< ULevi 21 >

1 INkosi yasisithi kuMozisi: Tshono kubapristi, amadodana kaAroni, uthi kubo: Kakungabi khona ozingcolisayo ngofileyo phakathi kwabantu bakibo,
Olúwa sọ fún Mose wí pe, “Bá àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni sọ̀rọ̀, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú wọn kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí àwọn ènìyàn wọn tí ó kù.
2 ngaphandle kwesihlobo sakhe, esiseduze laye, ngonina, langoyise, langendodana yakhe, langendodakazi yakhe, langomfowabo,
Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe àwọn tí ó súnmọ́ ọn bí ìyá rẹ̀, baba rẹ̀, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, àti arákùnrin rẹ̀.
3 langodadewabo intombi emsulwa, eseduze laye, engazange ibe ngeyendoda; angazingcolisa ngayo.
Tàbí fún arábìnrin rẹ̀ tí kò ì tí ì wọ ilé ọkọ tí ó ń gbé lọ́dọ̀ rẹ̀. Nítorí tí arábìnrin bẹ́ẹ̀, ó lè sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
4 Kayikuzingcolisa, eyisikhulu phakathi kwabantu bakibo, ukuzingcolisa.
Nítorí tí ó jẹ́ olórí, òun kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ ba ara rẹ̀ jẹ́ láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
5 Kabayikwenza impabanga ekhanda labo, bangageli igumbi lodevu lwabo, bangacabi inhlanga enyameni yabo.
“‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ fá irun orí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ rẹ́ irùngbọ̀n rẹ̀. Kò gbọdọ̀ fi abẹ ya ara rẹ̀ láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
6 Bazakuba ngcwele kuNkulunkulu wabo, bangeyisi ibizo likaNkulunkulu wabo. Ngoba banikela iminikelo yeNkosi eyenziwe ngomlilo, ukudla kukaNkulunkulu wabo. Ngakho bazakuba ngcwele.
Wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún Ọlọ́run, kí wọ́n má ba à sọ orúkọ Ọlọ́run wọn di àìmọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń fi iná sun ẹbọ sí Olúwa wọn, ti ó jẹ oúnjẹ Ọlọ́run wọn. Nítorí náà wọn gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́.
7 Kabayikuthatha owesifazana oyisifebe kumbe ongcolileyo, njalo kabayikuthatha owesifazana olahlwe yindoda yakhe; ngoba ungcwele kuNkulunkulu wakhe.
“‘Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ fẹ́ panṣágà tàbí obìnrin tí ó ti fi ọkùnrin ba ara rẹ̀ jẹ́ tàbí obìnrin tí ọkọ rẹ̀ ti kọ̀sílẹ̀ nítorí pé àwọn àlùfáà jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run wọn.
8 Ngakho uzamngcwelisa, ngoba unikela ukudla kukaNkulunkulu wakho. Uzakuba ngcwele kuwe, ngoba mina Nkosi elingcwelisayo ngingcwele.
Àwọn ènìyàn gbọdọ̀ máa kà wọ́n sí mímọ́, nítorí pé àwọn ni wọ́n ń rú ẹbọ oúnjẹ fún mi. Èmi ni Olúwa, mo jẹ́ mímọ́, mo sì ya àwọn ènìyàn mi sí mímọ́.
9 Lendodakazi yaloba nguwuphi umpristi, uba izingcolisa ngokuphinga, iyamngcolisa uyise; izatshiswa ngomlilo.
“‘Bí ọmọbìnrin àlùfáà kan bá fi iṣẹ́ àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ó dójútì baba rẹ̀, iná ni a ó dá sun ún.
10 Lompristi omkhulu phakathi kwabafowabo, okuthelwe ekhanda lakhe amafutha okugcoba, lowehlukaniselwa ukuthi embathe izembatho, kayikuvumela ukuthi ikhanda lakhe lembulwe, angadabuli izembatho zakhe;
“‘Lẹ́yìn tí a ti fi òróró yan olórí àlùfáà láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, tí a sì ti fi àmì òróró yàn án láti máa wọ aṣọ àlùfáà, ó gbọdọ̀ tọ́jú irun orí rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fa aṣọ rẹ̀ ya láti fihàn pé òun wà ní ipò ọ̀fọ̀.
11 angayi lakusiphi isidumbu, angazingcolisi ngoyise loba ngonina;
Kí ó ma ṣe wọlé tọ òkú lọ, kí ó má ṣe sọ ará rẹ di àìmọ́ nítorí baba tàbí nítorí ìyá rẹ̀.
