< UJoshuwa 2 >

1 UJoshuwa indodana kaNuni wasethuma eseShithimi amadoda amabili aba zinhloli ensitha, esithi: Hambani libone ilizwe, leJeriko. Asehamba, ayafikela endlini yomfazi, iwule, obizo lakhe lalinguRahabi, alala khona.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Kwatshelwa inkosi yeJeriko kwathiwa: Khangela, kufike lapha ebusuku amadoda abantwana bakoIsrayeli ukuhlola ilizwe.
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Inkosi yeJeriko yasithumela kuRahabi isithi: Khupha lawo amadoda afikele kuwe, angena endlini yakho, ngoba azehlola ilizwe lonke.
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Kodwa owesifazana wayethethe lawomadoda amabili, wawafihla, wakhuluma kanje: Afikile kimi amadoda, kodwa bengingazi lapha avela khona.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 Kwasekusithi sekuzavalwa isango lapho sekumnyama amadoda aphuma. Kangikwazi lapho amadoda aye khona; axhumeni ngokuphangisa liwalandele, ngoba lizawafica.
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 Kodwa yena wayewenyusele ephahleni, wawafihla phakathi kwamahlanga efilakisi ayechayelwe yena ephahleni.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Amadoda asewaxhuma ngendlela yeJordani aze afika emazibukweni; bavala amasango emva kokuphuma kwabawaxhumayo bewalandela.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Kwathi wona engakalali, yena wenyukela kuwo ephahleni;
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 wasesithi emadodeni: Ngiyazi ukuthi iNkosi ilinikile ilizwe, lokuthi ukwesabeka kwenu kuwele phezu kwethu, lokuthi bonke abakhileyo elizweni bayancibilika ngenxa yobukhona benu.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Ngoba sizwile ukuthi iNkosi yomisa amanzi oLwandle oluBomvu phambi kwenu ekuphumeni kwenu eGibhithe, lalokho elakwenza emakhosini amabili amaAmori ayengaphetsheya kweJordani, uSihoni loOgi elabatshabalalisayo.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Sathi sikuzwa lokho inhliziyo yethu yancibilika, kakusekho isibindi emuntwini ngenxa yenu. Ngoba iNkosi uNkulunkulu wenu, nguye uNkulunkulu emazulwini phezulu lemhlabeni phansi.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Ngakho-ke ake lifunge kimi ngeNkosi, ngoba ngilenzele umusa, lani-ke lizayenzela umusa indlu kababa, linginike isiboniso esiqinileyo,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 ukuthi ligcine bephila ubaba lomama, labanewethu labodadewethu, lakho konke abalakho, likhulule impilo yethu ekufeni.
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Lamadoda athi kuye: Umphefumulo wethu ufe esikhundleni senu, uba ungavezi obala loludaba lwethu. Njalo kuzakuthi lapho iNkosi isisinikile ilizwe, sizakwenzela umusa leqiniso.
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Wasewehlisa ngentambo ewindini, ngoba indlu yakhe yayisemdulini womuzi, wayehlala phezu komduli.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 Wasesithi kuwo: Yanini entabeni, hlezi abaxhumi bahlangane lani, licatshe khona insuku ezintathu, baze babuye abaxhumi, lemva kwalokho lihambe ngendlela yenu.
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Amadoda asesithi kuye: Thina sizakhululeka esifungweni sakho lesi osifungise sona.
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 Khangela, ekufikeni kwethu elizweni uzabophela lintambo yomnxeba obomvu ewindini osehlise ngalo, njalo uzibuthanisele endlini yakho oyihlo lonyoko labanewenu lendlu yonke kayihlo.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Kuzakuthi-ke, loba ngubani ophumela phandle kweminyango yendlu yakho, igazi lakhe lizakuba phezu kwekhanda lakhe, thina-ke sizakuba singelacala. Njalo loba ngubani ozakuba lawe endlini, igazi lakhe lizakuba sekhanda lethu, uba isandla sisiba phezu kwakhe.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Kodwa uba uluveza obala loludaba lwethu, sizakhululeka esifungweni sakho osifungise sona.
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Wasesithi: Njengamazwi enu, kakube njalo. Wasewayekela ehamba, ahamba, wabophela intambo ebomvu ewindini.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 Asehamba afika entabeni, ahlala khona insuku ezintathu, baze babuya abaxhumi, ngoba abaxhumi bawadinga endleleni yonke, kodwa kabawatholanga.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Ngakho amadoda womabili aphenduka asesehla entabeni, achapha, afika kuJoshuwa indodana kaNuni, amtshela konke okuwehleleyo.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Athi kuJoshuwa: Isibili iNkosi ilinikele esandleni sethu ilizwe lonke, futhi-ke bonke abakhileyo belizwe bancibilikile ngenxa yobukhona bethu.
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< UJoshuwa 2 >