< Esekiel 7 >
1 Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Og du menneskesønn! Så sier Herren, Israels Gud, til Israels land: Ende! - Enden kommer over landets fire hjørner.
“Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
3 Nu kommer enden over dig, og jeg vil sende min vrede mot dig og dømme dig efter din ferd, og jeg vil la dig bøte for alle dine vederstyggeligheter.
Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
4 Jeg vil ikke vise skånsel mot dig og ikke spare dig; men jeg vil la dig bøte for din ferd, og dine vederstyggeligheter skal komme over dig selv, og I skal kjenne at jeg er Herren.
Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
5 Så sier Herren, Israels Gud: Ulykke, en ulykke uten like, se, den kommer.
“Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
6 Det kommer en ende, enden kommer, den våkner op og kommer til dig; se, det kommer.
Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
7 Nu kommer turen til dig, du som bor i landet! Tiden kommer, dagen er nær, krigslarm er der og ikke fryderop på fjellene.
Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
8 Nu, om en liten stund, vil jeg utøse min harme over dig og uttømme min vrede på dig og dømme dig efter din ferd, og jeg vil la dig bøte for alle dine vederstyggeligheter.
Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
9 Jeg vil ikke vise skånsel og ikke spare dig; efter din ferd vil jeg gjengjelde dig, og dine vederstyggeligheter skal komme over dig selv, og I skal kjenne at jeg, Herren, slår.
Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
10 Se, dagen er der! Se, det kommer! Nu begynner det, riset blomstrer, overmotet grønnes;
“‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
11 voldsomheten reiser sig til et ris over ugudeligheten. Intet av dem, intet av deres larmende hop, intet av deres buldrende mengde, intet herlig blir tilbake iblandt dem.
Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
12 Tiden kommer, dagen er nær. Kjøperen glede sig ikke, og selgeren gremme sig ikke! For det kommer brennende vrede over hele deres hop.
Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
13 Selgeren skal ikke få igjen det han har solgt, om han enn er i live; for spådommen mot hele deres hop skal ikke tas tilbake, og for sin misgjernings skyld skal ingen kunne trygge sig i sitt liv.
Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
14 De støter i basun og gjør alt ferdig, men ingen drar ut til strid; for min harme er vendt mot hele deres hop.
“‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
15 Sverdet utenfor og pesten og hungeren innenfor; den som er ute på marken, skal dø ved sverdet, og den som er inne i byen, ham skal hunger og pest fortære.
Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
16 Og om nogen av dem undkommer, skal de alle være på fjellene som kurrende duer i dalene, hver for sin misgjernings skyld.
Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
17 Alle hender skal synke, og alle knær skal bli som vann.
Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
18 Og de skal binde sekk om sig, og redsel skal legge sig over dem, og alle ansikter skal dekkes av skam, og alle deres hoder skal være skallet.
Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
19 Sitt sølv skal de kaste på gatene, og sitt gull skal de akte for urent; deres sølv og deres gull skal ikke kunne berge dem på Herrens vredes dag; de skal ikke kunne mette sig eller fylle sin buk med det. For det har vært et anstøt til misgjerning for dem,
“‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
20 og sine prektige smykker som er laget av det, har de brukt til storaktighet, og sine vederstyggelige billeder, sine avskyelige avguder har de gjort av det; derfor gjør jeg det til urenhet for dem.
Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
21 Og jeg vil gi det i de fremmedes hånd som rov og til jordens ugudelige som hærfang, og de skal vanhellige det;
Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
22 Og jeg vil vende mitt åsyn bort fra dem, og de skal vanhellige min skatt; røvere skal komme inn over den og vanhellige den.
Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
23 Gjør lenken ferdig! For landet er fullt av bloddommer, og byen er full av vold.
“‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
24 Og jeg vil la de verste av hedningene komme, og de skal ta deres hus i eie, og jeg vil gjøre ende på de frekkes stolthet, og deres helligdommer skal vanhelliges.
Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
25 Det skal komme redsel, og de skal søke frelse, men der er ingen.
Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
26 Ulykke på ulykke skal komme, og rykte på rykte skal opstå, og de skal søke efter syn hos profeten, og lov skal ikke være å finne hos presten eller råd hos de gamle;
Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
27 kongen skal sørge, og høvdingen skal klæ sig i forferdelse, og hendene på landets folk skal skjelve. Efter deres ferd vil jeg gjøre med dem, og med deres dommer vil jeg dømme dem, og de skal kjenne at jeg er Herren.
Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”