< 2 Kongebok 22 >
1 Josias var åtte år gammel da han blev konge, og han regjerte en og tretti år i Jerusalem; hans mor hette Jedida; hun var datter av Adaja og var fra Boskat.
Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
2 Han gjorde hvad rett var i Herrens øine, og vandret i alle deler på sin far Davids vei; han vek ikke av hverken til høire eller til venstre.
Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
3 I kong Josias' attende år hendte det at kongen sendte statsskriveren Safan, sønn av Asalja, Mesullams sønn, til Herrens hus og sa:
Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
4 Gå op til ypperstepresten Hilkias og be ham telle sammen alle de penger som er kommet inn til Herrens hus, og som vokterne ved dørtreskelen har samlet inn hos folket,
“Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
5 og overgi dem til dem som forestår arbeidet og har tilsyn med Herrens hus, forat de igjen kan gi dem til dem som utfører arbeidet - dem som arbeider i Herrens hus for å bøte husets brøst,
Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
6 til tømmermennene og bygningsmennene og murerne, og likeså til innkjøp av tre og hugne stener for å sette huset i stand.
Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
7 Men det skal ikke holdes regnskap med dem for de penger som overgis til dem; for de farer redelig frem.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
8 Da sa ypperstepresten Hilkias til statsskriveren Safan: Jeg har funnet lovboken i Herrens hus. Og Hilkias gav boken til Safan, og han leste den.
Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
9 Så kom statsskriveren Safan tilbake til kongen og meldte: Dine tjenere har tømt ut de penger som fantes i huset, og overgitt dem til dem som forestår arbeidet og har tilsyn med Herrens hus.
Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
10 Og statsskriveren Safan fortalte kongen at presten Hilkias hadde gitt ham en bok. Og Safan leste den for kongen.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
11 Da kongen hørte lovbokens ord, sønderrev han sine klær.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
12 Og kongen bød presten Hilkias og Akikam, Safans sønn, og Akbor, Mikajas sønn, og statsskriveren Safan og kongens tjener Asaja:
Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
13 Gå og spør Herren for mig og for folket og for hele Juda om det som står i denne bok som nu er funnet! For stor er Herrens vrede, som er optendt mot oss fordi våre fedre ikke har vært lydige mot denne boks ord og ikke gjort alt det som er oss foreskrevet.
“Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
14 Så gikk presten Hilkias og Akikam og Akbor og Safan og Asaja til profetinnen Hulda, hustru til klædeskammervokteren Sallum, sønn av Tikva, Karkas' sønn; hun bodde Jerusalem i den annen bydel; og de talte med henne.
Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
15 Hun sa til dem: Så sier Herren, Israels Gud: Si til den mann som har sendt eder til mig:
Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
16 Så sier Herren: Se, jeg fører ulykke over dette sted og dets innbyggere - alt det som står i den bok som Judas konge har lest,
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
17 fordi de har forlatt mig og brent røkelse for andre guder for å vekke min harme med alt sine henders verk; min vrede er optendt mot dette sted, og den skal ikke utslukkes.
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
18 Og til Judas konge, som sendte eder for å spørre Herren, til ham skal I si således: Så sier Herren, Israels Gud: Du har nu hørt disse ord;
Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
19 men fordi ditt hjerte blev bløtt, og du ydmyket dig for Herrens åsyn da du hørte hvad jeg har talt mot dette sted og dets innbyggere - at de skal bli til ødeleggelse og forbannelse - og fordi du sønderrev dine klær og gråt for mitt åsyn, så har også jeg hørt, sier Herren.
Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
20 Derfor vil jeg samle dig til dine fedre, og du skal samles med dem i din grav i fred, og dine øine skal ikke se all den ulykke jeg vil føre over dette sted. Med dette svar kom de tilbake til kongen.
Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.