< 1 Mosebok 42 >
1 Da Jakob fikk vite at det var korn i Egypten, sa han til sine sønner: Hvorfor sitter I og ser på hverandre?
Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
2 Og han sa: Jeg har hørt at det er korn i Egypten; dra dit ned og kjøp korn til oss der, så vi kan leve og ikke dø!
“Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
3 Da drog Josefs ti brødre ned for å kjøpe korn i Egypten.
Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
4 Men Benjamin, Josefs bror, sendte Jakob ikke avsted med hans brødre; for han sa: Det kunde møte ham en ulykke.
Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
5 Så kom Israels sønner for å kjøpe korn blandt alle de andre som kom; for det var hungersnød i Kana'ans land.
Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
6 Og Josef var den som rådet i landet; det var han som solgte korn til alt folket i landet; og Josefs brødre kom og bøide sig med sitt ansikt til jorden for ham.
Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
7 Da Josef så sine brødre, kjente han dem igjen; men han lot som om de var fremmede for ham, og talte hårdt til dem og sa til dem: Hvor kommer I fra? De sa: Fra Kana'ans land for å kjøpe korn.
Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
8 Josef kjente sine brødre, men de kjente ikke ham.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
9 Og Josef kom i hu det han hadde drømt om dem, og sa til dem: I er speidere, I er kommet for å se hvor landet ligger åpent.
Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
10 De svarte ham: Nei, herre, dine tjenere er kommet for å kjøpe korn.
Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
11 Vi er alle sønner av én mann; vi er ærlige folk, dine tjenere er ikke speidere.
Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
12 Men han sa til dem: Jo, I er kommet for å se hvor landet ligger åpent.
Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
13 Men de sa: Vi, dine tjenere, er tolv brødre, sønner av én mann i Kana'ans land, den yngste er nu hjemme hos vår far, og én er ikke mere til.
Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
14 Josef sa til dem: Det er som jeg har sagt til eder: I er speidere.
Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
15 Men nu skal I prøves: Så sant Farao lever, skal I ikke komme herfra før eders yngste bror kommer hit.
Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
16 Send en av eder avsted for å hente eders bror, men I andre skal holdes fanget, og eders ord skal prøves, om det er sant det I sier; hvis ikke, så er I, så sant Farao lever, speidere.
Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
17 Og han holdt dem alle sammen i fengsel i tre dager.
Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
18 Men den tredje dag sa Josef til dem: Gjør som jeg nu sier, så skal I leve! Jeg frykter Gud.
Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
19 Dersom I er ærlige folk, så skal en av eder brødre bli tilbake i fengslet, men I andre kan dra avsted og ha med eder korn til hjelp mot hungersnøden i eders hjem,
Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
20 og før eders yngste bror til mig, så eders ord kan sannes, og I ikke skal dø. Og de så gjorde.
Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
21 Og de sa sig imellem: Sannelig, vi har skyld på oss for vår bror. Vi så hans sjeleangst da han bønnfalt oss, og vi vilde ikke høre; derfor er denne nød kommet over oss.
Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
22 Da tok Ruben til orde og sa til dem: Sa jeg ikke til eder: Gjør ikke synd mot gutten? Men I vilde ikke høre; se, derfor kreves nu hans blod.
Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
23 Men de visste ikke at Josef forstod det; for han brukte tolk når han talte med dem.
Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
24 Og han vendte sig fra dem og gråt. Så vendte han sig til dem igjen og talte til dem, og han tok Simeon fra dem og lot ham binde så de så på.
Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
25 Og Josef bød sine folk at de skulde fylle deres sekker med korn og legge enhvers penger igjen i hans sekk og gi dem niste med på veien. Og de gjorde således med dem.
Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
26 Så la de kornet på sine asener og drog derfra.
wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
27 Men da en av dem åpnet sin sekk for å gi sitt asen fôr i herberget, da fikk han se sine penger, de lå øverst i hans sekk.
Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
28 Og han sa til sine brødre: Mine penger er kommet igjen, og se, de ligger her i min sekk. Da blev de motfalne og vendte sig forferdet til hverandre og sa: Hvad er det Gud har gjort mot oss?
Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
29 Så kom de hjem til Jakob, sin far, i Kana'ans land, og de fortalte ham alt det som hadde hendt dem, og sa:
Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
30 Mannen som råder der i landet, talte hårdt til oss og tok oss for folk som vilde speide ut landet.
“Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
31 Og vi sa til ham: Vi er ærlige folk, vi er ikke speidere;
Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
32 vi er tolv brødre, alle sønner av samme far, én er ikke mere til, og den yngste er nu hjemme hos vår far i Kana'ans land.
Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
33 Da sa mannen som råder der i landet, til oss: Av dette vil jeg forstå om I er ærlige folk: La en av eder brødre bli her hos mig og ta hvad I trenger mot hungersnøden i eders hjem, og far eders vei;
“Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
34 og kom så hit til mig med eders yngste bror, så jeg kan forstå at I ikke er speidere, men ærlige folk! Da vil jeg gi eder eders bror igjen, og I kan fritt dra omkring i landet.
Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
35 Da de så tømte sine sekker, se, da lå enhvers pengepung i hans sekk; og da de og deres far så pengepungene, blev de redde.
Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
36 Og Jakob, deres far, sa til dem: I gjør mig barnløs; Josef er ikke mere til, og Simeon er ikke mere til, og Benjamin vil I ta fra mig; det kommer over mig alt sammen.
Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
37 Da sa Ruben til sin far: Begge mine sønner kan du drepe hvis jeg ikke kommer tilbake til dig med ham; gi ham i min hånd, så vil jeg føre ham tilbake til dig.
Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
38 Men han sa: Min sønn skal ikke dra ned med eder; for hans bror er død, og han er alene tilbake, og dersom det møter ham nogen ulykke på den vei som I drar, så kommer I til å sende mine grå hår med sorg ned i dødsriket. (Sheol )
Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol )