< Jeremias 29 >
1 Dette er innholdet av det brev som profeten Jeremias sendte fra Jerusalem til de gjenlevende av de eldste blandt de bortførte og til prestene og profetene og hele det folk som Nebukadnesar hadde bortført fra Jerusalem til Babel,
Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremiah rán láti Jerusalẹmu sí ìyókù nínú àwọn àgbàgbà tí ó wà ní ìgbèkùn àti sí àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari tí kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
2 efterat kong Jekonja og kongens mor og hoffmennene, Judas og Jerusalems høvdinger og tømmermennene og smedene hadde draget bort fra Jerusalem.
Lẹ́yìn ìgbà tí Jekoniah, ọba, àti ayaba, àti àwọn ìwẹ̀fà, àti àwọn ìjòyè Juda àti Jerusalẹmu, àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùyàwòrán tí wọ́n lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu.
3 Han sendte brevet med El'asa, Safans sønn, og Gemarja, Hilkias' sønn, som Judas konge Sedekias sendte til Babel, til Babels konge Nebukadnesar, og det lød således:
Ó fi lẹ́tà náà rán Eleasa ọmọ Ṣafani àti Gemariah ọmọ Hilkiah, ẹni tí Sedekiah ọba Juda rán sí Nebukadnessari ọba Babeli. Wí pé.
4 Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud, til alle dem som jeg har ført bort fra Jerusalem til Babel:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí mo kó lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu ní Babeli:
5 Bygg hus og bo i dem, plant haver og et deres frukt!
“Ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.
6 Ta eder hustruer og få sønner og døtre, og ta hustruer til eders sønner og gift bort eders døtre, så de kan få føde sønner og døtre; bli tallrike der, og bli ikke færre!
Ẹ ṣe ìgbéyàwó, kí ẹ sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin, ẹ gbé ìyàwó fún àwọn ọmọkùnrin yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọbìnrin yín fún ọkọ. Kí àwọn náà lè ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ẹ máa pọ̀ sí i ní iye, ẹ kò gbọdọ̀ dínkù ní iye níbẹ̀ rárá.
7 Og søk den bys vel som jeg har bortført eder til, og bed for den til Herren! For når det går den vel, så går det eder vel.
Bákan náà, ẹ máa wá àlàáfíà àti ìre ìlú, èyí tí mo kó yín lọ láti ṣe àtìpó. Ẹ gbàdúrà sí Olúwa fún ìre ilẹ̀ náà; nítorí pé bí ó bá dára fún ilẹ̀ náà, yóò dára fún ẹ̀yin pẹ̀lú.”
8 For så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: La ikke eders profeter, som er iblandt eder, og eders spåmenn dåre eder, og lytt heller ikke til de drømmer som I har!
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: “Ẹ má ṣe gbà kí àwọn wòlíì èké àti àwọn aláfọ̀ṣẹ àárín yín tàn yín jẹ. Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí àlá, èyí tí ẹ gbà wọ́n níyànjú láti lá.
9 For falskelig profeterer de for eder i mitt navn; jeg har ikke sendt dem, sier Herren.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín lórúkọ mi, Èmi kò rán wọn níṣẹ́,” ni Olúwa wí.
10 For så sier Herren: Når sytti år er gått til ende for Babel, vil jeg se til eder og opfylle for eder mitt gode ord, at jeg vil føre eder tilbake til dette sted.
Báyìí ni Olúwa wí: “Nígbà tí ẹ bá lo àádọ́rin ọdún pé ní Babeli, èmi yóò tọ̀ yín wá láti ṣe àmúṣẹ ìlérí ńlá mi fún un yín, àní láti kó o yín padà sí Jerusalẹmu.
11 For jeg vet de tanker jeg tenker om eder, sier Herren, fredstanker og ikke tanker til ulykke, å gi eder fremtid og håp.
Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín,” ni Olúwa wí, “àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.
