< UJeremiya 10 >
1 Zwanini ilizwi iNkosi elikhuluma kini, lina ndlu kaIsrayeli.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
2 Itsho njalo INkosi: Lingafundi indlela yabahedeni, lingatshaywa luvalo ngezibonakaliso zamazulu, ngenxa yokuthi abahedeni bayazesaba.
Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
3 Ngoba imikhuba yabantu iyize; ngoba kuganyulwa isihlahla ehlathini, umsebenzi wezandla zengcitshi, ngehloka.
Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
4 Basicecisa ngesiliva langegolide, basiqinisa ngezipikili langezando, ukuze singazamazami.
Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
5 Zinjengesihlahla selala somsebenzi obaziweyo, kodwa kazikhulumi; kusweleka zithwalwe, ngoba zingehambe; lingazesabi, ngoba zingelakwenza okubi, futhi kakukho ukwenza okuhle kuzo.
Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
6 Njengoba kungekho onjengawe, Nkosi; umkhulu, lebizo lakho likhulu ngobuqhawe.
Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
7 Ngubani ongekwesabe, wena Nkosi yezizwe? ngoba kukufanele. Ngoba phakathi kwabo bonke abahlakaniphileyo bezizwe, lakuyo yonke imibuso yabo, kakho onjengawe.
Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
8 Kodwa kanyekanye banjengezinyamazana bayiziphukuphuku; isigodo siyimfundiso sokuyize.
Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
9 Isiliva esikhandiweyo silethwa sivela eTarshishi, legolide livela eUfazi, umsebenzi wengcitshi, lowezandla zomkhandi wegolide; ziluhlaza okwesibhakabhaka lokuyibubende izigqoko zabo; konke kungumsebenzi wabahlakaniphileyo.
Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
10 Kodwa iNkosi inguNkulunkulu weqiniso, inguNkulunkulu ophilayo lenkosi yaphakade. Ekuthukutheleni kwayo umhlaba uyazamazama, lezizwe kazilakulumela ulaka lwayo.
Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
11 Lizakutsho njalo kubo: Onkulunkulu abangenzanga amazulu lomhlaba bazabhubha basuke emhlabeni langaphansi kwala amazulu.
“Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
12 Owenza umhlaba ngamandla akhe, wamisa ilizwe ngenhlakanipho yakhe, langokuqedisisa kwakhe wendlala amazulu.
Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
13 Lapho ekhupha ilizwi, kulenhlokomo yamanzi emazulwini; wenza inkungu yenyuke emkhawulweni womhlaba, wenza imibane lezulu, akhuphe umoya eziphaleni zakhe.
Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
14 Wonke umuntu unjengenyamazana elwazini; wonke umkhandi wegolide uyangiswa yisithombe esibaziweyo; ngoba isithombe sakhe esibunjwe ngokuncibilikisa siyinkohliso, njalo kakulamphefumulo kuzo.
Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
15 Ziyize, umsebenzi wezinkohliso; ngesikhathi sempindiselo yazo zizabhubha.
Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
16 Isabelo sikaJakobe kasinjengazo, ngoba ungumbumbi wakho konke, loIsrayeli uyintonga yelifa lakhe; iNkosi yamabandla libizo layo.
Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
17 Qoqa impahla yakho uyikhuphe elizweni, wena mhlalikazi wenqaba.
Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
18 Ngoba itsho njalo iNkosi: Khangela, ngizabajikijela ngaphandle abahlali belizwe ngalesisikhathi, ngibacindezele ukuze bakuthole.
Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
19 Maye kimi ngenxa yokwephuka kwami! Inxeba lami linzima; kodwa mina ngathi: Isibili lokhu yinhlupheko yami engizayithwala.
Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
20 Ithente lami lidiliziwe, lentambo zami zonke ziqamukile; abantwana bami basukile kimi, njalo kabakho; kakho ongelula ithente lami futhi, amise amakhetheni ami.
Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
21 Ngoba abelusi sebenjengenyamazana, kabadinganga iNkosi; ngakho-ke kabaphumelelanga, lomhlambi wabo wonke uhlakazekile.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
22 Khangela, umsindo wombiko ufikile, lokuzamazama okukhulu okuvela elizweni lenyakatho, okuzakwenza imizi yakoJuda ibe lunxiwa, indawo yokuhlala yemigobho.
Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
23 Nkosi, ngiyazi ukuthi indlela yomuntu kayikho kuye; kakukho emuntwini ohambayo ukuthi aqondise ukunyathela kwakhe.
Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
24 Nkosi, ngilaya, kodwa ngesahlulelo, hatshi olakeni lwakho, hlezi unginciphise.
Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
25 Thululela ulaka lwakho phezu kwabahedeni abangakwaziyo, laphezu kwensendo ezingabizi ibizo lakho; ngoba bamdlile uJakobe, bamginya, bamqeda, bachitha indawo yakhe yokuhlala.
Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.