< U-Isaya 52 >

1 Vuka, vuka, wembathe amandla akho, Ziyoni! Yembatha izembatho zakho ezinhle, Jerusalema, muzi ongcwele! Ngoba kakusayikungena kuwe futhi ongasokanga longcolileyo.
Jí, jí, ìwọ Sioni, wọ ara rẹ ní agbára. Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀, ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́ n nì. Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́ kì yóò wọ inú rẹ mọ́.
2 Zithintithe usuke othulini, sukuma, uhlale phansi, Jerusalema! Zikhululekuzibopho zentamo yakho, ndodakazi ethunjiweyo yeZiyoni!
Gbọn eruku rẹ kúrò; dìde sókè, kí o sì gúnwà, ìwọ Jerusalẹmu. Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò, ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbèkùn Sioni.
3 Ngoba itsho njalo iNkosi: Lathengiswa ngeze; njalo lizahlengwa ngaphandle kwemali.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́, láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà.”
4 Ngoba itsho njalo iNkosi uJehova: Abantu bami behlela eGibhithe esikhathini sendulo ukuhlala njengabezizwe khona, njalo iAsiriya yabacindezela ngaphandle kwesizatho.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí. “Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti gbé; láìpẹ́ ni Asiria pọ́n wọn lójú.
5 Khathesi-ke, ngilani lapha, itsho iNkosi, ukuthi abantu bami bathethwe ngeze? Labo abababusayo babenza baqhinqe isililo, itsho iNkosi, lebizo lami liqhubeka lihlanjazwa lonke usuku.
“Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?” ni Olúwa wí. “Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́, àwọn tí ó sì ń jẹ ọba lórí wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,” ni Olúwa wí. “Àti ní ọjọọjọ́ orúkọ mi ni asọ̀rọ̀-òdì sí nígbà gbogbo.
6 Ngakho abantu bami bazalazi ibizo lami; ngakho ngalolosuku bazakwazi ukuthi yimi engikhulumayo; khangela, yimi.
Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi; nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni ó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni.”
7 Zinhle kangakanani phezu kwezintaba inyawo zalowo oletha izindaba ezinhle, omemezela ukuthula, oletha indaba ezinhle zokulunga, ozwakalisa usindiso, othi kuyo iZiyoni: UNkulunkulu wakho uyabusa.
Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìnrere ayọ̀ wá, tí wọ́n kéde àlàáfíà, tí ó mú ìyìnrere wá, tí ó kéde ìgbàlà, tí ó sọ fún Sioni pé, “Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!”
8 Ilizwi labalindi bakho! Bazaphakamisa ilizwi, bahlabele kakhulu kanyekanye, ngoba bazabona ilihlo ngelihlo, lapho iNkosi izabuyisa iZiyoni.
Tẹ́tí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn sókè wọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀. Nígbà tí Olúwa padà sí Sioni, wọn yóò rí i pẹ̀lú ojú u wọn.
9 Qhamukani ngentokozo, lihlabelele kanyekanye, lina manxiwa eJerusalema, ngoba iNkosi isibaduduzile abantu bayo, iyihlengile iJerusalema.
Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀, ẹ̀yin ahoro Jerusalẹmu, nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú, ó sì ti ra Jerusalẹmu padà.
10 INkosi yembule ingalo yayo engcwele emehlweni azo zonke izizwe, njalo imikhawulo yonke yomhlaba izabona usindiso lukaNkulunkulu wethu.
Olúwa yóò ṣí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀ ní ojú gbogbo orílẹ̀-èdè, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò rí ìgbàlà Ọlọ́run wa.
11 Sukani, sukani, liphume lapha, lingathinti okungcolileyo, phumani phakathi kwayo, banini ngabahlambulukileyo, lina elithwala izitsha zeNkosi.
Ẹ túká, ẹ túká, ẹ jáde kúrò níhìn-ín yìí! Ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan! Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ kí ẹ sì di mímọ́, ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò Olúwa.
12 Ngoba kaliyikuphuma ngokuphangisa, kumbe lihambe ngokubaleka, ngoba iNkosi izahamba phambi kwenu, loNkulunkulu kaIsrayeli uzakuba ngumvikeli wenu ngasemuva.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò yára kúrò tàbí kí ẹ sáré lọ; nítorí Olúwa ni yóò síwájú yín lọ, Ọlọ́run Israẹli ni yóò sì ṣe ààbò lẹ́yìn ín yín.
13 Khangela, inceku yami izakwenza ngenhlakanipho, iphakeme njalo iphakanyisiwe, iphakeme kakhulu.
Kíyèsi i, ìránṣẹ́ mi yóò hùwà ọlọ́gbọ́n; òun ni a ó gbé sókè tí a ó sì gbéga a ó sì gbé e lékè gidigidi.
14 Njengoba abanengi babethithibele ngawe; ukukhangeleka kwayo kwakonakele kangaka, okwedlula loba nguwuphi, lesimo sayo okwedlula amadodana abantu.
Gẹ́gẹ́ bí a ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń bu ọlá fún un— ìwò ojú rẹ ni a ti bàjẹ́ kọjá ti ẹnikẹ́ni àti ìrísí rẹ̀ ní a ti bàjẹ́ kọjá ohun tí ènìyàn ń fẹ́.
15 Ngokunjalo izafafaza izizwe ezinengi; amakhosi azayivalela umlomo wawo; ngoba lokho abangakulandiselwanga bazakubona, lalokho abangakuzwanga bazakuqedisisa.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe bomirin àwọn orílẹ̀-èdè ká, àwọn ọba yóò sì pa ẹnu wọn mọ́ nítorí rẹ̀. Nítorí ohun tí a kò sọ fún wọn, wọn yóò rí i, àti ohun tí wọn kò tí ì gbọ́, ni yóò sì yé wọn.

< U-Isaya 52 >