< 5 Mosebok 2 >
1 Så vendte vi om og drog til ørkenen på veien til det Røde Hav, således som Herren hadde sagt til mig; og vi drog i lang tid omkring Se'ir-fjellene.
Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
3 Lenge nok har I draget omkring disse fjell; vend eder nu mot nord!
“Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
4 Og byd folket og si: I drar nu frem gjennem det land som tilhører eders brødre Esaus barn, som bor i Se'ir; og de blir redde for eder, men I skal ta eder vel i akt,
Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
5 så I ikke gir eder i strid med dem; jeg vil ikke gi eder så meget som en fotbredd av deres land, for jeg har gitt Esau Se'ir-fjellene til eiendom.
Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
6 Mat skal I kjøpe av dem for penger, så I kan ete, og vann skal I også kjøpe av dem for penger, så I kan drikke;
Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
7 for Herren din Gud har velsignet dig i alt det du har tatt dig fore, han har båret omsorg for dig på din vandring gjennem denne store ørken; i firti år har Herren din Gud nu vært med dig, du har ikke manglet noget.
Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
8 Så drog vi videre, bort fra våre brødre Esaus barn, som bor i Se'ir; vi tok av fra veien som går fra Elat og Esjon-Geber gjennem ødemarken, og vendte oss til en annen kant og drog frem på veien til Moabs ørken.
Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
9 Da sa Herren til mig: Du må ikke angripe moabittene og ikke gi dig i strid med dem; jeg vil ikke gi dig noget av deres land til eiendom, for jeg har gitt Lots barn Ar til eiendom.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
10 Før i tiden bodde emittene der, et stort og tallrikt folk og høit av vekst likesom anakittene.
(Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
11 Også de regnes for kjemper likesom anakittene, og moabittene kaller dem emitter.
Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
12 Og i Se'ir bodde før i tiden horittene; men Esaus barn drev dem bort og utryddet dem og bosatte sig der i deres sted, likesom Israel nu har gjort med sitt land, det som Herren har gitt dem til eiendom.
Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
13 Gjør eder nu rede og gå over Sered-bekken! Så gikk vi over Sered-bekken.
Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
14 Den tid vi var på vandring fra Kades-Barnea, til vi gikk over Sered-bekken, var åtte og tretti år, og da var hele den slekt - alle våbenføre menn - utdød av leiren, som Herren hadde svoret at det skulde gå dem.
Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
15 Og Herrens hånd var også mot dem, så han rev dem bort av leiren, til det var ute med dem.
Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
16 Da nu alle våbenføre menn var utdød av folket,
Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
17 da talte Herren til mig og sa:
Olúwa sọ fún mi pé,
18 Du drar nu over Moabs landemerker, gjennem Ar,
“Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
19 og du kommer nær Ammons barns land; men du må ikke angripe dem eller gi dig i strid med dem; jeg vil ikke gi dig noget av Ammons barns land til eiendom, for jeg har gitt Lots barn det til eiendom.
Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
20 Også dette land regnes for et land med kjemper; før i tiden bodde kjemper der, og ammonittene kaller dem samsummitter.
(A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
21 De var et stort og tallrikt folk og høie av vekst likesom anakittene; men Herren utryddet dem for Ammons barn, så de drev dem bort og bosatte sig der i deres sted.
Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
22 Det samme gjorde han for Esaus barn, som bor i Se'ir; for dem utryddet han horittene, så de drev dem bort og bosatte sig der i deres sted, og siden har de bodd der til denne dag.
Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
23 Likedan gikk det med avittene, som bodde i landsbyene like til Gasa; de blev ødelagt av kaftorerne, som kom fra Kaftor og bosatte sig der i deres sted.
Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
24 Gjør eder rede, bryt op og gå over Arnon-åen! Se, jeg har gitt amoritten Sihon, kongen i Hesbon, og hans land i din hånd; gå nu i gang med å innta det, og gi dig i strid med ham!
“Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
25 Fra denne dag vil jeg la redsel for dig og frykt for dig komme over alle folk under himmelen; alle som får høre om dig, skal skjelve og beve for dig.
Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
26 Da sendte jeg bud fra ørkenen Kedemot til Sihon, kongen i Hesbon, med fredelige ord og lot si:
Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
27 La mig få dra gjennem ditt land! Jeg vil holde mig på veien, jeg vil ikke vike av, hverken til høire eller til venstre.
“Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
28 Mat kan du selge mig for penger, så jeg kan ete, og vann kan du også gi mig for penger, så jeg kan drikke. La mig bare få dra igjennem på min fot,
Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
29 likesom Esaus barn, som bor i Se'ir, og moabittene, som bor i Ar, gav mig lov til å gjøre - så jeg kan gå over Jordan til det land som Herren vår Gud gir oss.
gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
30 Men Sihon, kongen i Hesbon, vilde ikke la oss dra gjennem sitt land; for Herren din Gud hadde forherdet hans sinn og gjort hans hjerte hårdt for å gi ham i din hånd, som det kan sees på denne dag.
Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
31 Og Herren sa til mig: Se, nu gir jeg Sihon og hans land i din vold; gå nu du i gang med å innta det, så du får hans land i eie.
Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
32 Og Sihon og hele hans folk drog ut mot oss til strid, til Jahas.
Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
33 Og Herren vår Gud gav ham i vår vold, og vi slo ham og hans sønner og alt hans folk ihjel.
Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
34 Og vi inntok dengang alle hans byer og slo hver by med bann, menn og kvinner og barn; vi lot ikke nogen bli tilbake eller slippe unda.
Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
35 Bare feet tok vi til bytte foruten hærfanget fra byene som vi inntok.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
36 Fra Aroer, som ligger ved bredden av Arnon-åen, og fra byen i dalen og like til Gilead var der ikke en by hvis murer var oss for høie; Herren vår Gud gav dem alle i vår vold.
Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
37 Men Ammons barns land kom du ikke nær, hverken landet langsmed Jabbok-åen eller byene i fjellene eller noget annet som Herren vår Gud hadde forbudt oss å ta.
Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.