12 angaphumi endlini engcwele, angangcolisi indlu engcwele kaNkulunkulu wakhe, ngoba umqhele wamafutha okugcoba kaNkulunkulu wakhe uphezu kwakhe. NgiyiNkosi.
Kò gbọdọ̀ kúrò ní ibi mímọ́ Ọlọ́run tàbí kí ó sọ ọ́ di aláìmọ́ torí pé a ti fi ìfòróróyàn Ọlọ́run yà á sí mímọ́. Èmi ni Olúwa.
13 Njalo yena uzathatha umfazi ebuntombini bakhe.
“‘Ọmọbìnrin tí yóò fẹ́ gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí kò mọ ọkùnrin rí.
14 Umfelokazi, kumbe olahliweyo, loba isifebe esingcolisiweyo, laba kangabathathi. Kodwa uzathatha intombi emsulwa ebantwini bakibo ibe ngumkakhe,
Kò gbọdọ̀ fẹ́ opó tàbí ẹni tí a kọ̀sílẹ̀ tàbí obìnrin tí ó ti fi àgbèrè ba ara rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n kí ó fẹ́ obìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí, láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 njalo angangcolisi inzalo yakhe phakathi kwabantu bakibo. Ngoba ngiyiNkosi emngcwelisayo.
Kí ó má ba à sọ di aláìmọ́ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀. Èmi ni Olúwa tí ó sọ ọ́ di mímọ́.’”
16 INkosi yasikhuluma kuMozisi isithi:
Olúwa sì bá Mose sọ̀rọ̀ pé,
17 Khuluma kuAroni usithi: Loba ngubani owenzalo yakho ezizukulwaneni zabo okulesici kuye kangasondeli ukunikela ukudla kukaNkulunkulu wakhe.
“Sọ fún Aaroni pé, ‘Ẹnikẹ́ni nínú irú-ọmọ rẹ̀ ní ìran-ìran wọn, tí ó bá ní ààrùn kan, kí ó má ṣe súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ ohun jíjẹ sí Ọlọ́run rẹ̀.
18 Ngoba loba nguwuphi umuntu okulesici kuye angasondeli, umuntu oyisiphofu, kumbe oyisiqhuli, kumbe olimele ebusweni, kumbe olesitho eselulekileyo,
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi ẹbọ náà. Kò gbọdọ̀ sí afọ́jú tàbí arọ, alábùkù ara tàbí àwọn tí ara wọn kò pé.
19 kumbe umuntu okulokwephuka konyawo kuye, kumbe ukwephuka kwesandla,
Kò gbọdọ̀ sí ẹnikẹ́ni yálà ó rọ lápá lẹ́sẹ̀,
20 kumbe olesifumbu, kumbe ongumuthwa, kumbe olomntwana elihlweni lakhe, kumbe olentembuzane, kumbe oloqweqwe olulumayo, loba olimele emasendeni.
tàbí tí ó jẹ́ abuké, tàbí tí ó ya aràrá tàbí tí ó ní àìsàn ojú tàbí tí ó ní egbò tàbí tí a ti yọ nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀.
21 Kakulamuntu owenzalo kaAroni umpristi okukuye isici ozasondela ukunikela iminikelo yeNkosi eyenziwe ngomlilo; kulesici kuye, angasondeli ukunikela ukudla kukaNkulunkulu wakhe.
Ẹnikẹ́ni tí ó ní àbùkù nínú irú-ọmọ Aaroni àlùfáà kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ tí fi iná sun sí Olúwa. Nítorí pé ó jẹ́ alábùkù, kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí láti rú ẹbọ àkàrà sí Ọlọ́run rẹ̀.
22 Angadla ukudla kukaNkulunkulu wakhe, ezintweni ezingcwelengcwele lezintweni ezingcwele,
Ó lè jẹ́ oúnjẹ Ọlọ́run rẹ̀ tàbí èyí tí ó mọ́ jùlọ, ṣùgbọ́n torí pé ó ní àbùkù kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi aṣọ títa tàbí pẹpẹ.
23 kodwa angezi kulo iveyili, angasondeli elathini, ngoba kulesici kuye, ukuze angangcolisi izindlu zami ezingcwele. Ngoba ngiyiNkosi ebangcwelisayo.
Nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀ yóò ba ibi mímọ́ mi jẹ́ torí pé, Èmi Olúwa ló ti sọ wọ́n di mímọ́.’”
24 UMozisi wasekhuluma lokho kuAroni, lakumadodana akhe, lakubo bonke abantwana bakoIsrayeli.
Wọ̀nyí ni àwọn ohun tí Mose sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ Aaroni àti gbogbo ọmọ Israẹli.

< ULevi 21 >