< 5 Mosebok 11 >
1 Så skal du da elske Herren din Gud og ta vare på det han vil ha varetatt, hans lover og hans forskrifter og hans bud, alle dager.
Ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ sì pa ìfẹ́ rẹ̀, ìlànà rẹ̀, òfin rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ ní ìgbà gbogbo.
2 Og I skal idag - for det er ikke eders barn jeg taler med, de som ikke kjenner det og ikke har sett det - komme I hu Herrens, eders Guds optuktelse, hans storhet, hans sterke hånd og hans utrakte arm
Ẹ rántí lónìí pé, kì í ṣe àwọn ọmọ yín, ni ó rí ìbáwí Olúwa Ọlọ́run yín; títóbi rẹ̀, ọwọ́ agbára rẹ̀, nína ọwọ́ rẹ̀;
3 og hans tegn og gjerninger, som han gjorde i Egypten med Farao, kongen i Egypten, og med hele hans land,
iṣẹ́ àmì rẹ̀ àti ohun tí ó ṣe ní àárín àwọn ará Ejibiti, sí Farao ọba Ejibiti àti gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ̀.
4 og hvad han gjorde med egypternes hær, med deres hester og vogner, da han lot det Røde Havs vann strømme sammen over dem mens de forfulgte eder, og lot dem gå til grunne, så ingen har sett dem mere til denne dag,
Ohun tí ó ṣe sí àwọn jagunjagun Ejibiti, sí kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin rẹ̀: bí ó ṣe rì wọ́n sínú Òkun Pupa, bí wọ́n ṣe ń lé e yín tí Olúwa fi pa wọ́n run pátápátá títí di òní olónìí yìí.
5 og hvad han gjorde med eder i ørkenen inntil I kom til dette sted,
Kì í ṣe àwọn ọmọ yín ni ó rí ohun tí ó ṣe fún un yín ní aginjù, títí ẹ fi dé ìhín yìí,
6 og hvad han gjorde med Datan og Abiram, sønnene til Eliab, Rubens sønn, da jorden lukket op sin munn og midt iblandt hele Israel slukte dem og deres hus og deres telter og hvert liv som var i følge med dem;
ohun tí ó ṣe sí Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, ẹ̀yà Reubeni, bí ilẹ̀ ti lanu ní ojú gbogbo ará Israẹli tí ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ìdílé wọn, gbogbo àgọ́ ọ wọn àti gbogbo ohun alààyè tí ó jẹ́ tiwọn.
7 for I har selv med egne øine sett alle de storverk Herren har gjort.
Ṣùgbọ́n ojú u yín gan an ni ó rí gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí tí Olúwa ti ṣe.
8 Ta da vare på alle de bud jeg gir dig idag, forat I kan bli sterke og komme inn og eie det land I nu drar over til og skal ta i eie,
Nítorí náà, ẹ kíyèsi gbogbo àṣẹ tí mo ń fún yín lónìí, kí ẹ ba à lè lágbára àti lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí ẹ ó la Jordani kọjá lọ.
9 og forat I kan få leve lenge i det land Herren tilsvor eders fedre å ville gi dem og deres ætt, et land som flyter med melk og honning.
Kí ẹ ba à lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa ti búra fún àwọn baba ńlá a yín, láti fún àwọn àti àwọn ọmọ wọn: ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
10 For det land du kommer inn i og skal ta i eie, er ikke som Egyptens land, som I drog ut fra, hvor du sådde din sæd og så vannet jorden med din fot som en kålhave.
Ilẹ̀ tí ẹ̀ ń wọ̀ lọ láti gbà kò rí bí ilẹ̀ Ejibiti, níbi tí ẹ ti wá, níbi tó jẹ́ wí pé ẹsẹ̀ yín ni ẹ fi ń rìn lọ bomirin irúgbìn tí ẹ gbìn bí oko ẹ̀fọ́.
11 Men det land I drar over til og skal ta i eie, er et land med fjell og daler, som drikker vann av himmelens regn,
Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí ẹ ó la Jordani kọjá láti gbà, jẹ́ ilẹ̀ olókè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ tí òjò ń rọ̀ sí latọ̀run.
12 et land som Herren din Gud bærer omsorg for; alltid hviler Herrens, din Guds øine på det, fra årets begynnelse til dets ende.
Ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń mójútó ni, ojú Olúwa Ọlọ́run yín sì ń fi ìgbà gbogbo wà lórí rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún dé òpin ọdún.
13 Dersom I nu er lydige mot mine bud, som jeg gir eder idag, så I elsker Herren eders Gud og tjener ham av alt eders hjerte og av all eders sjel,
Nítorí náà, bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ tí mo fún un yín lónìí tọkàntọkàn: tí ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì sìn ín, pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn yín:
14 da vil jeg gi eders land regn i rette tid, høstregn og vårregn, og du skal samle i hus ditt korn og din most og din olje,
nígbà náà, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ ẹ yín lákòókò rẹ̀, àti òjò àkọ́rọ̀ àti ti àrọ̀kẹ́yìn, kí ẹ ba à lè kórè oúnjẹ yín wọlé àní wáìnì tuntun àti òróró.
15 og for ditt fe vil jeg gi dig gress på dine marker, og du skal ete og bli mett.
Èmi yóò mú kí koríko hù lórí ilẹ̀ yín fún àwọn ohun ọ̀sìn in yín, ẹ ó sì jẹ, ẹ ó sì yó.
16 Ta eder i vare at eders hjerte ikke dåres, så I viker av og dyrker andre guder og tilbeder dem,
Ẹ ṣọ́ra, kí a má ba à tàn yín jẹ láti yípadà kí ẹ sì sin ọlọ́run mìíràn àti láti máa foríbalẹ̀ fún wọn.
