< UHoseya 9 >

1 Ungajabuli, wena Israyeli, kube yinjabulo, njengezizwe, ngoba uwulile usuka kuNkulunkulu wakho; uthanda umvuzo wobuwule emabaleni wonke okubhulela amabele.
Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
2 Ibala lokubhulela lesikhamelo sewayini kakuyikubondla, lewayini elitsha lizabakhohlisa.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
3 Kabayikuhlala elizweni leNkosi, kodwa uEfrayimi uzabuyela eGibhithe, badle okungcolileyo eAsiriya.
Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
4 Kabayikuthululela iwayini eNkosini, kabayikuyithokozisa; imihlatshelo yabo izakuba njengesinkwa sokulila kubo; bonke abasidlayo bazangcola; ngoba isinkwa sabo ngesomphefumulo wabo, kasiyikufika endlini yeNkosi.
Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
5 Lizakwenzani ngosuku lomkhosi omisiweyo, langosuku lwedili leNkosi?
Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
6 Ngoba khangela, bahambile ngenxa yokuchitheka, iGibhithe izababutha, iMofi ibangcwabe, izindawo zabo eziloyisekayo zesiliva, ukhula oluhlabayo luzakudla ilifa lazo, ameva abe semathenteni abo.
Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
7 Insuku zokuhanjelwa sezifikile, insuku zempindiselo sezifikile; uIsrayeli uzakwazi; umprofethi uyisithutha, umuntu womoya uyahlanya, ngenxa yobunengi bobubi benu, lenzondo enkulu.
Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
8 Umlindi wakoEfrayimi uloNkulunkulu wami, kodwa umprofethi uyisifu somthiyi wenyoni endleleni zakhe zonke, inzondo endlini kaNkulunkulu wakhe.
Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
9 Bazonakalisile ngokujulileyo njengensukwini zeGibeya. Uzakhumbula ububi babo, ajezise izono zabo.
Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
10 Ngamthola uIsrayeli njengezithelo zevini enkangala, ngababona oyihlo njengezithelo zokuqala emkhiweni ekuqaleni kwazo. Kodwa bona baya eBhali-Peyori, bazehlukanisela lelohlazo, baba ngokunengekayo njengokuthanda kwabo.
“Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
11 NgoEfrayimi, udumo lwabo luzaphapha luhambe njengenyoni, kusukela ekuzalweni, njalo kusukela esiswini, njalo kusukela ekumithweni.
Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
12 Loba bekhulisa abantwana babo, kube kanti ngizabenza bafelwe, kungasali muntu. Yebo-ke, maye kubo ekusukeni kwami kubo!
Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
13 UEfrayimi, njengokubona kwami iTire, uhlanyelwe endaweni yokuhlala; kodwa uEfrayimi uzakhuphela abantwana bakhe kumbulali.
Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
14 Banike, Nkosi! Uzanikani? Banike isizalo esiphunzayo, lamabele omileyo.
Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
15 Bonke ububi babo buseGiligali, ngoba ngabazonda khona, ngenxa yobubi bezenzo zabo, ngizabaxotsha endlini yami, kangisayikubathanda; zonke iziphathamandla zabo zingabahlamuki.
“Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
16 UEfrayimi utshayiwe; impande yabo yomile, kabayikuthela isithelo; yebo loba bezala, ngizabulala izithelo zesizalo sabo ezithandekayo.
Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
17 UNkulunkulu wami uzabala, ngoba kabamlaleli; bazakuba ngabazulayo phakathi kwezizwe.
Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< UHoseya 9 >