< Jeremias 23 >

1 Ve de hyrder som ødelegger og adspreder den hjord jeg før, sier Herren.
“Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
2 Derfor sier Herren, Israels Gud, så om de hyrder som røkter mitt folk: I har adspredt mine får og jaget dem bort og ikke sett efter dem; se, jeg hjemsøker eder for eders onde gjerninger, sier Herren.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
3 Og jeg vil selv samle resten av mine får fra alle de land jeg har drevet dem bort til, og jeg vil føre dem tilbake til deres egne beitemarker, og de skal være fruktbare og bli mange.
“Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
4 Og jeg vil sette hyrder over dem, og de skal røkte dem; og de skal ikke frykte mere og ikke forferdes, og ingen av dem skal savnes, sier Herren.
Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
5 Se, dager kommer, sier Herren, da jeg vil la stå frem for David en rettferdig spire, og han skal regjere som konge og gå frem med visdom og gjøre rett og rettferdighet i landet.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
6 I hans dager skal Juda bli frelst, og Israel bo trygt; og dette er det navn som han skal kalles med: Herren, vår rettferdighet.
Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
7 Se, derfor skal dager komme, sier Herren, da en ikke mere skal si: Så sant Herren lever, han som førte Israels barn op fra Egyptens land,
Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
8 men: Så sant Herren lever, som førte Israels hus og ætt op og lot dem komme fra et land i nord og fra alle de land jeg hadde drevet dem bort til. Og de skal bo i sitt land.
Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
9 Om profetene. Mitt hjerte er sønderknust i mitt indre, alle mine ben skjelver, jeg er som en drukken mann, en mann som vinen har overveldet, for Herrens skyld og for hans hellige ords skyld.
Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
10 For landet er fullt av horkarler; for forbannelsens skyld visner landet, for dens skyld er ørkenens beitemarker avsvidd; deres løp er ondt, og deres styrke er urett.
Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
11 For både profet og prest er gudløse; selv i mitt hus har jeg funnet deres ondskap, sier Herren.
“Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
12 Derfor skal deres vei bli for dem som glatte steder i mørket; de skal støtes over ende og falle der; for jeg lar ulykke komme over dem i det år da de blir hjemsøkt, sier Herren.
“Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
13 Hos Samarias profeter har jeg sett dårskap; de profeterte ved Ba'al og førte mitt folk Israel vill.
“Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
14 Men hos Jerusalems profeter har jeg sett grufulle ting; de driver hor og farer med løgn og styrker de ondes hender, så ingen av dem vender om fra sin ondskap; de er alle sammen blitt for mig som Sodoma, og dets innbyggere som Gomorra.
Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
15 Derfor sier Herren, hærskarenes Gud, så om profetene: Se, jeg gir dem malurt å ete og beskt vann å drikke; for fra Jerusalems profeter er gudløshet gått ut over hele landet.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
16 Så sier Herren, hærskarenes Gud: Hør ikke på de profeters ord som profeterer for eder! De fyller eder med tomme innbilninger; de bærer frem sitt eget hjertes syner, ikke ord av Herrens munn.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
17 De sier atter og atter til dem som forakter mig: Herren har sagt: I skal ha fred. Og til hver den som følger sitt hårde hjerte, sier de: Det skal ikke komme ulykke over eder.
Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
18 For hvem av dem har stått i Herrens fortrolige råd, så han så og hørte hans ord? Hvem har gitt akt på mitt ord og hørt det?
Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
19 Se, Herrens storm, hans vrede farer ut, en hvirvlende stormvind; den hvirvler over hodet på de ugudelige.
Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
20 Herrens vrede skal ikke vende tilbake før han har utført og fullbyrdet sitt hjertes tanker; i de siste dager skal I forstå det helt.
Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
21 Jeg har ikke sendt profetene, allikevel løp de; jeg har ikke talt til dem, allikevel profeterte de.
Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
22 Og hadde de stått i mitt fortrolige råd, vilde de la mitt folk høre mine ord og føre dem tilbake fra deres onde vei og fra deres onde gjerninger.
Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
23 Er jeg en Gud bare nær ved, sier Herren, og ikke en Gud langt borte?
“Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
24 Eller kan nogen skjule sig på lønnlige steder så jeg ikke kan se ham? sier Herren. Opfyller jeg ikke himmelen og jorden? sier Herren.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
25 Jeg har hørt hvad de profeter har sagt som profeterer løgn i mitt navn og sier: Jeg har drømt, jeg har drømt.
“Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
26 Hvor lenge skal dette vare? Har de i sinne de profeter som profeterer løgn, og som bærer frem sitt eget hjertes svik -
Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
27 tenker de på å få mitt folk til å glemme mitt navn ved sine drømmer som de forteller hverandre, likesom deres fedre glemte mitt navn for Ba'als skyld?
Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
28 Den profet som har en drøm, han får fortelle en drøm, og den som har mitt ord, han skal tale mitt ord i sannhet! Hvad har halmen å gjøre med kornet? sier Herren.
Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
29 Er ikke mitt ord som en ild, sier Herren, og lik en hammer som knuser berg?
“Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
30 Se, derfor, sier Herren, kommer jeg over de profeter som stjeler mine ord fra hverandre.
“Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
31 Se, jeg kommer over de profeter som bruker sin tunge og sier: Så sier Herren.
Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
32 Se, jeg kommer over dem som bærer frem løgnaktige drømmer, sier Herren, og som forteller dem og fører mitt folk vill ved sine løgner og ved sitt skryt; jeg har ikke sendt dem og ikke gitt dem befaling, og noget gagn gjør de ikke dette folk, sier Herren.
Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
33 Og når dette folk eller en profet eller en prest spør dig: Hvad er Herrens byrde? - da skal du si dem hvad byrden er: I er byrden og jeg vil kaste eder bort, sier Herren.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
34 Og den profet og den prest og den av folket som sier: Herrens byrde, den mann og hans hus vil jeg hjemsøke.
Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
35 Således skal I si hver til sin næste og hver til sin bror: Hvad har Herren svart? Hvad har Herren talt?
Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
36 Men "Herrens byrde" skal I ikke nevne mere; for hver manns eget ord skal være hans byrde, fordi I har forvendt den levende Guds, Herrens, hærskarenes Guds, vår Guds ord.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
37 Således skal du si til profeten: Hvad har Herren svart dig? Hvad har Herren talt?
Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
38 Men dersom I sier "Herrens byrde", da sier Herren så: Fordi I sier dette ord, "Herrens byrde", enda jeg sendte eder bud og sa: I skal ikke si "Herrens byrde",
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
39 se, derfor vil jeg aldeles glemme eder og kaste eder og den by jeg gav eder og eders fedre, bort fra mitt åsyn,
Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
40 og jeg vil legge på eder en evig skam og en evig vanære, som aldri skal glemmes.
Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”

< Jeremias 23 >