< Esaias 61 >

1 Herrens, Israels Guds Ånd er over mig, fordi Herren har salvet mig til å forkynne et godt budskap for de saktmodige; han har sendt mig til å forbinde dem som har et sønderbrutt hjerte, til å utrope frihet for de fangne og løslatelse for de bundne,
Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
2 til å utrope et nådens år fra Herren og en hevnens dag fra vår Gud, til å trøste alle sørgende,
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
3 til å gi de sørgende i Sion hodepryd i stedet for aske, gledes olje i stedet for sorg, lovprisnings klædebon i stedet for en vansmektet ånd, og de skal kalles rettferdighetens terebinter, Herrens plantning til hans ære.
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
4 Og de skal bygge op igjen det som blev ødelagt i eldgammel tid, gjenreise det som har ligget øde fra de første slekter; de skal fornye ødelagte byer, det som har ligget øde fra slekt til slekt.
Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
5 Og fremmede skal stå og vokte eders hjorder, og utlendinger skal være eders akerdyrkere og vingårdsmenn.
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
6 Men I, I skal kalles Herrens prester, vår Guds tjenere skal de kalle eder; folkenes gods skal I ete, og deres herlighet skal gå over til eder.
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
7 For eders skam skal I få dobbelt gjengjeld, og de som led vanære, skal nu juble over sin lodd; derfor skal de få dobbelt lodd i sitt land, evig glede skal bli dem til del;
Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
8 for jeg, Herren, elsker rett og hater urettferdig rov, og trofast vil jeg gi dem deres lønn, og en evig pakt vil jeg gjøre med dem.
“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
9 Og deres ætt skal bli kjent blandt folkene, og deres avkom blandt folkeslagene; alle som ser dem, skal kjenne at de er en ætt Herren har velsignet.
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
10 Jeg vil glede mig i Herren, min sjel skal fryde sig i min Gud; for han har klædd mig i frelsens klædebon, i rettferdighetens kappe har han svøpt mig, likesom brudgommen, som setter på sig en hue prektig som prestens, og likesom bruden, som pryder sig med sine smykker.
Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
11 For som jorden lar sine spirer skyte frem, og som en have lar sine vekster spire, således skal Herren, Israels Gud, la rettferdighet og lovsang fremspire for alle folkenes åsyn.
Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

< Esaias 61 >