< Amos 3 >

1 Hør dette ord som Herren har talt mot eder, Israels barn, mot hele den ætt jeg har ført op fra Egyptens land:
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 Eder alene har jeg villet kjennes ved blandt alle jordens ætter; derfor vil jeg hjemsøke eder for alle eders misgjerninger.
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Går vel to sammen uten at de har avtalt det med hverandre?
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Brøler vel løven i skogen uten at den har funnet noget rov? Lar vel ungløven sin røst høre fra sin hule uten at den har fanget noget?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Faller vel fuglen i en snare på marken uten at det er satt nogen snare for den? Spretter vel snaren op fra marken uten at den fanger noget?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 Eller støtes det vel i basun i en by uten at folket forferdes? Eller skjer det vel en ulykke i en by uten at Herren har gjort det?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 For Herren, Israels Gud, gjør ikke noget uten at han har åpenbaret sitt lønnlige råd for sine tjenere profetene.
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Når løven brøler, hvem skulde ikke da reddes? Når Herren, Israels Gud, taler, hvem skulde ikke da profetere?
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Rop ut i palassene i Asdod og i palassene i Egyptens land og si: Samle eder på Samaria-fjellene og se hvor stor forvirring det er der inne, og hvor megen undertrykkelse der råder!
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 De vet ikke å gjøre det som rett er, sier Herren, de som dynger op vold og ødeleggelse i sine palasser.
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 Derfor sier Herren, Israels Gud, så: Fiender skal komme og omringe hele landet. Og de skal styrte ned din borg, så du mister ditt vern, og dine palasser skal bli plyndret.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Så sier Herren: Likesom en hyrde berger to leggeben eller en ørelapp av løvens gap, således skal Israels barn berges, de som sitter i Samaria i sofahjørnet og på damaskes hynder.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 Hør og vidne mot Jakobs hus, sier Herren, Israels Gud, hærskarenes Gud:
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 På den dag jeg hjemsøker Israel for dets misgjerninger, da vil jeg hjemsøke Betels altere, så alterhornene blir avhugget og faller til jorden,
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
15 og jeg vil sønderslå både vinterhusene og sommerhusene, og elfenbenshusene skal gå til grunne, og mange hus rives bort, sier Herren.
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.

< Amos 3 >