< Esekiel 9 >
1 Og jeg hørte ham rope med høi røst og si: Kom hit med hjemsøkelsene over staden, hver med sitt ødeleggelsesredskap i sin hånd!
Mo gbọ́ ti ó kígbe ní ohùn rara pé, “Mú àwọn olùṣọ́ ìlú súnmọ́ itòsí, kí olúkúlùkù wọn mú ohun ìjà olóró lọ́wọ́.”
2 Og se, det kom seks menn på veien gjennem den øvre port, som vender mot nord, hver med sitt ødeleggelsesredskap i sin hånd, og midt iblandt dem var det en mann som var klædd i linklær og hadde et skrivetøi ved sin lend, og de kom inn og stilte sig ved siden av kobberalteret.
Lójú ẹsẹ̀ ni ọkùnrin mẹ́fà jáde láti ẹnu-ọ̀nà òkè tó kọjú sí ìhà àríwá, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà olóró lọ́wọ́ wọn. Ọkùnrin kan tó wọ aṣọ funfun gbòò wa láàrín wọn, pẹ̀lú ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Gbogbo wọn sì dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ idẹ.
3 Og Israels Guds herlighet hevet sig op fra kjerubene, som den hvilte på, og flyttet sig til husets dørtreskel, og han ropte til den mann som var klædd i linklærne og hadde skrivetøiet ved sin lend.
Ògo Ọlọ́run Israẹli sì gòkè kúrò lórí kérúbù, níbi tó wà tẹ́lẹ̀ lọ sí ibi ìloro tẹmpili. Nígbà náà ni Olúwa pe ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun náà tí ó sì ní ohun ìkọ̀wé lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
4 Og Herren sa til ham: Gå midt igjennem staden, midt igjennem Jerusalem, og sett et tegn i pannen på de menn som sukker og jamrer over alle de vederstyggelige ting som skjer der.
Ó sì sọ fún un pé, “La àárín ìlú Jerusalẹmu já, kí ìwọ sì fi àmì síwájú orí gbogbo àwọn tó ń kẹ́dùn, tó sì ń sọkún nítorí ohun ìríra tí wọn ń ṣe láàrín rẹ̀.”
5 Og til de andre hørte jeg ham si: Gå gjennem staden efter ham og slå ned! Vis ikke skånsel og spar ingen!
Bí mo ṣe ń fetí sí èyí, O tún sọ fún àwọn yòókù pé, “Tẹ̀lé ọkùnrin náà lọ sí àárín ìlú láti pa láì dá sí àti láì ṣàánú rárá.
6 Gamle folk, unge menn og jomfruer, spebarn og kvinner skal I hugge ned for fote; men I må ikke røre nogen av dem som tegnet er på. I skal begynne fra min helligdom. Og de begynte med de gamle menn som stod foran huset.
Ẹ pa arúgbó àti ọ̀dọ́mọkùnrin, ẹ pa ọlọ́mọge, obìnrin àti ọmọ kéékèèké, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan àwọn tó ní àmì. Ẹ bẹ̀rẹ̀ láti ibi mímọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà tó wà níwájú tẹmpili.
7 Og han sa til dem: Gjør huset urent og fyll forgårdene med drepte! Dra ut! Og de drog ut og slo ned folket i staden.
Nígbà náà lo sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ tẹmpili náà di àìmọ́, kí òkú sì kún àgbàlá náà. Ẹ lọ!” Wọ́n jáde síta, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa ènìyàn láàrín ìlú.
8 Men mens de slo ned, og jeg blev igjen, falt jeg på mitt ansikt og ropte: Akk, Herre, Herre! Vil du ødelegge alt som er igjen av Israel, idet du utøser din harme over Jerusalem?
Èmi nìkan ló ṣẹ́kù nígbà tí wọ́n lọ pa àwọn ènìyàn, mo dójú mi bolẹ̀, mo kígbe pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli nípa dída ìbínú gbígbóná rẹ sórí Jerusalẹmu?”
9 Og han sa til mig: Israels og Judas folks misgjerning er over all måte stor; landet er fullt av blodskyld, og staden er full av urettferdige dommer; for de sier: Herren har forlatt landet, Herren ser det ikke.
Ó dá mi lóhùn pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli àti Juda pọ gidigidi; ilé wọn kún fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àti àìṣòótọ́. Wọ́n ní, ‘Olúwa tí kọ ilẹ̀ náà sílẹ̀; Olúwa kò sì rí wa.’
10 Derfor vil heller ikke jeg vise skånsel og ikke spare dem; jeg vil la deres gjerninger komme over deres eget hode.
Nítorí náà, èmi kò ní wò wọ́n pẹ̀lú àánú, èmi kò sì ní dá wọn sí, ṣùgbọ́n Èmi yóò dá ohun tí wọ́n ti ṣe padà sórí wọn.”
11 Og se, den mann som var klædd i linklærne og hadde skrivetøiet ved sin lend, kom tilbake og meldte: Jeg har gjort som du bød mig.
Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀, tí ó ní ìwo tàdáwà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ròyìn pé, “Mo ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti pàṣẹ fún mi.”