mann av Davids ætt som skal sitte på Israels trone,
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dafidi kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Israẹli.
18 og av de levittiske presters ætt skal det aldri fattes en mann for mitt åsyn som ofrer brennoffer og brenner matoffer og bærer frem slaktoffer alle dager.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Lefi kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’”
19 Og Herrens ord kom til Jeremias, og det lød så:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá wí pé:
20 Så sier Herren: Dersom I kan bryte min pakt med dagen og min pakt med natten, så det ikke blir dag og natt i sin tid,
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Tí ìwọ bá lè dá májẹ̀mú mi ní òru tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀sán àti òru kò lè sí ní àkókò wọn mọ́.
21 da skal også min pakt med min tjener David bli brutt, så han ikke får nogen sønn som blir konge og sitter på hans trone, og min pakt med mine tjenere de levittiske prester.
Nígbà náà ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú Dafidi ìránṣẹ́ mi àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi tí ó jẹ́ àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ níwájú mi lè bàjẹ́, tí Dafidi kò sì rí ẹni láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
22 Likesom himmelens hær ikke kan telles og havets sand ikke måles, således vil jeg gjøre min tjener Davids ætt og levittene som tjener mig, tallrike.
Èmi ó mú àwọn ọmọ lẹ́yìn Dafidi ìránṣẹ́ mi àti Lefi tí ó jẹ́ oníwàásù níwájú mi di bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, tí kò ṣe é kà àti bí iyẹ̀pẹ̀ ojú Òkun tí kò ṣe é wọ́n.’”
23 Og Herrens ord kom til Jeremias, og det lød så:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
24 Har du ikke gitt akt på hvad dette folk har talt og sagt: De to slekter som Herren hadde utvalgt, dem forkastet han? Og mitt folk forakter de, så det ikke mere er noget folk i deres øine.
“Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan.
25 Så sier Herren: Dersom jeg ikke har oprettet min pakt med dag og natt, ikke gitt lover for himmel og jord,
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀.
26 så vil jeg også forkaste Jakobs og min tjener Davids ætt, så jeg ikke av hans ætt tar nogen til å herske over Abrahams, Isaks og Jakobs ætt; for jeg vil gjøre ende på deres fangenskap og forbarme mig over dem.
Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọ lẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’”

< Jeremias 33 >