< 2 Kongebok 20 >

1 Ved den tid blev Esekias dødssyk; da kom profeten Esaias, Amos' sønn, inn til ham og sa til ham: Så sier Herren: Beskikk ditt hus! For du skal dø og ikke leve lenger.
Ní ayé ìgbà wọ̀n-ọn-nì Hesekiah ṣe àìsàn ó sì wà ní ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: tún ilé rẹ ṣe, ṣùgbọ́n ìwọ yóò kú; o kò ní í gbádùn.”
2 Da vendte han sitt ansikt mot veggen og bad til Herren og sa:
Hesekiah yí ojú rẹ̀ padà sí ògiri ó sì gbàdúrà sí Olúwa pé,
3 Akk, Herre! kom dog i hu at jeg har vandret for ditt åsyn i trofasthet og med helt hjerte og gjort hvad godt er i dine øine! Og Esekias gråt høit.
“Rántí, Olúwa mi, bí èmi ṣe rìn níwájú rẹ àti pẹ̀lú bí èmi ṣe jẹ́ olóòtítọ́ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn ìfọkànsìn mi tí èmi sì ti ṣe ohun tí ó dára níwájú rẹ.” Hesekiah sọkún kíkorò.
4 Men Esaias var ennu ikke kommet ut av den indre by, da kom Herrens ord til ham, og det lød så:
Kí ó tó di wí pé Isaiah jáde kúrò ní àárín àgbàlá ààfin, ọ̀rọ̀ Olúwa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé:
5 Vend tilbake og si til Esekias, mitt folks fyrste: Så sier Herren, din far Davids Gud: Jeg har hørt din bønn, jeg har sett dine tårer. Se, jeg vil helbrede dig; på den tredje dag skal du gå op til Herrens hus.
“Lọ padà kí o sì sọ fún Hesekiah, olórí àwọn ènìyàn mi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Dafidi sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò wò ọ́ sàn. Ní ọjọ́ kẹta láti ìsinsin yìí, ìwọ yóò lọ sókè ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
6 Og jeg vil legge femten år til din alder, og jeg vil redde dig og denne by av assyrerkongens hånd, og jeg vil verne denne by for min skyld og for min tjener Davids skyld.
Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ. Èmi yóò sì gbà ọ́ àti ìlú ńlá yìí láti ọwọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí nítorí ti èmi tìkára mi àti nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi.’”
7 Og Esaias sa: Hent en fikenkake! Så hentet de en fikenkake og la den på bylden, og han frisknet til.
Nígbà náà ni Isaiah wí pé, “Mú odidi ọ̀pọ̀tọ́.” Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fi lé oówo náà, ara rẹ̀ sì yá.
8 Og Esekias sa til Esaias: Hvad skal jeg ha til tegn på at Herren vil helbrede mig, så jeg den tredje dag kan gå op til Herrens hus?
Hesekiah sì béèrè lọ́wọ́ Isaiah pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé Olúwa yóò wò mí sàn àti wí pé èmi yóò lọ sókè sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa láti ọjọ́ kẹta títí di òní?”
9 Esaias svarte: Dette skal du ha til tegn fra Herren på at Herren vil holde det han har lovt: Skal skyggen gå ti streker frem, eller skal den gå ti streker tilbake?
Isaiah dáhùn pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa fún ọ wí pé Olúwa yóò ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí: kí òjìji lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá, tàbí kí ó padà lọ ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá?”
10 Esekias sa: Det er en lett sak for skyggen å strekke sig ti streker frem; nei, skyggen skal gå ti streker tilbake.
“Ó jẹ́ ohun ìrọ̀rùn fún òjìji láti lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá,” Hesekiah wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí ó lọ padà ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá.”
11 Da ropte profeten Esaias til Herren; og han lot skyggen gå tilbake de streker som den var gått ned på Akas' solskive - ti streker.
Nígbà náà wòlíì Isaiah ké pe Olúwa, Olúwa sì ṣe òjìji padà sí ìgbésẹ̀ mẹ́wàá ó ti sọ̀kalẹ̀ ní òpópó ọ̀nà Ahasi.