12 Og I skal påkalle mig og gå avsted og bede til mig, og jeg vil høre på eder,
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò ké pè mí, tí ẹ̀yin yóò sì gbàdúrà sí mi, tí èmi yóò sì gbọ́ àdúrà yín.
13 og I skal søke mig, og I skal finne mig når I søker mig av hele eders hjerte.
Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.
14 Jeg vil la mig finne av eder, sier Herren, og jeg vil gjøre ende på eders fangenskap og samle eder fra alle de folk og alle de steder som jeg har drevet eder bort til, sier Herren, og jeg vil føre eder tilbake til det sted som jeg førte eder bort fra.
Èmi yóò di rí rí fún yín ni Olúwa wí, Èmi yóò sì mú yín padà kúrò ní ìgbèkùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè àti ibi gbogbo tí Èmi ti lé yín jáde, ni Olúwa wí. Èmi yóò sì kó yín padà sí ibi tí mo ti mú kí a kó yín ní ìgbèkùn lọ.”
15 Dette skriver jeg fordi I sier: Herren har latt profeter fremstå for oss i Babel.
Ẹ̀yin lè wí pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Babeli.”
16 For så sier Herren om kongen som sitter på Davids trone, og om alt folket som bor i denne by, eders brødre, som ikke har draget ut med eder blandt de bortførte -
Ṣùgbọ́n èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi àti ní ti gbogbo ènìyàn tó ṣẹ́kù ní ìlú yìí; àní ní ti àwọn ènìyàn yín tí kò bá yín lọ sí ìgbèkùn,
17 så sier Herren, hærskarenes Gud: Se, jeg sender sverd, hunger og pest iblandt dem og gjør med dem som en gjør med de dårlige fikener, som ikke kan etes, fordi de er så dårlige.
bẹ́ẹ̀ ni, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín wọn; Èmi yóò ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ búburú tí kò ṣe é jẹ.
18 Og jeg vil forfølge dem med sverd, hunger og pest, og jeg vil la dem bli mishandlet av alle jordens riker og gjøre dem til en forbannelse og en forferdelse, til spott og hån blandt alle de folkeslag som jeg driver dem bort til,
Èmi yóò fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn lépa wọn, Èmi yóò sì sọ wọ́n di ìríra lójú gbogbo ìjọba ayé, fún ègún, àti ìyanu, àti ẹ̀sín, àti ẹ̀gàn láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, ní ibi tí Èmi yóò lé wọn sí.
19 fordi de ikke hørte på mine ord, sier Herren, da jeg sendte mine tjenere profetene til dem, tidlig og sent; men I vilde ikke høre, sier Herren.
Nítorí wọ́n kọ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,” ni Olúwa Ọlọ́run wí. Ọ̀rọ̀ tí mo tún ti ẹnu àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sọ ní ẹ̀yin tí ń ṣe àtìpó kò gbọ́ ni Olúwa Ọlọ́run wí.
20 Men hør nu I Herrens ord, alle I bortførte som jeg har sendt fra Jerusalem til Babel!
Nítorí náà, gbogbo ẹ̀yin ìgbèkùn, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí mo rán lọ kúrò ní Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
21 Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud, om Akab, Kolajas sønn, og om Sedekias, Ma'asejas sønn, som profeterer løgn for eder i hans navn: Se, jeg gir dem i Babels konge Nebukadnesars hånd, og han skal drepe dem for eders øine.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Kolaiah àti nípa Sedekiah ọmọ Maaseiah tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún un yín lórúkọ mi: “Èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́. Òun yóò sì gba ẹ̀mí wọn ní ìṣẹ́jú yìí gan an.
22 Og fra dem skal alle Judas bortførte som er i Babel, hente en forbannelse og si: Herren gjøre med dig som med Sedekias og med Akab, som Babels konge stekte i ilden,
Nítorí tiwọn, ègún yìí yóò ran gbogbo àwọn àtìpó tó wà ní ilẹ̀ Babeli láti Juda: ‘Olúwa yóò ṣe yín bí i Sedekiah àti Ahabu tí ọba Babeli dáná sun.’
