< UJeremiya 30 >
1 Ilizwi elafika kuJeremiya livela eNkosini lisithi:
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
2 Itsho njalo iNkosi uNkulunkulu kaIsrayeli, isithi: Zibhalele encwadini wonke amazwi engiwakhulume kuwe.
“Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
3 Ngoba khangela, insuku ziyeza, itsho iNkosi, ukuthi ngizabuyisa ukuthunjwa kwabantu bami uIsrayeli loJuda, itsho iNkosi, ngibabuyisele elizweni engalinika oyise, njalo bazakudla ilifa lalo.
Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
4 Lala ngamazwi iNkosi eyawakhuluma mayelana loIsrayeli lamayelana loJuda.
Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
5 Ngoba itsho njalo iNkosi: Sizwile ilizwi lokuthuthumela; kulokwesaba, hatshi ukuthula.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
6 Ake libuze, libone uba indoda ingabeletha yini? Kungani ngibona ngulowo lalowo owesilisa isandla sakhe siphezu kokhalo lwakhe njengowesifazana obelethayo, lobuso bonke sebuphenduke baba mhlotshana?
Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
7 Maye! ngoba lukhulu lolosuku, okokuthi kalukho olunjengalo; kuyisikhathi sokuhlupheka kukaJakobe, kodwa uzasindiswa kukho.
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
8 Kuzakuthi-ke ngalolosuku, itsho iNkosi yamabandla, ngizakwephula ijogwe lakhe entanyeni yakho, ngiqamule izibopho zakho; labezizwe kabasayikumsebenzisa.
“‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
9 Kodwa bazasebenzela uJehova, uNkulunkulu wabo, loDavida inkosi yabo engizabavusela yena.
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
10 Ngakho wena ungesabi, nceku yami Jakobe, itsho iNkosi; futhi ungatshaywa luvalo, Israyeli; ngoba khangela, ngizakusindisa ukhatshana, lenzalo yakho elizweni lokuthunjwa kwayo; njalo uJakobe uzaphenduka, athule, onwabe, njalo kakho ozamenza esabe.
“‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
11 Ngoba mina ngilawe, itsho iNkosi, ukukusindisa; ngoba ngizakwenza ukuphela kuzo zonke izizwe engikuhlakazele khona, kodwa kangiyikwenza ukuphela kuwe; kodwa ngizakulaya ngokufaneleyo, kangiyikukuyekela ungajeziswanga ngokupheleleyo.
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
12 Ngoba itsho njalo iNkosi: Ukwaphuka kwakho kakwelapheki, isilonda sakho sibi.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
13 Kakho owahlulela udaba lwakho, ukuthi abophe isilonda sakho; kawulamithi epholisayo.
Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
14 Zonke izithandwa zakho zikukhohliwe; kazikudingi; ngoba ngikutshayile ngokutshaya kwesitha, ngokulaywa kololunya, ngenxa yobunengi besiphambeko sakho, izono zakho zandile.
Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
15 Ukhalelani ngokwephuka kwakho? Usizi lwakho kalwelapheki ngenxa yobunengi besiphambeko sakho; ngoba izono zakho zandile, ngizenzile lezizinto kuwe.
Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
16 Ngakho bonke abakudlayo bazadliwa; lazo zonke izitha zakho, zonke zizakuya ekuthunjweni; labakuphangayo bazakuba yimpango, labo bonke abakwemukayo ngizabanikela ekwemukweni.
“‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
17 Ngoba ngizakwenyusela ukuphila kuwe, ngikwelaphe emanxebeni akho, itsho iNkosi; ngoba bakubize ngokuthi oXotshiweyo, besithi: YiZiyoni, kakulamuntu oyidingayo.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
18 Itsho njalo iNkosi: Khangela, ngizabuyisa ukuthunjwa kwamathente kaJakobe, ngihawukele amakhaya abo; njalo umuzi uzakwakhiwa phezu kwenqumbi yawo, lesigodlo sizahlala njengomkhuba waso.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
19 Njalo kuzaphuma kubo ukubonga, lelizwi labathokozayo; njalo ngizabandisa, kabayikuba balutshwana; ngibadumise, kabayikweyiswa.
Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
20 Labantwana babo bazakuba njengendulo, lenhlangano yabo izamiswa phambi kwami; njalo ngizajezisa bonke ababacindezelayo.
Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
21 Lesikhulu sabo sizavela kubo, lombusi wabo uzaphuma evela phakathi kwabo; njalo ngizamsondeza, asondele kimi; ngoba ngubani lowo ongenza inhliziyo yakhe isibambiso sokusondela kimi? itsho iNkosi.
Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
22 Njalo lizakuba ngabantu bami, lami ngibe nguNkulunkulu wenu.
‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
23 Khangelani isivunguzane seNkosi, ukuvutha kuphumile, isivunguzane esikhukhulayo; sizakwehla ngamandla phezu kwekhanda lababi.
Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
24 Ukuvutha kolaka lweNkosi kakuyikudeda, ize ikwenze, ize iqinise injongo zenhliziyo yayo; ekucineni kwezinsuku lizanakana ngalokhu.
Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.