< UHoseya 7 >
1 Lapho bengingelapha uIsrayeli, khona isiphambeko sikaEfrayimi sembulwa, lobubi beSamariya; ngoba benza amanga, lesela liyangena, leviyo labaphangi liyaphanga ngaphandle.
nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá. Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta. Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn, àwọn olè ń fọ́ ilé; àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
2 Njalo kabangatsho enhliziyweni yabo ukuthi ngiyabukhumbula bonke ububi babo. Khathesi izenzo zabo zibahanqile, ziphambi kobuso bami.
ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn. Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá; wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.
3 Bayayithokozisa inkosi ngobubi babo, leziphathamandla ngamanga abo.
“Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn, àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.
4 Bonke bayafeba; banjengeziko elibaselwa ngumphekizinkwa, oyekela ukukhwezela umlilo kusukela ekuxoveni inhlama kuze kube sekubileni kwayo.
Alágbèrè ni gbogbo wọn wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà tí a dáwọ́ kíkoná dúró, lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
5 Kulusuku lwenkosi yethu; iziphathamandla ziyigulise ngokutshisa kwewayini; yelulela isandla sayo kanye labaklolodayo.
Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
6 Ngoba zalungisa inhliziyo yazo njengeziko ngokucathamela kwazo; umphekizinkwa wazo ulala ubusuku bonke; ekuseni libhebhe njengomlilo olelangabi.
Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí, ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
7 Zonke ziyatshisa njengeziko; zidle abehluleli bazo; amakhosi azo wonke awile; kakulamuntu phakathi kwazo ongibizayo.
Gbogbo wọn gbóná bí ààrò wọ́n pa gbogbo olórí wọn run, gbogbo ọba wọn si ṣubú kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.
8 UEfrayimi yena uzihlanganise lezizwe; uEfrayimi uliqebelengwana elingaphendulwanga.
“Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà; Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.
9 Abezizwe badla amandla akhe, kodwa yena kazi. Yebo, inwele ezimpunga zihlakazekile phezu kwakhe, kodwa yena kazi.
Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run ṣùgbọ́n kò sì mọ̀. Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.
10 Lokuzigqaja kukaIsrayeli kuyafakaza ebusweni bakhe, kodwa kababuyeli eNkosini uNkulunkulu wabo, kabayidingi ngakho konke lokhu.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.
11 Njalo uEfrayimi unjengejuba eliyisiphukuphuku elingelangqondo; bakhalela iGibhithe, baye eAsiriya.
“Efraimu dàbí àdàbà tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
12 Lapho behamba ngizakwendlala imbule lami phezu kwabo, ngibehlise njengenyoni zamazulu, ngibajezise njengokwezwakala ebandleni labo.
Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn, Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run. Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀, Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
13 Maye kubo, ngoba babalekile kimi! Incithakalo kubo, ngoba baphambukile bemelene lami. Lanxa mina bengingabahlenga, kube kanti bona baqamba amanga bemelene lami.
Ègbé ní fún wọn, nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi! Ìparun wà lórí wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi! Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà. Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.
14 Kabakhaleli-ke kimi ngenhliziyo yabo, lapho beqhinqa isililo emibhedeni yabo; babuthana ngenxa yamabele lewayini elitsha, bayaphambuka bemelene lami.
Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn. Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
15 Lanxa mina ngibalaya ngiqinisa izingalo zabo, kanti baceba okubi bemelene lami.
Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára, síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
16 Bayaphenduka kodwa kunge koPhezukonke; banjengedandili elikhohlisayo; iziphathamandla zabo ziwa ngenkemba ngenxa yentukuthelo yolimi lwabo. Lokhu kuzakuba yinhlekisa yabo elizweni leGibhithe.
Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo; wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́. Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú nítorí ìrunú ahọ́n wọn. Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.