23 fordi de gjorde en skjendig gjerning i Israel og drev hor med hverandres hustruer og talte løgnaktige ord i mitt navn, noget jeg ikke hadde befalt dem; og jeg vet det og er vidne, sier Herren.
Nítorí wọ́n ti ṣe ibi ní ilé Israẹli, wọ́n ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ìyàwó aládùúgbò wọn, àti ní orúkọ mi ni wọ́n ti ṣe èké, èyí tí Èmi kò rán wọn láti ṣe. Ṣùgbọ́n, Èmi mọ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo sì jẹ́ ẹlẹ́rìí sí i,” ni Olúwa wí.
24 Og til nehelamitten Semaja skal du si:
Wí fún Ṣemaiah tí í ṣe Nehalami pé,
25 Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: Du har sendt brev i ditt eget navn til alt folket i Jerusalem og til presten Sefanja, Ma'asejas sønn, og til alle prestene og sagt:
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí: Ìwọ fi lẹ́tà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu sí Sefaniah ọmọ Maaseiah tí í ṣe àlùfáà ní orúkọ mi; ó sì sọ fún Sefaniah wí pé,
26 Herren har satt dig til prest i presten Jojadas sted, forat det skal være tilsynsmenn i Herrens hus over alle som er fra vettet og gir sig av med å profetere, så du kan legge dem i blokk og bånd.
‘Olúwa ti yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà rọ́pò Jehoiada láti máa jẹ́ alákòóso ilé Olúwa, kí o máa fi èyíkéyìí nínú àwọn aṣiwèrè tó bá ṣe bí i wòlíì si inú àgò irin.
27 Hvorfor har du da ikke refset Jeremias fra Anatot, som gir sig av med å profetere for eder?
Nítorí náà, èéṣe tí o kò fi bá Jeremiah ará Anatoti wí. Ẹni tí ó ń dúró bí i wòlíì láàrín yín?
28 For han har sendt brev til oss i Babel og sagt: Det vil vare lenge; bygg hus og bo i dem, plant haver og et deres frukt!
Ó ti rán iṣẹ́ yìí sí wa ni Babeli wí pé, àtìpó náà yóò pẹ́ kí ó tó parí, nítorí náà, ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.’”
29 Og presten Sefanja leste op dette brev for profeten Jeremias.
Sefaniah àlùfáà ka lẹ́tà náà sí etí ìgbọ́ Jeremiah tí í ṣe wòlíì.
30 Da kom Herrens ord til Jeremias, og det lød så:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé,
31 Send bud til alle de bortførte og si: Så sier Herren om nehelamitten Semaja: Fordi Semaja har profetert for eder uten at jeg har sendt ham, og har fått eder til å sette eders lit til løgn,
“Rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo àwọn ìgbèkùn wí pé: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí ní ti Ṣemaiah, ará Nehalami: Nítorí pé Ṣemaiah ti sọtẹ́lẹ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n èmi kò ran an, tí òun sì ń mú u yín gbẹ́kẹ̀lé èké.
32 derfor sier Herren så: Se, jeg hjemsøker nehelamitten Semaja og hans ætt; ingen av hans ætt skal få bo blandt dette folk, og han skal ikke få se det gode jeg gjør for mitt folk, sier Herren; for han har preket frafall fra Herren.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Wò ó, èmi yóò bẹ Ṣemaiah, ará Nehalami wò, àti irú-ọmọ rẹ̀; òun kì yóò ní ọkùnrin kan láti máa gbé àárín ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò rí rere náà tí èmi yóò ṣe fún àwọn ènìyàn mi ni Olúwa wí, nítorí ó ti ti kéde ìṣọ̀tẹ̀ sí mi.’”