17 og Herrens vrede optendes mot eder, og han lukker himmelen til, så det ikke kommer regn, og jorden ikke gir sin grøde, og I hastig blir utryddet av det gode land Herren gir eder.
Nígbà náà ni ìbínú Olúwa yóò sì ru sí i yín, Òun yóò ti ìlẹ̀kùn ọ̀run kí òjò má ba à rọ̀, ilẹ̀ kì yóò sì so èso kankan, ẹ ó sì ṣègbé ní ilẹ̀ rere tí Olúwa fi fún un yín.
18 Så legg eder da disse mine ord på hjerte og på sinne og bind dem som et tegn på eders hånd og la dem være som en minneseddel på eders panne
Ẹ fi gbogbo ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí sí àyà a yín, àti ọkàn an yín, ẹ so wọ́n bí àmì sórí ọwọ́ yín, kí ẹ sì so wọ́n mọ́ iwájú orí yín.
19 og lær eders barn dem ved å tale om dem når du sitter i ditt hus, og når du går på veien, og når du legger dig, og når du står op,
Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín, ẹ máa sọ̀rọ̀ nípa wọn bí ẹ bá jókòó nínú ilé, àti ní ojú ọ̀nà bí ẹ bá ń rìn lọ, bí ẹ bá sùn àti bí ẹ bá jí.
20 og skriv dem på dørstolpene i ditt hus og på dine porter,
Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ.
21 forat eders og eders barns dager må bli mange i det land som Herren tilsvor eders fedre å ville gi dem, og I må leve der like så lenge som himmelen hvelver sig over jorden.
Kí ọjọ́ ọ yín àti ti àwọn ọmọ yín lè pọ̀ ní ilẹ̀ tí Olúwa ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá a yín, ní ìwọ̀n ìgbà tí ọ̀run wà lókè tí ayé sì ń bẹ ní ìsàlẹ̀.
22 For tar I vare på alle disse bud som jeg byder eder å holde, så I elsker Herren eders Gud og vandrer på alle hans veier og holder fast ved ham,
Bí ẹ bá fi ara balẹ̀ kíyèsi àwọn òfin tí mo ń fún un yín, láti tẹ̀lé, láti fẹ́ Olúwa Ọlọ́run yín, láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti láti dìímú ṣinṣin:
23 da skal Herren drive ut alle disse folk for eder, og I skal jage bort folk som er større og tallrikere enn I selv.
Olúwa yóò sì lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí kúrò níwájú u yín. Ẹ ó sì gba orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì tóbi jù yín lọ.
24 Hvert sted I treder på med eders fot, skal høre eder til; fra ørkenen og Libanon, fra den store elv, elven Frat, og til havet i vest skal eders landemerker nå.
Gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀ ni yóò jẹ́ tiyín, ilẹ̀ ẹ yín yóò gbilẹ̀ láti aginjù dé Lebanoni, àti láti odò Eufurate dé Òkun Ńlá.
25 Ingen skal kunne stå sig imot eder; redsel for eder og frykt for eder skal Herren eders Gud la komme over hele det land I treder på, således som han har sagt til eder.
Kò sí ẹni náà tí yóò lè kò yín lójú ìjà, Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi ẹ̀rù àti ìwárìrì i yín sórí gbogbo ilẹ̀ náà bí ó ti ṣèlérí fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá lọ.
26 Se, jeg legger idag frem for eder velsignelse og forbannelse:
Ẹ kíyèsi i, mo fi ìbùkún àti ègún lélẹ̀ níwájú u yín lónìí:
27 velsignelsen, så sant I lyder Herrens, eders Guds bud, som jeg gir eder idag,
ìbùkún ni, bí ẹ bá pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí mo ń fún un yín lónìí mọ́.
28 og forbannelsen, dersom I ikke lyder Herrens, eders Guds bud, men viker av fra den vei jeg idag byder eder å vandre på, og følger andre guder, som I ikke kjenner.
Ègún ni, bí ẹ bá ṣàìgbọ́ràn, sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì yapa kúrò ní ọ̀nà tí mo ti là sílẹ̀ fún yín lónìí, nípa títẹ̀lé ọlọ́run mìíràn, tí ẹ kò tí ì mọ̀.
29 Og når Herren din Gud fører dig inn i det land du nu drar inn i og skal ta i eie, da skal du lyse velsignelsen på fjellet Garisim og forbannelsen på fjellet Ebal.
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti mú un yín dé ilẹ̀ náà tí ẹ ń wọ̀ láti gbà, kí ẹ kéde àwọn ìbùkún náà ní orí òkè Gerisimu, kí ẹ sì kéde àwọn ègún ní orí òkè Ebali.
30 Disse to fjell ligger, som i vet, på hin side Jordan bortenfor veien som bærer mot vest, i kana'anittenes land, de som bor i ødemarken midt imot Gilgal, ved Mores terebintelund.
Bí ẹ ti mọ̀ pé àwọn òkè wọ̀nyí wà ní ìkọjá a Jordani ní apá ìwọ̀-oòrùn lójú ọ̀nà lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó More, ní ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, tí wọ́n ń gbé ní aginjù, ni agbègbè Gilgali.
31 For nu går I over Jordan for å komme inn og ta det land i eie som Herren eders Gud gir eder, og I skal ta det i eie og bo der.
Ẹ ti ṣetán láti la Jordani kọjá láti lè gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín. Nígbà tí ẹ bá gbà á, tí ẹ bá sì ń gbé ibẹ̀,
32 Akt da vel på at I holder alle de bud og lover som jeg idag legger frem for eder!
ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà àti òfin tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.