< UJeremiya 22 >

1 Itsho njalo iNkosi: Yehlela endlini yenkosi yakoJuda, ukhulume khona lelilizwi,
Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
2 uthi: Zwana ilizwi leNkosi, wena nkosi yakoJuda, ohlezi esihlalweni sobukhosi sikaDavida, wena, lezinceku zakho, labantu bakho abangena ngalamasango.
‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
3 Itsho njalo iNkosi: Yenzani isahlulelo lokulunga, lophule ophangiweyo esandleni somcindezeli; lingacindezeli, lingenzi udlakela kowezizwe, izintandane, lomfelokazi, njalo lingachithi igazi elingelacala kulindawo.
Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
4 Ngoba uba lisenza linto isibili, khona kuzangena ngamasango alindlu amakhosi ahlalela uDavida esihlalweni sakhe sobukhosi, egade izinqola lamabhiza, yona lenceku zayo labantu bayo.
Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
5 Kodwa uba lingawalaleli lamazwi, ngiyafunga ngami, kutsho iNkosi, ukuthi lindlu izakuba lunxiwa.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
6 Ngoba itsho njalo iNkosi mayelana lendlu yenkosi yakoJuda: UyiGileyadi kimi, inhloko yeLebhanoni; isibili ngizakwenza inkangala, imizi engahlalwayo.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
7 Ngizakulungisela abachithi, ngulowo elezikhali zakhe; njalo bazagamula ikhethelo lemisedari yakho, bayiphosele emlilweni.
Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
8 Lezizwe ezinengi zizadlula kulumuzi, zithi, ngulowo kumakhelwane wakhe: INkosi yenzeleni kanje kulumuzi omkhulu?
“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
9 Khona bazakuthi: Ngenxa yokuthi basidelile isivumelwano seNkosi uNkulunkulu wabo, bakhonza abanye onkulunkulu, babasebenzela.
Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
10 Lingamkhaleli ofileyo, lingamlileli; khalelani kakhulu ohambileyo, ngoba kasayikubuya kumbe abone ilizwe lokuzalwa kwakhe.
Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
11 Ngoba itsho njalo iNkosi mayelana loShaluma indodana kaJosiya, inkosi yakoJuda, owabusa esikhundleni sikaJosiya uyise, owaphuma kulindawo: Kasayikubuya lapha;
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
12 kodwa uzafela endaweni abamthumbele kuyo, kasayikulibona lelilizwe.
Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
13 Maye kowakha indlu yakhe ngokungalungi, lamakamelo akhe aphezulu ngokungaqondanga, osebenzisa umakhelwane wakhe ngeze, angamniki umvuzo wakhe;
“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
14 othi: Ngizazakhela indlu enkulu lamakamelo aphezulu abanzi; azisikele amawindi, yembeswe ngemisedari, iconjwe ngokubomvu.
Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
15 Uzabusa yini, ngoba utshisekela ulaka ugqoke imisedari? Uyihlo kadlanga yini wanatha, wenza isahlulelo lokulunga, kwasekusiba kuhle kuye?
“Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
16 Wehlulela udaba lomyanga loswelayo; khona kwaba kuhle. Lokhu kakusikungazi yini? itsho iNkosi.
Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
17 Kodwa amehlo akho lenhliziyo yakho kakukho kokunye ngaphandle kwemhawini wakho, lekuchitheni igazi elingelacala, lencindezelweni, lekwenzeni udlakela.
“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
18 Ngakho itsho njalo iNkosi mayelana loJehoyakhimi indodana kaJosiya, inkosi yakoJuda: Kabayikumkhalela besithi: Hawu mfowethu! kumbe: Hawu dadewethu! Kabayikumkhalela besithi: Hawu nkosi! loba: Hawu, bukhosi bakhe!
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
19 Uzangcwatshwa ngokungcwatshwa kukababhemi, ehudulwa alahlwe ngaphandle kwamasango eJerusalema.
A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
20 Yenyukela eLebhanoni, umemeze, uphakamise ilizwi lakho eBashani, umemeze useAbarimi, ngoba zonke izithandwa zakho zibhujisiwe.
“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
21 Ngakhuluma lawe ekonwabeni kwakho, kodwa wathi: Kangiyikulalela. Lokhu bekuyindlela yakho kusukela ebutsheni bakho, ukuthi ungalilaleli ilizwi lami.
Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
22 Umoya uzakudla bonke abelusi bakho, lezithandwa zakho zizakuya ekuthunjweni; isibili khona uzakuba lenhloni, uyangeke, ngenxa yobubi bakho bonke.
Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
23 Wena ohlala eLebhanoni, owakhe isidleke phakathi kwemisedari, uzahawukelwa kangakanani ekuzeni kwenhlungu kuwe, ubuhlungu obunjengobowesifazana ohelelwayo.
Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
24 Kuphila kwami, itsho iNkosi, loba uKoniya indodana kaJehoyakhimi, inkosi yakoJuda, ebeyindandatho elophawu esandleni sami sokunene, kanti bengizakuhluthula kuso,
“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
25 ngikunikele esandleni sabadinga impilo yakho, lesandleni salabo owesaba ubuso babo, ngitsho esandleni sikaNebhukadirezari inkosi yeBhabhiloni, lesandleni samaKhaladiya,
Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
26 ngikuphosele phandle kanye lonyoko owakubelethayo, liye kwelinye ilizwe, elingazalelwanga kulo; njalo lizafela khona.
Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
27 Kodwa elizweni abaphakamisa umphefumulo wabo ukubuyela kulo, kabayikubuyela kulo.
Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
28 Lumuntu uKoniya uyisithombe esidelelekayo lesiphahlazekileyo yini? Uyisitsha okungelantokozo kuso yini? Baphoselwani phandle, yena lenzalo yakhe, yebo, bephoselwa elizweni abangalaziyo?
Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
29 Lizwe, lizwe, lizwe, zwana ilizwi leNkosi.
Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
30 Itsho njalo iNkosi: Bhalani lumuntu ukuthi kalabantwana, umuntu ongayikuphumelela ensukwini zakhe; ngoba kakulamuntu enzalweni yakhe ozaphumelela, ohlezi esihlalweni sobukhosi sikaDavida, esabusa koJuda.
Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

< UJeremiya 22 >