12 På den tid sendte Berodak Baladan, Baladans sønn, kongen i Babel, brev og gaver til Esekias; for han hadde hørt at Esekias hadde vært syk.
Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli ránṣẹ́ ìwé àti ẹ̀bùn sí Hesekiah nítorí tí ó ti gbọ́ nípa àìsàn Hesekiah.
13 Da Esekias hadde hørt på dem, lot han dem få se hele sitt skattkammer, sølvet og gullet og krydderiene og den kostbare olje og hele sitt våbenhus og alt det som fantes i hans skattkammere; det var ikke den ting Esekias ikke lot dem få se i sitt hus og i hele sitt rike.
Hesekiah gba ìránṣẹ́ náà ó sì fihàn wọ́n, gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé ìṣúra—sílífà, àti wúrà, àti tùràrí, àti òróró dáradára àti ìhámọ́ra àti gbogbo èyí tí a rí lára ìṣúra rẹ̀. Kò sí nǹkan nínú ààfin rẹ̀ tàbí nínú gbogbo ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò sì fihàn wọ́n.
14 Da kom profeten Esaias til kong Esekias og sa til ham: Hvad sa disse menn, og hvorfra kommer de til dig? Esekias svarte: De er kommet fra et land langt borte, fra Babel.
Nígbà náà Isaiah wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?” “Láti ìlú jíjìn réré,” Hesekiah dáhùn. “Wọ́n wá láti Babeli.”
15 Og han sa: Hvad fikk de se i ditt hus? Esekias svarte: Alt det som er i mitt hus, har de fått se; det var ikke den ting jeg ikke lot dem lå se i mine skattkammer.
Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?” “Wọ́n rí gbogbo nǹkan ní ààfin mi,” Hesekiah wí pé. “Kò sí nǹkan kan lára àwọn ìṣúra tí èmi kò fihàn wọ́n.”
16 Da sa Esaias til Esekias: Hør Herrens ord!
Nígbà náà Isaiah wí fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
17 Se, de dager kommer da alt det som er i ditt hus, og alle de skatter dine fedre har samlet like til denne dag, skal føres bort til Babel; det skal ikke bli nogen ting tilbake, sier Herren.
àkókò náà yóò sì dé nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà ní ààfin àti gbogbo ohun tí baba rẹ̀ ti kó pamọ́ sókè títí di ọjọ́ òní, wọn yí ó gbe lọ sí Babeli, kò sí ohun tí yóò kù, ni Olúwa wí.
18 Og blandt dine sønner som skal utgå av dig, som du skal avle, skal det være nogen som blir tatt til hoffmenn i kongen av Babels palass.
Àti díẹ̀ nínú àwọn ìran rẹ, ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀, tí wọn yóò bí fún ọ, ni wọn yóò kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà ní ààfin ọba Babeli.”
19 Da sa Esekias til Esaias: Det Herrens ord som du har talt, er godt. Så sa han: Er det ikke så, når det skal være fred og trygghet i mine dager?
Hesekiah wí fún Isaiah pé. “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò wí pé, “Kò ha dára àlàáfíà àti òtítọ́ ní ọjọ́ ayé mi?”
20 Hvad som ellers er å fortelle om Esekias og om alle hans store gjerninger, og hvorledes han gjorde dammen og vannledningen og førte vannet inn i byen, det er opskrevet i Judas kongers krønike.
Ní ti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tókù nípa ìjọba Hesekiah, gbogbo ohun tí ó ṣe tan àti bí ó ti ṣe adágún omi àti ọ̀nà omi náà nípa èyí tí ó gbé wá omi sínú ìlú ńlá, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìgbésẹ̀ ayé àwọn ọba àwọn Juda?
21 Og Esekias la sig til hvile hos sine fedre, og hans sønn Manasse blev konge i hans sted.
Hesekiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀: Manase ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 2 Kongebok 20 >