< Esekiel 31 >

1 I det ellevte år, i den tredje måned, på den første dag i måneden, kom Herrens ord til mig, og det lød så:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Menneskesønn! Si til Farao, Egyptens konge, og til hans larmende hop. Hvem er du lik i din storhet?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Se, Assur var en seder på Libanon med fagre grener, en skyggende skog og høi av vekst, og hans krone nådde op mellem skyene.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Vannet gjorde ham stor, vanndypet gjorde ham høi; med sine strømmer gikk det rundt om det sted hvor han var plantet, og sendte sine vannløp ut til alle markens trær.
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 Derfor blev han høiere av vekst enn alle markens trær, og han fikk mange grener og lange kvister, fordi det var så rikelig med vann der han bredte sig ut;
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 på hans kvister bygget alle himmelens fugler rede, og under hans grener fødte alle markens dyr sine unger, og i hans skygge bodde alle de mange folkeslag.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 Han var fager i sin storhet, med sine lange grener; for ved hans rot var det rikelig med vann.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Sedrene i Guds have stilte ham ikke i skyggen, cypresser var ikke å ligne med hans kvister, og lønnetrær var ikke som hans grener; intet tre i Guds have var å ligne med ham i skjønnhet.
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Fager hadde jeg gjort ham i hans rikdom på grener, og alle Edens trær i Guds have misunte ham.
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 Derfor sa Herren, Israels Gud, så: Siden han er blitt høi av vekst og har strakt sin krone op mellem skyene, og han er blitt overmodig fordi han var blitt så høi,
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 så gir jeg ham i hendene på folkenes hersker, så han kan gjøre med ham som han vil. For hans ugudelighets skyld drev jeg ham ut,
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 og fremmede, de grusomste blandt folkene, hugg ham ned og lot ham ligge; på fjellene og i alle daler falt hans kvister, og hans grener blev sønderbrutt ved alle landets bekker, og alle jordens folk steg ned fra hans skygge og lot ham ligge,
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 på hans falne stamme slo alle himmelens fugler sig ned, og ved hans grener leiret sig alle markens dyr -
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 forat ingen trær som vokser ved vann, skal bli overmodige av sin vekst og strekke sin krone op mellem skyene, og de sterkeste av dem, alle de som suger vann til sig, ikke skal stå der i sin høide; for de er alle sammen overgitt til døden og må ned til dødsrikets land, blandt menneskenes barn, til dem som har faret ned i graven.
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Så sier Herren, Israels Gud: Den dag han fór ned i dødsriket, lot jeg vanndypet sørge; jeg tildekket det for hans skyld, jeg stanset dets strømmer, og mange vann blev holdt tilbake. Jeg klædde Libanon i sort for hans skyld, og alle markens trær vansmektet for hans skyld. (Sheol h7585)
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
16 Ved braket av hans fall fikk jeg folkeslag til å skjelve, da jeg lot ham fare ned i dødsriket med dem som farer ned i graven; da blev de trøstet i dødsrikets land alle Edens trær, de beste og fagreste på Libanon, alle de som suget vann til sig. (Sheol h7585)
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
17 Også de fór ned med ham i dødsriket til dem som var drept med sverdet; for som hans arm hadde de sittet i hans skygge midt iblandt folkene. (Sheol h7585)
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
18 Hvem er du således lik i herlighet og storhet blandt Edens trær? - Så skal du da nedstøtes med Edens trær til dødsrikets land; midt iblandt uomskårne skal du ligge, sammen med dem som er drept med sverdet. Således skal det gå Farao og hele hans larmende hop, sier Herren, Israels Gud.
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Esekiel 31 >